< 1 Reyes 4 >
1 Salomón fue rey sobre todo Israel.
Solomoni ọba sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli.
2 Y estos eran sus principales: Azarías, hijo de Sadoc, era el sacerdote;
Àwọn wọ̀nyí sì ni ìjòyè rẹ̀: Asariah ọmọ Sadoku àlùfáà:
3 Elihoref y Ahías, los hijos de Sisa, eran escribas; Josafat, el hijo de Ahilud, fue el registrador;
Elihorefu àti Ahijah àwọn ọmọ Ṣisa akọ̀wé; Jehoṣafati ọmọ Ahiludi ni akọ̀wé ìlú;
4 Benaía, el hijo de Joiada, era jefe del ejército; Sadoc y Abiatar eran sacerdotes;
Benaiah ọmọ Jehoiada ni olórí ogun; Sadoku àti Abiatari ni àwọn àlùfáà;
5 Azarías, el hijo de Natán, estaba sobre los que tenían autoridad en las diferentes divisiones del país; Zabud, el hijo de Natán, era sacerdote y amigo del rey;
Asariah ọmọ Natani ni olórí àwọn agbègbè; Sabudu ọmọ Natani, àlùfáà àti olùgba ọba ní ìmọ̀ràn;
6 Ahisar era el controlador de la casa del rey; Adoniram, el hijo de Abda, fue supervisor del trabajo forzado.
Ahiṣari ni olùtọ́jú ààfin; Adoniramu ọmọ Abida ni ó ń ṣe olórí iṣẹ́-ìlú.
7 Y Salomón puso doce supervisores sobre todo Israel, para que se hiciera cargo de las tiendas que necesitaban el rey y los de su casa; Cada hombre era responsable de un mes en el año.
Solomoni sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbègbè Israẹli, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.
8 Y estos son sus nombres: el hijo de Hur en la región montañosa de Efraín;
Orúkọ wọn ni wọ̀nyí: Bene-Huri ní ìlú olókè Efraimu.
9 El hijo de Decar, en Macaz y Saalbim y Bet-semes, Elon y Bet-hanan;
Bene-Dekeri ní Makasi, Ṣaalbimu, Beti-Ṣemeṣi, àti Eloni Beti-Hanani;
10 El hijo de Jésed en Arubot, y también en Soco y toda la tierra de Hefer; estaban bajo su control;
Bene-Hesedi, ní Aruboti (tirẹ̀ ni Soko àti gbogbo ilẹ̀ Heferi ń ṣe);
11 El hijo de Abinadab en todo el territorio de dor; Su esposa fue Tafat, la hija de Salomón.
Bene-Abinadabu, ní Napoti (Dori; òun ni ó fẹ́ Tafati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
12 Baana, el hijo de Ahilud, en Taanac, y Meguido y todo Bet- seán que está al lado de Saretan, debajo de Jezreel, desde Bet-seán hasta Abel-mehola, hasta el otro lado de Jocmeam;
Baana ọmọ Ahiludi, ní Taanaki àti Megido, àti ní gbogbo Beti-Ṣeani tí ń bẹ níhà Saretani ní ìsàlẹ̀ Jesreeli, láti Beti-Ṣeani dé Abeli-Mehola títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jokimeamu.
13 El hijo de Geber en Ramot de Galaad; tenía los pueblos de Jair, el hijo de Manasés, que están en Galaad, y el país de Argob, que está en Basán, sesenta grandes pueblos con muros y cerraduras de bronce.
Ọmọ Geberi ní Ramoti Gileadi (tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jairi ọmọ Manase tí ń bẹ ní Gileadi, tirẹ̀ sì ni agbègbè Argobu, tí ń bẹ ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu-ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin).
14 Ahinadab, el hijo de Ido, en Mahanaim;
Ahinadabu ọmọ Iddo ní Mahanaimu
15 Ahimaas en Neftalí; tomó a Basemat, la hija de Salomón, como a su esposa;
Ahimasi ní Naftali (ó fẹ́ Basemati ọmọbìnrin Solomoni ní aya).
16 Baana, el hijo de Husai, en Aser y Alot;
Baana ọmọ Huṣai ní Aṣeri àti ní Aloti;
17 Josafat, hijo de Parua, en Isacar;
Jehoṣafati ọmọ Parua ni ó wà ní Isakari;
18 Simei, el hijo de Ela, en Benjamín;
Ṣimei ọmọ Ela ni Benjamini;
19 Geber, hijo de Uri, en la tierra de Galaad, la tierra de Sehón, rey de los amorreos, y Og, rey de Basán; y un supervisor general, tenía autoridad sobre todos los supervisores que estaban en la tierra.
Geberi ọmọ Uri ní Gileadi (orílẹ̀-èdè Sihoni ọba àwọn ará Amori àti orílẹ̀-èdè Ogu ọba Baṣani). Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.
20 Judá e Israel eran tan numerosos en número como la arena junto al mar, y tomaron su comida y bebida con alegría en sus corazones.
Àwọn ènìyàn Juda àti ti Israẹli pọ̀ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn tí ń bẹ ní etí Òkun; wọ́n ń jẹ, wọ́n sì ń mu, wọ́n sì ń yọ ayọ̀.
21 Y Salomón gobernó todos los reinos desde el río hasta la tierra de los filisteos, hasta el borde de Egipto; Los hombres le dieron ofrendas y fueron sus sirvientes todos los días de su vida.
Solomoni sì ń ṣàkóso lórí gbogbo àwọn ìjọba láti odò Eufurate títí dé ilẹ̀ àwọn ará Filistini, àti títí dé etí ilẹ̀ Ejibiti. Àwọn orílẹ̀-èdè yìí ń mú owó òde wá, wọ́n sì ń sin Solomoni ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀.
22 Y la cantidad de comida de Salomón por un día fue de treinta medidas de grano triturado y sesenta medidas de comida;
Oúnjẹ Solomoni fún ọjọ́ kan jásí ọgbọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná àti ọgọ́ta òsùwọ̀n ìyẹ̀fun,
23 Diez bueyes gordos y veinte bueyes de los pastos, y cien ovejas, además venados y gacelas y aves gordas.
Màlúù mẹ́wàá tí ó sanra, àti ogún màlúù láti inú pápá wá, àti ọgọ́rùn-ún àgùntàn àti ewúrẹ́, láìka àgbọ̀nrín àti èsúró, àti ogbúgbu, àti ẹyẹ tí ó sanra.
24 Porque tenía autoridad sobre todo el país en este lado del río, desde Tifsa hasta Gaza, sobre todos los reyes en este lado del río; y tuvo paz a su alrededor por todos lados.
Nítorí òun ni ó ṣàkóso lórí gbogbo agbègbè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn odò Eufurate, láti Tifisa títí dé Gasa, lórí gbogbo àwọn ọba ní ìhà ìhín odò, ó sì ní àlàáfíà ní gbogbo ìlú tí ó yí i káàkiri.
25 Y vivían Judá e Israel a salvo, cada uno debajo de su vid y su higuera, desde Dan hasta Beerseba, todos los días de Salomón.
Nígbà ayé Solomoni, Juda àti Israẹli, láti Dani títí dé Beerṣeba, wọ́n ń gbé ní àlàáfíà, olúkúlùkù lábẹ́ àjàrà rẹ̀ àti lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀.
26 Y Salomón tenía cuatro mil casilleros para caballos en sus carruajes y doce mil jinetes.
Solomoni sì ní ẹgbàajì ilé ẹṣin fún kẹ̀kẹ́ rẹ̀, àti ẹgbàá mẹ́fà ẹlẹ́ṣin.
27 Y esos supervisores, todos los hombres en turno del mes, vieron que se producía comida para Salomón y todos sus invitados, y cuidaban de que nada se pasara por alto.
Àwọn ìjòyè agbègbè, olúkúlùkù ní oṣù rẹ̀, ń pèsè oúnjẹ fún Solomoni ọba àti gbogbo àwọn tí ń wá sí ibi tábìlì ọba, wọ́n sì rí i pé ohun kankan kò ṣẹ́kù.
28 Y llevaron grano y pasto seco para los caballos y los carruajes, al lugar correcto, cada uno como se le ordenó.
Wọ́n tún máa ń mú ọkà barle àti koríko fún ẹṣin àti fún ẹṣin sísáré wá pẹ̀lú sí ibi tí ó yẹ, olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí ìlànà tirẹ̀.
29 Y Dios le dio a Salomón una gran cantidad de sabiduría y buen sentido, y una mente de gran alcance, tan ancha como la arena junto al mar.
Ọlọ́run sì fún Solomoni ní ọgbọ́n, àti òye ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, àti ìmọ̀ gbígbòòrò òye tí a kò le è fiwé iyanrìn tí ó wà létí Òkun.
30 Y la sabiduría de Salomón era mayor que la sabiduría de todos los pueblos del este y toda la sabiduría de Egipto.
Ọgbọ́n Solomoni sì pọ̀ ju ọgbọ́n ọkùnrin ìlà-oòrùn lọ, ó sì pọ̀ ju gbogbo ọgbọ́n Ejibiti lọ.
31 Porque era más sabio que todos los hombres, incluso que Etán de Zera, y Heman y Calcol y Darda, los hijos de Mahol; y tuvo un gran nombre entre todas las naciones alrededor.
Ó sì ní òye ju gbogbo ènìyàn lọ, ju Etani, ará Esra, àti Hemani àti Kalkoli, àti Darda àwọn ọmọ Maholi lọ. Òkìkí rẹ̀ sì kàn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yíká.
32 Fue el creador de tres mil dichos sabios, y de canciones hasta el número de mil cinco.
Ó sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́ta òwe, àwọn orin rẹ̀ sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé márùn-ún.
33 Hizo dichos sobre todas las plantas, desde el cedro en el Líbano hasta el hisopo colgado en la pared; y sobre todas las bestias y aves y peces y las cosas pequeñas de la tierra.
Ó sì sọ̀rọ̀ ti igi, láti kedari tí ń bẹ ní Lebanoni dé Hísópù tí ń dàgbà lára ògiri. Ó sì tún sọ ti àwọn ẹranko àti ti àwọn ẹyẹ, àti ohun tí ń rákò àti ti ẹja.
34 La gente venía de todas las naciones para escuchar la sabiduría de Salomón, de todos los reinos de la tierra que habían oído de las palabras de su sabiduría.
Àwọn ènìyàn sì ń wá láti gbogbo orílẹ̀-èdè láti gbọ́ ọgbọ́n Solomoni, láti ọ̀dọ̀ àwọn ọba ayé láti wá gbọ́ nípa ọgbọ́n rẹ̀.