< 1 Crónicas 9 >

1 Así que todo Israel fue enumerado por sus geneologias; están registrados en el libro de los reyes de Israel. Y a Judá se lo llevaron como prisionero a Babilonia por su pecado.
Gbogbo Israẹli ni a kọ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ àwọn baba ńlá nínú ìwé àwọn ọba Israẹli. Àwọn ènìyàn Juda ni a kó ní ìgbèkùn lọ sí Babeli nítorí àìṣòótọ́ wọn.
2 Los primeros en retomar su herencia en sus ciudades fueron: Israel, los sacerdotes, los levitas y los sirvientes del templo.
Nísinsin yìí, àwọn tí ó kọ́kọ́ tún tẹ̀dó lórí ohun ìní wọn ní ìlú wọn ni díẹ̀ nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa.
3 Y en Jerusalén vivían algunos de los hijos de Judá, Benjamín, Efraín y Manasés;
Àwọn tí ó wá láti Juda láti Benjamini àti láti Efraimu àti Manase tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu jẹ́:
4 Utai, el hijo de Amiud, el hijo de Omri, el hijo de Imri, el hijo de Bani, de los hijos de Fares, el hijo de Judá.
Uttai ọmọ Ammihudu, ọmọ Omri, ọmọ Imri, ọmọ Bani, ìran ọmọ Peresi ọmọ Juda.
5 Y de los silonitas: Asaías el mayor, y sus hijos.
Àti nínú ará Ṣilo: Asaiah àkọ́bí àti àwọn ọmọ rẹ̀.
6 De los hijos de Zera, Jeuel y sus hermanos, seiscientos noventa.
Ní ti ará Sera: Jeueli. Àwọn ènìyàn láti Juda sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́wàá.
7 De los hijos de Benjamín: Salu, hijo de Mesulam, hijo de Hodavias, hijo de Asenua.
Àti nínú àwọn ọmọ Benjamini ni: Sallu ọmọ Meṣullamu, ọmọ Hodafiah; ọmọ Hasenuah;
8 E Ibneias, hijo de Jeroham, Ela, hijo de Uzi, hijo de Micri, y Mesulam, hijo de Sefatías, hijo de Reuel, hijo de Ibnias;
Ibinaiah ọmọ Jerohamu; Ela ọmọ Ussi, ọmọ Mikri; àti Meṣullamu ọmọ Ṣefatia; ọmọ Reueli, ọmọ Ibinijah.
9 Y sus hermanos, en la lista de sus generaciones, novecientos cincuenta y seis. Todos estos hombres eran jefes de familia, enumerados por los nombres de sus padres.
Àwọn ènìyàn láti Benjamini gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ ọ́ nínú ìran wọn nínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó dín mẹ́rìnlélógójì. Gbogbo àwọn ọkùnrin yí jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé.
10 Y de los sacerdotes: Jedaías y Joiarib y Jaquin.
Ní ti àwọn àlùfáà: Jedaiah; Jehoiaribi; Jakini;
11 Y Azarías, hijo de Hilcías, hijo de Mesulam, hijo de Sadoc, hijo de Meraiot, hijo de Ahitob, jefe principal de la casa de Dios;
Asariah ọmọ Hilkiah, ọmọ Meṣullamu, ọmọ Sadoku, ọmọ Meraioti, ọmọ Ahitubu, olórí tí ó ń bojútó ilé Ọlọ́run;
12 Adaía, hijo de Jeroham, hijo de Pasur, hijo de Malquías, y Masai, hijo de Adiel, hijo de Jazera, hijo de Mesulam, hijo de Mesilemit, hijo de Imer.
Adaiah ọmọ Jerohamu, ọmọ Paṣuri, ọmọ Malkiah; àti Masai ọmọ Adieli, ọmọ Jahisera, ọmọ Meṣullamu ọmọ Meṣilemiti, ọmọ Immeri.
13 Y sus hermanos, jefes de sus familias, mil setecientos sesenta: hombres capaces, para él servicio del templo de Dios.
Àwọn àlùfáà, tí wọ́n jẹ́ àwọn olórí àwọn ìdílé, tí ó jẹ́ ẹgbẹ̀sán ó dín méjì. Wọ́n jẹ́ alágbára ọkùnrin, tí wọ́n lè dúró fún iṣẹ́ ìránṣẹ́ nínú ilé Ọlọ́run.
14 Y de los levitas: Semaías, hijo de Hasub, hijo de Azricam, hijo de Hasabías, de los hijos de Merari;
Ní ti àwọn ará Lefi: Ṣemaiah ọmọ Haṣubu, ọmọ Asrikamu, ọmọ Haṣabiah ará Merari;
15 Y Bacbacar, Heres, Galal, Matanias, el hijo de Micaía, el hijo de Zicri, el hijo de Asaf;
Bakibakari, Hereṣi, Galali àti Mattaniah, ọmọ Mika, ọmọ Sikri, ọmọ Asafu;
16 Obadias, hijo de Semaías, hijo de Galal, hijo de Jedutún, y Berequías, hijo de Asa, hijo de Elcana, que vivían en las pequeñas aldeas de los netofatitas.
Obadiah ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Galali, ọmọ Jedutuni; àti Berekiah ọmọ Asa, ọmọ Elkana, tí ó ń gbé nínú àwọn ìlú àwọn ará Netofa.
17 Y los encargados de las puertas: Salum y Acub, Talmón, Ahiman y sus hermanos: Salum era el jefe.
Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà: Ṣallumu, Akkubu, Talmoni, Ahimani àti arákùnrin wọn, Ṣalumu olóyè wọn,
18 Hasta entonces habían estado en la puerta del rey, al este. Eran guardianes de las puertas de los campamentos de los hijos de Leví.
ti wà ní ipò ìdúró ní ẹnu-ọ̀nà ọba ní apá ìhà ìlà-oòrùn títí di àkókò yí. Wọ̀nyí ni àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà tí ó jẹ́ ti ìpàgọ́ àwọn ará Lefi.
19 Y Salum, el hijo de Coré, el hijo de Ebiasaf, el hijo de Coré, y sus hermanos, de su familia, los coeritas, eran responsables de todo lo que debía hacerse en relación con el orden del culto, guardianes de las puertas del santuario; como sus padres habían tenido el cuidado del santuario del Señor, siendo guardianes de la puerta.
Ṣallumu ọmọ Kore ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora, àti àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ẹlẹgbẹ́ rẹ̀. Láti ìdílé rẹ̀ (àwọn ará Korati) ni ó dúró fún ṣíṣọ́ ìloro ẹnu-ọ̀nà àgọ́ gẹ́gẹ́ bí baba wọn ti ń dúró fún ṣíṣọ́ àbáwọlé ibùgbé Olúwa.
20 En el pasado, Finees, el hijo de Eleazar, había gobernado sobre ellos; ¡Que el Señor esté con él!
Ní ìgbà àkọ́kọ́ Finehasi ọmọ Eleasari jẹ́ olórí fún àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà, Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
21 Zacarías, el hijo de Meselemías, era el guardián de la puerta de la tienda de la reunión.
Sekariah, ọmọ Meṣelemiah jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àbáwọlé sí àgọ́ ibi ìpàdé.
22 Había doscientos doce cuya misión era mantener la puerta. Estos fueron enumerados por las familias en los lugares del país donde vivían, a quienes David y Samuel, el vidente, colocaron en sus posiciones responsables.
Gbogbo rẹ̀ lápapọ̀, àwọn tí a yàn láti jẹ́ olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ní àwọn ìloro jẹ́ igba ó lé méjìlá. A ka àwọn wọ̀nyí nípa ìdílé ní ìletò wọn. Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà ni a ti yàn sí ipò láti ọ̀dọ̀ Dafidi àti Samuẹli, aríran, nítorí òtítọ́ wọn.
23 Así que ellos y sus hijos cuidaban las puertas del Templo del Señor, vigilantes del santuario.
Àwọn àti àwọn ọmọ wọn ni ó wà fún ṣíṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa ilé tí a pè ní àgọ́.
24 Había guardias de las puertas en los cuatro lados, al este, al oeste, al norte y al sur.
Àwọn olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà wà ní igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin: ìlà-oòrùn, ìwọ̀-oòrùn àríwá àti gúúsù.
25 Y sus hermanos, en los países donde vivían, debían venir cada siete días para estar con ellos de vez en cuando.
Àwọn arákùnrin wọn ní àwọn ìletò wọn ní láti wá ní àkókò dé àkókò láti pín iṣẹ́ ìsìn wọn fún àkókò ọjọ́ méje.
26 Porque los cuatro jefes de las puertas, que eran levitas, tenían una posición especial, cuidando las habitaciones y los tesoros de la casa de Dios.
Ṣùgbọ́n àwọn olórí alábojútó ẹnu-ọ̀nà mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí wọ́n jẹ́ ará Lefi ni a yàn fún àwọn iyàrá àti àwọn àpótí ìṣúra ní ilé Ọlọ́run.
27 Sus dormitorios estaban alrededor del templo de Dios, porque eran responsables de cuidarlo y eran responsables de abrirlo cada mañana.
Wọ́n á lo gbogbo òru ní dídúró yí ilé Ọlọ́run ká, nítorí wọ́n ní láti ṣọ́ ọ, wọ́n sì ní àṣẹ sí kọ́kọ́rọ́ fún ṣíṣí i ní àràárọ̀.
28 Algunos de ellos cuidaban de los recipientes que se usaban en la adoración, para mantener un registro de ellos cuando entraron y cuando los sacaron nuevamente.
Díẹ̀ wà ní ìdí ohun èlò tí à ń lò fún ìsìn ilé Ọlọ́run; wọn a máa kà á nígbà tí wọ́n gbé e wọlé àti nígbà tí a kó wọn jáde.
29 Y algunos de ellos eran responsables de las cosas santas y de los vasos del Lugar Santísimo, y de la comida y el vino y el aceite y el incienso y las especias.
Àwọn mìíràn ni a yàn láti bojútó ohun èlò àti gbogbo ohun èlò ilé tí a yà sọ́tọ̀ fún Ọlọ́run, àti ìyẹ̀fun àti ọtí èso àjàrà àti òróró náà, tùràrí àti tùràrí olóòórùn dídùn.
30 Y algunos de los hijos de los sacerdotes fueron responsables de triturar las especias.
Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn àlùfáà ni ó ń bojútó pípò tùràrí olóòórùn dídùn papọ̀.
31 Y Matatías, uno de los levitas, el hijo mayor de Salum el Coreita, fue el responsable de cocinar las tortas para la ofrenda.
Ará Lefi tí a sọ ní Mattitiah àkọ́bí ọmọkùnrin Ṣallumu ará Kora ni a yàn, tí ń ṣe alábojútó ohun tí a dín.
32 Y algunos hijos de los Coatitas, y de sus hermanos fueron responsables del pan sagrado que fue puesto en orden delante del Señor, para que esté listo cada sábado.
Àti nínú àwọn arákùnrin wọn, nínú àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣe ìtọ́jú àkàrà ìfihàn, láti máa pèsè rẹ̀ ní ọjọọjọ́ ìsinmi.
33 Y estos eran los que ordenaban la música y las canciones, los jefes de las familias de los levitas, que vivían en las habitaciones y estaban libres de otros trabajos, porque su trabajo continuaba día y noche.
Àwọn tí wọ́n jẹ́ ọkùnrin, olórí àwọn ìdílé Lefi dúró nínú àgọ́ ilé Olúwa, wọn kò sì ṣe lára iṣẹ́ ìsìn yòókù nítorí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ náà lọ́sàn, lóru.
34 Estos eran jefes de familia de los levitas en sus generaciones, hombres principales; vivían en Jerusalén.
Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Lefi, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti ṣe kọ lẹ́sẹẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu.
35 Y en Gabaón vivía el padre de Gabaón, Jeiel, cuya esposa se llamaba Maaca;
Jeieli baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Orúkọ ìyàwó rẹ̀ a máa jẹ́ Maaka,
36 Y Abdón su hijo mayor, y Zur, Cis, y Baal, Ner y Nadab.
pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀ jẹ́ Abdoni, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu.
37 Y Gedor y Ahio y Zacarías y Miclot.
Gedori, Ahio, Sekariah àti Mikiloti.
38 Miclot fue el padre de Simeam. Vivían con sus hermanos en Jerusalén frente a sus hermanos.
Mikiloti jẹ́ baba Ṣimeamu, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu.
39 Y Ner fue el padre de Cis; y Cis fue el padre de Saúl; y Saúl fue el padre de Jonatán y Malquisua, Abinadab y Esbaal.
Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba a Saulu, àti Saulu baba a Jonatani, àti Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali.
40 Y el hijo de Jonatán fue Merib-baal; y Merib-baal fue el padre de Micaia.
Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali, tí ó jẹ́ baba Mika.
41 Y los hijos de Micaia: Pitón, Melec y Tarea y Acaz.
Àwọn ọmọ Mika: Pitoni. Meleki, Tarea àti Ahasi.
42 Y Acaz fue el padre de Jara; y Jara fue el padre de Alemet y Azmavet y Zimri; y Zimri fue el padre de Mosa.
Ahasi jẹ́ baba Jada, Jada jẹ́ baba Alemeti, Asmafeti, Simri, sì Simri jẹ́ baba Mosa.
43 Y Mosa fue el padre de Bina; Y Refaias era su hijo, Elasa su hijo, Azel su hijo.
Mosa jẹ́ baba Binea; Refaiah jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀.
44 Y Azel tuvo seis hijos, cuyos nombres son: Azricam, su hijo mayor, Bocru, Ismael, Searias Obadias y Hanan: estos fueron los hijos de Azel.
Aseli ní ọmọ mẹ́fà, pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli Ṣeariah, Obadiah àti Hanani, gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli.

< 1 Crónicas 9 >