< Job 28 >

1 Ciertamente la plata tiene su oculto nacimiento, y el oro lugar de donde lo sacan.
Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2 El hierro es tomado del polvo, y de la piedra es fundido el metal.
Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3 A las tinieblas puso término; y a toda obra perfecta que él hizo, puso piedra de oscuridad y de sombra de muerte.
Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4 Sale el río junto al morador, y las aguas sin pie, más altas que el hombre, se fueron.
Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5 Tierra de la cual nace el pan, y debajo de ella estará como convertida en fuego.
Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
6 Lugar que sus piedras serán zafiro, y tendrá polvos de oro.
òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7 Senda que nunca la conoció ave, ni ojo de buitre la vio;
Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
8 nunca la pisaron animales fieros, ni león pasó por ella.
Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9 En el pedernal puso su mano, y trastornó los montes de raíz.
Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 De los peñascos cortó ríos, y sus ojos vieron todo lo preciado.
Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 Detuvo los ríos en su nacimiento, e hizo salir a luz lo escondido.
Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
12 Mas ¿dónde se hallará la sabiduría? ¿Y dónde está el lugar de la prudencia?
Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
13 El hombre nunca supo su valor, ni se halla en la tierra de los vivientes.
Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 El abismo dice: No está en mí; y el mar dijo: Ni conmigo.
Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 No se dará por oro, ni su precio será a peso de plata.
A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 No puede ser apreciada con oro de Ofir, ni con ónice precioso, ni con zafiro.
A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
17 El oro no se le igualará, ni el diamante; ni se cambiará por vaso de oro fino.
Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 De coral ni de perlas no se hará mención; la sabiduría es mejor que las piedras preciosas.
A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 No se igualará con ella esmeralda de Etiopía; no se podrá apreciar con oro fino.
Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20 ¿De dónde pues vendrá la sabiduría? ¿Y dónde esta el lugar de la inteligencia?
Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 Porque encubierta está a los ojos de todo viviente, y a toda ave del cielo es oculta.
A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 El infierno y la muerte dijeron: Su fama hemos oído con nuestros oídos. (questioned)
Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 Dios entiende el camino de ella, y él solo conoce su lugar.
Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 Porque él mira hasta los fines de la tierra, y ve debajo de todo el cielo.
Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 Haciendo peso al viento, y poniendo las aguas por medida;
láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
26 cuando él hizo ley a la lluvia, y camino al relámpago de los truenos.
Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 Entonces la vio él, y la tasó; la preparó y también la inquirió.
nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 Y dijo al hombre: He aquí que el temor del Señor es la sabiduría, y el apartarse del mal la inteligencia.
Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”

< Job 28 >