< 1 Crónicas 3 >

1 ESTOS son los hijos de David, que le nacieron en Hebrón: Amnón el primogénito, de Achînoam Jezreelita; el segundo, Daniel, de Abigail de Carmelo;
Àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Dafidi tí a bí fún un ní Hebroni. Àkọ́bí sì ni Amnoni ọmọ Ahinoamu ti Jesreeli; èkejì sì ni Daniẹli ọmọ Abigaili ará Karmeli;
2 El tercero, Absalom, hijo de Maachâ hija de Talmai rey de Gesur; el cuarto, Adonías hijo de Aggith;
ẹ̀kẹta sì ni Absalomu ọmọ Maaka ọmọbìnrin Talmai ọba Geṣuri bí fún un; ẹ̀kẹrin sì ni Adonijah ọmọ Haggiti;
3 El quinto, Sephatías, de Abithal; el sexto, Itream, de Egla su mujer.
ẹ̀karùnún ni Ṣefatia láti ọ̀dọ̀ Abitali; àti ẹ̀kẹfà, Itreamu, láti ọ̀dọ̀ Egla aya rẹ̀.
4 Estos seis le nacieron en Hebrón, donde reinó siete años y seis meses: y en Jerusalem reinó treinta y tres años.
Àwọn mẹ́fà wọ̀nyí ni a bí fún Dafidi ni Hebroni, níbi tí ó ti jẹ ọba fún ọdún méje àti oṣù mẹ́fà. Dafidi sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n.
5 Estos cuatro le nacieron en Jerusalem: Simma, Sobab, Nathán, y Salomón, de Beth-sua hija de Ammiel.
Wọ̀nyí ni ọmọ wẹ́wẹ́ tí a bí fún un ní Jerusalẹmu: Ṣimea, Ṣobabu, Natani àti Solomoni. Àwọn mẹ́rin wọ̀nyí sì ni a bí láti ọ̀dọ̀ Bati-Ṣua ọmọbìnrin Ammieli.
6 Y [otros] nueve: Ibaar, Elisama, y Eliphelet,
Ibhari sì wà pẹ̀lú, Eliṣama, Elifeleti,
7 Noga, Nepheg, y Japhia,
Noga, Nefegi, Jafia,
8 Elisama, Eliada, y Eliphelet.
Eliṣama, Eliada àti Elifeleti mẹ́sàn-án ni wọ́n.
9 Todos estos fueron los hijos de David, sin los hijos de las concubinas. Y Thamar fué hermana de ellos.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dafidi yàtọ̀ sí àwọn ọmọ tí àlè bí fún un. Tamari sì ni arábìnrin wọn.
10 Hijo de Salomón fué Roboam, cuyo hijo [fué] Abía, del cual [fué] hijo Asa, cuyo hijo [fué] Josaphat;
Ọmọ Solomoni ni Rehoboamu, Abijah ọmọ rẹ̀, Asa ọmọ rẹ̀, Jehoṣafati ọmọ rẹ̀,
11 De quien [fué] hijo Joram, cuyo hijo [fué] Ochôzías, hijo del cual [fué] Joas;
Jehoramu ọmọ rẹ̀, Ahasiah ọmọ rẹ̀, Joaṣi ọmọ rẹ̀,
12 Del cual [fué] hijo Amasías, cuyo hijo [fué] Azarías, é hijo de éste Jotham;
Amasiah ọmọ rẹ̀, Asariah ọmọ rẹ̀, Jotamu ọmọ rẹ̀,
13 E hijo del cual [fué] Achâz, del que [fué] hijo Ezechîas, cuyo hijo [fué] Manasés;
Ahasi ọmọ rẹ̀, Hesekiah ọmọ rẹ̀, Manase ọmọ rẹ̀,
14 Del cual [fué] hijo Amón, cuyo hijo [fué] Josías.
Amoni ọmọ rẹ̀, Josiah ọmọ rẹ̀.
15 Y los hijos de Josías: Johanán su primogénito, el segundo Joacim, el tercero Sedecías, el cuarto Sallum.
Àwọn ọmọ Josiah: àkọ́bí ọmọ rẹ̀ ni Johanani, èkejì ọmọ rẹ̀ ni Jehoiakimu, ẹ̀kẹta ọmọ rẹ̀ ni Sedekiah, ẹ̀kẹrin ọmọ rẹ̀ ni Ṣallumu.
16 Los hijos de Joacim: Jechônías su hijo, hijo del cual [fué] Sedecías.
Àwọn ìran ọmọ Jehoiakimu: Jekoniah ọmọ rẹ̀, àti Sedekiah.
17 Y los hijos de Jechônías: Asir, Salathiel,
Àwọn ọmọ Jekoniah tí a mú ní ìgbèkùn: Ṣealitieli ọmọ rẹ̀ ọkùnrin,
18 Mechiram, Pedaía, Seneaser, y Jecamía, Hosama, y Nedabía.
Malkiramu, Pedaiah, Ṣenasari, Jekamiah, Hoṣama àti Nedabiah.
19 Y los hijos de Pedaía: Zorobabel, y Simi. Y los hijos de Zorobabel: Mesullam, Hananías, y Selomith su hermana.
Àwọn ọmọ Pedaiah: Serubbabeli àti Ṣimei. Àwọn ọmọ Serubbabeli: Meṣullamu àti Hananiah. Ṣelomiti ni arábìnrin wọn.
20 Y [de Mesullam]: Hasuba, Ohel, y Berechîas, Hasadía, y Jusabhesed; cinco [en todos].
Àwọn márùn-ún mìíràn sì tún wà: Haṣuba, Oheli, Berekiah, Hasadiah àti Jusabhesedi.
21 Los hijos de Hananías: Pelatías, y Jesaías, hijo de Rephaías, hijo de Arnán, hijo de Obdías, hijo de Sechânías.
Àwọn ọmọ Hananiah: Pelatiah àti Jeṣaiah, àti àwọn ọmọ Refaiah, ti Arnani, ti Obadiah àti ti Ṣekaniah.
22 Hijo de Sechânías [fué] Semaías; y los hijos de Semaías: Hattus, Igheal, Barias, Nearías, y Saphat; seis.
Àwọn ọmọ Ṣekaniah: Ṣemaiah àti àwọn ọmọ rẹ̀: Hattusi, Igali, Bariah, Neariah àti Ṣafati, mẹ́fà ni gbogbo wọn.
23 Los hijos de Nearías [fueron] estos tres: Elioenai, Ezechîas, y Azricam.
Àwọn ọmọ Neariah: Elioenai; Hesekiah, àti Asrikamu, mẹ́ta ni gbogbo wọn.
24 Los hijos de Elioenai [fueron] estos siete: Odavias, Eliasib, Palaías, Accub, Johanán, Dalaías, y Anani.
Àwọn ọmọ Elioenai: Hodafiah, Eliaṣibu, Pelaiah, Akkubu, Johanani, Delaiah àti Anani, méje sì ni gbogbo wọn.

< 1 Crónicas 3 >