< Salmos 29 >
1 ¡Tributen a Yavé, oh hijos de los poderosos! ¡Tributen a Yavé la gloria y el poder!
Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
2 ¡Tributen a Yavé la gloria debida a su Nombre! ¡Póstrense ante Yavé en el esplendor de la santidad!
Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
3 Voz de Yavé sobre las aguas: ¡El ʼElohim de gloria truena! ¡Yavé está sobre muchas aguas!
Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
4 Voz de Yavé es poderosa, Voz de Yavé es majestuosa.
Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5 Voz de Yavé que quiebra los cedros, Yavé destroza los cedros del Líbano.
Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6 Él hace saltar al Líbano como un becerro.
Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7 Voz de Yavé que enciende llamaradas.
Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
8 Voz de Yavé que estremece el desierto. Yavé sacude al desierto de Cades.
Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9 Voz de Yavé que estremece los robles y desnuda los bosques. En su Templo todos proclaman su gloria.
Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
10 Yavé preside en el diluvio. Yavé se sienta como Rey para siempre.
Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
11 Yavé dará fortaleza a su pueblo. Yavé bendecirá a su pueblo con paz.
Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.