< Amós 1 >

1 Las palabras de Amos, que estaba entre los pastores de Tecoa; lo que vio de Israel en los días de Uzías, rey de Judá, y en los días de Jeroboam, hijo de Joás, rey de Israel, dos años antes del terremoto.
Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
2 Y él dijo: El Señor dará un rugido de león desde Sión, su voz sonará desde Jerusalén; y los campos de los criadores de ovejas estarán de duelo, y la parte superior del Carmelo se secará.
Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
3 Estas son las palabras del Señor: por tres crímenes de Damasco, y por cuatro, no dejaré que cambie su destino; porque trillaron a Galaad con instrumentos de trituración de hierro.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
4 Y enviaré fuego a la casa de Hazael, quemando las grandes casas de Ben Hadad.
Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5 Y tendré las cerraduras de la puerta de Damasco rotas, y al que está sentado en el poder lo exterminare del valle de Avén, y aquel en cuya mano está gobierno de la casa del Edén; y la gente de Siria se irá como prisioneros a Kir, dice el Señor.
Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
6 Estas son las palabras del Señor: por tres crímenes de Gaza, y por cuatro, no dejaré que cambie su destino; porque se llevaron a toda la gente prisioneros, para entregarlos a Edom.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7 Y enviaré un incendio al muro de Gaza, quemando sus palacios.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
8 Al que está sentado en el poder, lo habré cortado de Asdod, y aquel que gobierna en Ascalon; y mi mano se volverá contra Ecrón, y el resto de los filisteos vendrán a la destrucción, dice el Señor Dios.
Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Estas son las palabras del Señor: por tres crímenes de Tiro, y por cuatro, no dejaré que cambie su destino; porque entregaron a todos los prisioneros a Edom, sin pensar en el acuerdo de los hermanos entre ellos.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
10 Y enviaré fuego sobre el muro de Tiro, quemando sus palacios.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
11 Estas son las palabras del Señor: por tres crímenes de Edom, y por cuatro, no dejaré que cambie su destino; porque su espada se volvió contra su hermano, sin piedad, y su ira ardía en todo momento, y estaba enojado para siempre.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
12 Y enviaré fuego a Teman, quemando los palacios de Bosra.
Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
13 Estas son las palabras del Señor: por tres crímenes de los hijos de Amón, y por cuatro, no revocara su castigo; porque en Galaad abrían los vientres de las mujeres embarazadas, con el fin de ampliar los límites de sus tierras.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Y haré un fuego en el muro de Rabá, quemando sus palacios, en medio de gritos en el día de la batalla, en medio de una tempestad, en el día de la tormenta.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 Y su rey será hecho prisionero, él y sus capitanes juntos, dice el Señor.
Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.

< Amós 1 >