< Nehemías 7 >

1 Cuando el muro quedó reconstruido y coloqué las hojas de las puertas, los porteros, los cantores y los levitas se encargaron de sus funciones.
Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
2 Entonces puse al frente de Jerusalén a mi hermano Hanani, y a Hananías, jefe de la ciudadela, pues éste era un hombre fiel y temía a ʼElohim más que muchos.
Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
3 Les dije: Las puertas de Jerusalén no serán abiertas hasta que caliente el sol. Aunque los porteros estén presentes, las puertas permanecerán cerradas y trancadas. Sean designados vigías de entre los habitantes de Jerusalén, cada cual en su vigilia, y cada uno frente a su propia casa.
Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
4 Porque la ciudad era espaciosa y grande, pero la gente que vivía allí era poca, y las casas aún no estaban reconstruidas.
Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
5 Mi ʼElohim puso en mi corazón reunir a los notables, los jefes y el pueblo, para que fueran reconocidos por genealogía, pues yo encontré el rollo de la genealogía de los que subieron primero, donde hallé escrito:
Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
6 Estos son hijos de la provincia que subieron del cautiverio de los que fueron deportados, a quienes Nabucodonosor, rey de Babilonia, se llevó, y que regresaron a Jerusalén y Judá, cada uno a su ciudad,
Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
7 quienes vinieron con Zorobabel, Jesuá, Nehemías, Azarías, Raamías, Nahamani, Mardoqueo, Bilsán, Misperet, Bigvay, Nehum, Baana. El número de los varones del pueblo de Israel fue:
Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
8 Hijos de Paros: 2.171;
àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
9 hijos de Sefatías: 372;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
10 hijos de Ara: 652;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
11 hijos de Pahat-moab, de los hijos de Jesuá y Joab: 2.818;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
12 hijos de Elam: 1.254;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
13 hijos de Zatu: 845;
Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
14 hijos de Zacay: 760;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
15 hijos de Binúi: 648;
Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
16 hijos de Bebay: 628;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
17 hijos de Azgad: 2.322;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
18 hijos de Adonicam: 667;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
19 hijos de Bigvay: 2.077;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
20 hijos de Adín: 655;
Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
21 hijos de Ater, de Ezequías: 98;
Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
22 hijos de Hasum: 328;
Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
23 hijos de Bezay: 324;
Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
24 hijos de Harif: 112;
Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
25 hijos de Gabaón: 95;
Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
26 varones de Belén y de Netofa: 188;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
27 varones de Anatot: 128;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
28 varones de Bet-azmavet: 42;
Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
29 de Quiriat-jearim, Cafira y Beerot: 743;
Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
30 varones de Ramá y de Geba: 621;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
31 varones de Micmás: 122;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
32 varones de Bet-ʼEl y de Hai: 123;
Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
33 varones del otro Nebo: 52;
Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
34 varones del otro Elam: 1.254;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
35 hijos de Harim: 320;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
36 hijos de Jericó: 345;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
37 hijos de Lod, Hadid y Ono: 721;
Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
38 hijos de Senaa: 3.930.
Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
39 Los sacerdotes: hijos de Jedaía, de la casa de Jesuá: 973;
Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
40 hijos de Imer: 1.502;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
41 hijos de Pasur: 1.247;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
42 hijos de Harim: 1.017.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
43 Los levitas, hijos de Jesuá, de Cadmiel, de los hijos de Hodavías: 74.
Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
44 Los cantores, hijos de Asaf: 148.
Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
45 Los porteros, hijos de Salum, hijos de Ater, hijos de Talmón, hijos de Acub, hijos de Hatita, hijos de Sobay: 138.
Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
46 Los servidores, hijos de Ziha, hijos de Hasufa, hijos de Tabaot,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
47 hijos de Queros, hijos de Siaha, hijos de Padón,
Kerosi, Sia, Padoni,
48 hijos de Lebana, hijos de Hagaba, hijos de Salmai,
Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
49 hijos de Hanán, hijos de Gidel, hijos de Gahar,
Hanani, Giddeli, Gahari,
50 hijos de Reaía, hijos de Rezín, hijos de Necoda,
Reaiah, Resini, Nekoda,
51 hijos de Gazam, hijos de Uza, hijos de Paseah,
Gassamu, Ussa, Pasea,
52 hijos de Besai, hijos de Mehunim, hijos de Nefisesim,
Besai, Mehuni, Nefisimu,
53 hijos de Bacbuc, hijos de Hacufa, hijos de Harhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri,
54 hijos de Bazlut, hijos de Mehída, hijos de Harsa,
Basluti, Mehida, Harṣa,
55 hijos de Barcos, hijos de Sísara, hijos de Tema,
Barkosi, Sisera, Tema,
56 hijos de Nezía, hijos de Hatifa,
Nesia, àti Hatifa.
57 hijos de los esclavos de Salomón, hijos de Sotay, hijos de Soferet, hijos de Perida,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
58 hijos de Jaala, hijos de Darcón, hijos de Gidel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
59 hijos de Sefatías, hijos de Hatil, hijos de Poqueret-hazebaim, hijos de Amón:
Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
60 Todos los servidores y los hijos de los esclavos de Salomón eran 392.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
61 Y éstos son los que subieron de Telmela, Telharsa, Querub, Adón e Imer, y no pudieron indicar sus casas paternas, ni su linaje, ni si eran de Israel o no:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
62 Los hijos de Delaía, los hijos de Tobías, los hijos de Necoda: 642.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
63 Y de los sacerdotes: los hijos de Habaía, los hijos de Cos, los hijos de Barzilay, el cual tomó esposa de las hijas de Barzilay galaadita, con el nombre del cual fue llamado.
Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
64 Éstos buscaron su registro genealógico pero no fue hallado, por lo cual fueron excluidos del sacerdocio por estar impuros.
Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
65 Y el gobernador les dijo que no comieran de las cosas santas hasta que se levantara sacerdote con Urim y Tumim.
Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
66 Toda la congregación reunida era de 42.360,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
67 aparte de sus esclavos y sus esclavas, que eran 6.336; y entre ellos había 245 cantores y cantoras.
yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
68 Sus caballos eran 736, y sus mulas 245.
Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 Sus camellos eran 435, y sus asnos 6.730.
ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
70 Algunos jefes de las casas paternas aportaron para la obra. El gobernador dio al tesoro 8 kilogramos de oro, 50 tazones y 530 túnicas sacerdotales.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
71 Algunos jefes de las casas paternas ofrendaron 160 kilogramos de oro y 1.210 kilogramos de plata para el tesoro de la obra.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
72 El resto del pueblo dio 160 kilogramos de oro, 1.100 kilogramos de plata y 67 túnicas sacerdotales.
Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
73 Los sacerdotes y levitas, los porteros y cantores, algunos del pueblo, los servidores y todo Israel vivieron nuevamente en sus ciudades. Cuando llegó el mes séptimo los hijos de Israel estaban en sus ciudades.
Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,

< Nehemías 7 >