< Lamentaciones 3 >
1 Yo soy un hombre que vio aflicción en la vara de su enojo.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Guióme, y me llevó en tinieblas, mas no en luz.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Ciertamente contra mí volvió, y revolvió su mano todo el día.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Hizo envejecer mi carne y mi piel: quebrantó mis huesos.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Edificó contra mí, y cercó me de tóxico, y de trabajo.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Asentóme en oscuridades como los muertos para siempre.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Cercóme de seto, y no saldré: agravó mis grillos.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Aun cuando clamé, y di voces, cerró mi oración.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Cercó de seto mis caminos a piedra tajada: torció mis senderos.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Oso que asecha fue para mí, león en escondrijos.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Torció mis caminos, y despedazóme: tornóme asolado.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Su arco entesó, y púsome como blanco a la saeta.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Hizo entrar en mis riñones la saetas de su aljaba.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Fui escarnio a todo mi pueblo, canción de ellos todos los días.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Hartóme de amarguras, embriagóme de ajenjos.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Quebróme los dientes con cascajo, cubrióme de ceniza.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Y mi alma se alejó de la paz, olvidéme del bien.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Y dije: Pereció mi fortaleza, y mi esperanza de Jehová.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Acuérdate de mi aflicción, y de mi abatimiento, del ajenjo, y de la hiel.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Acordándose se acordará, porque mi alma es humillada en mí.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Esto reduciré a mi corazón; por tanto esperaré.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Misericordias de Jehová son, que no somos consumidos; porque sus misericordias nunca desfallecieron.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Nuevas cada mañana: grande es tu fe.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Mi parte es Jehová, dijo mi alma: por tanto a él esperaré.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Bueno es Jehová a los que en él esperan, al alma que le buscare.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Bueno es esperar callando en la salud de Jehová.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Bueno es al varón, si llevare el yugo desde su mocedad.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Asentarse ha solo, y callará; porque llevó sobre sí.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Pondrá su boca en el polvo, si quizá habrá esperanza.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Dará la mejilla al que le hiriere: hartarse ha de afrenta.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Porque el Señor no desechará para siempre.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Antes si afligiere, también se compadecerá según la multitud de sus misericordias.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Porque no aflige, ni congoja de su corazón a los hijos de los hombres.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Para desmenuzar debajo de sus pies todos los encarcelados de la tierra;
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Para hacer apartar el derecho del hombre delante de la presencia del Altísimo;
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 Para trastornar al hombre en su causa, el Señor no lo sabe.
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 ¿Quién será pues aquel que diga, que vino algo que el Señor no mandó?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 ¿De la boca del Altísimo no saldrá malo ni bueno?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 ¿Por qué pues tiene dolor el hombre viviente, el hombre en su pecado?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Escudriñemos nuestros caminos, y busquemos, y volvámonos a Jehová.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Levantemos nuestros corazones con las manos a Dios en los cielos.
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Nosotros habemos rebelado, y fuimos desleales: por tanto tú no perdonaste.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Tendiste la ira, y perseguístenos; mataste, no perdonaste.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Cubrístete de nube, porque no pasase la oración.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Raedura y abominación nos tornaste en medio de los pueblos.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Todos nuestros enemigos abrieron sobre nosotros su boca.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Temor, y lazo fue a nosotros, asolamiento, y quebrantamiento.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Ríos de aguas echan mis ojos por el quebrantamiento de la hija de mi pueblo.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Mis ojos destilan, y no cesan; porque no hay relajación,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 Hasta que Jehová mire, y vea desde los cielos.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Mis ojos contristaron a mi alma por todas las hijas de mi ciudad.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Cazando me cazarón mis enemigos como a ave, sin porqué.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Ataron mi vida en mazmorra, y pusieron piedra sobre mí.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Aguas vinieron de avenida sobre mi cabeza: yo dije: Muerto soy.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Invoqué tu nombre, o! Jehová, desde la cárcel profunda.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Oíste mi voz: no escondas tu oído a mi clamor, para que yo respire.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Acercástete el día que te invoqué: dijiste: No temas.
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Pleiteaste, Señor, la causa de mi alma, redimiste mi vida.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Tú has visto, o! Jehová, mi sin razón: pleitea mi causa.
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Tú has visto, toda su venganza, todos sus pensamientos contra mí.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Tu has oído la afrenta de ellos, o! Jehová, todos sus pensamientos contra mí:
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Los dichos de los que se levantaron contra mí, y su pensamiento contra mí siempre.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Su sentarse, y su levantarse mira: yo soy su canción.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Págales paga, o! Jehová, según la obra de sus manos.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Dáles ansia de corazón, dáles tu maldición.
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Persíguelos en furor, y quebrántalos de debajo de los cielos, o! Jehová.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.