< Proverbios 18 >

1 Conforme al deseo busca el apartado: en toda doctrina se envolverá.
Ènìyàn tí kò ba ni rẹ́ a máa lépa ìmọ̀ ara rẹ̀; ó kọjú ìjà sí gbogbo ìdájọ́ òdodo.
2 No toma placer el insensato en la inteligencia: mas en lo que se descubre su corazón.
Aláìgbọ́n kò rí inú dídùn sí òye ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí sísọ èrò tirẹ̀.
3 Cuando viene el impío, viene también el menosprecio; y con el deshonrador, la vergüenza.
Nígbà ti ènìyàn búburú dé ni ẹ̀gàn dé, nígbà ti ẹ̀gàn dé ni ìtìjú dé.
4 Aguas profundas son las palabras de la boca del hombre; y arroyo revertiente la fuente de la sabiduría.
Ọ̀rọ̀ ẹnu ènìyàn jẹ́ omi jíjìn, ṣùgbọ́n orísun ọgbọ́n jẹ́ odò tí ń sàn.
5 Tener respeto a la persona del impío, para hacer caer al justo de su derecho, no es bueno.
Kò dára kí ènìyàn ṣe ojúsàájú fún ènìyàn búburú tàbí kí a fi ìdájọ́ òdodo du aláìṣẹ̀.
6 Los labios del insensato vienen con pleito; y su boca a cuestiones llama.
Ètè aláìgbọ́n dá ìjà sílẹ̀ ẹnu rẹ̀ sì ń ṣokùnfà ẹgba.
7 La boca del insensato es quebrantamiento para sí; y sus labios son lazos para su alma.
Ẹnu aláìgbọ́n ni ó ba tirẹ̀ jẹ́, ètè rẹ̀ sì jẹ́ ìdẹ̀kùn fún ọkàn rẹ̀.
8 Las palabras del chismoso parecen blandas: mas ellas descienden hasta lo íntimo del vientre.
Ọ̀rọ̀ olófòófó dàbí oúnjẹ àdídùn; wọ́n a sì wọ ìsàlẹ̀ inú lọ.
9 También el que es negligente en su obra, es hermano del dueño disipador.
Ẹni tí kò ṣe déédé nínú iṣẹ́ rẹ̀ arákùnrin ló jẹ́ fún apanirun.
10 Torre fuerte es el nombre de Jehová: a él correrá el justo, y será levantado.
Orúkọ Olúwa, ilé ìṣọ́ agbára ni; olódodo sá wọ inú rẹ̀, ó sì rí ìgbàlà.
11 Las riquezas del rico son la ciudad de su fortaleza; y como un muro alto, en su imaginación.
Ọ̀rọ̀ olówó ni ìlú olódi wọn; wọ́n rò ó bí i wí pé odi tí kò ṣe é gùn ni.
12 Antes del quebrantamiento se eleva el corazón del hombre; y antes de la honra, el abatimiento.
Ṣáájú ìṣubú ọkàn ènìyàn a kọ́kọ́ máa gbéraga, ṣùgbọ́n ìrẹ̀lẹ̀ ni ó máa ń ṣáájú ọlá.
13 El que responde palabra antes de oír, insensatez le es, y vergüenza.
Ẹni tí ó ń fèsì kí ó tó gbọ́, èyí ni ìwà òmùgọ̀ àti ìtìjú rẹ̀.
14 El ánimo del hombre suportará su enfermedad: mas al ánimo angustiado, ¿quién le suportará?
Ọkàn ènìyàn a máa gbé e ró nígbà àìsàn, ṣùgbọ́n ta ni ó le forí ti ọkàn tí ó rẹ̀wẹ̀sì.
15 El corazón del entendido adquiere sabiduría; y el oído de los sabios busca la ciencia.
Ọkàn olóye ní i gba ìmọ̀; etí ọlọ́gbọ́n ní í ṣe àwárí rẹ̀.
16 El presente del hombre le ensancha el camino; y le lleva delante de los grandes.
Ẹ̀bùn máa ń ṣí ọ̀nà fún ẹni tí ń fún ni lẹ́bùn a sì mú un wọlé sí ọ̀dọ̀ àwọn olókìkí.
17 El justo es primero en su pleito; y su adversario viene, y búscale.
Ẹni tí ó kọ́kọ́ rọjọ́ máa ń dàbí i pé ó jàre, títí ẹlòmíràn yóò fi bọ́ síwájú kí ó sì tú àṣírí gbogbo.
18 La suerte pone fin a los pleitos; y desparte los fuertes.
Ìbò dídì máa ń parí ìjà a sì mú kí àwọn alátakò méjì jìnnà sí ara wọn.
19 El hermano ofendido es más contumaz que una ciudad fuerte; y las contiendas de los hermanos son como cerrojos de alcázar.
Arákùnrin tí a ṣẹ̀ sí ṣòro yípadà ju ìlú olódi lọ, ìjà wọ sì dàbí ọ̀pá ìdábùú ààfin.
20 Del fruto de la boca del hombre se hartará su vientre: de la renta de sus labios se hartará.
Láti inú èso ẹnu rẹ̀ ikùn ènìyàn a yó; láti inú ìkórè ẹnu rẹ̀ ni ó ti jẹ yó.
21 La muerte y la vida están en poder de la lengua; y el que la ama, comerá de sus frutos.
Ikú àti ìyè ń bẹ nípa ahọ́n wọn, àwọn tí ó sì fẹ́ràn rẹ̀ yóò jẹ ẹ́.
22 El que halló mujer, halló el bien; y alcanzó la benevolencia de Jehová.
Ẹni tí ó rí aya fẹ́, rí ohun rere, o sì gba ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa.
23 El pobre habla ruegos; mas el rico responde durezas.
Tálákà ń bẹ̀bẹ̀ fún àánú, ṣùgbọ́n ọlọ́rọ̀ a dáhùn pẹ̀lú ìkanra.
24 El hombre de amigos mantiénese en amistad; y a veces hay amigo más conjunto que el hermano.
Ènìyàn tí ó ní ọ̀rẹ́ púpọ̀ le è parun, ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ kan wà tí ó súnmọ́ ni tímọ́tímọ́ ju arákùnrin.

< Proverbios 18 >