< Lamentaciones 5 >
1 Acuérdate, oh Yavé, de lo que nos sucedió. Ve y mira nuestro oprobio.
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Nuestra heredad pasó a extraños, Nuestras casas a extranjeros.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Somos huérfanos, sin padre. Nuestras madres son como viudas.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 Tenemos que pagar el agua que bebemos. Pagamos también nuestra leña.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 Los que nos siguen están sobre nuestras nucas. Trabajamos y no tenemos descanso.
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 Tuvimos que someternos a Egipto y a Asiria Para tener suficiente pan.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Nuestros antepasados pecaron, no existen. Nosotros cargamos sus iniquidades.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Unos esclavos nos dominan. No hay uno que nos libre de su mano.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Para conseguir nuestro pan arriesgamos nuestras vidas A causa de la espada en la región despoblada.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Nuestra piel arde como un horno A causa de los ardores del hambre.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 Violaron a las mujeres en Sion, A las doncellas en los pueblos de Judá.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Los magistrados fueron colgados de las manos, Y los ancianos no fueron respetados.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Los jóvenes trabajan en la piedra del molino, Y los niños se tambalean bajo el peso de la leña.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Los ancianos se fueron de la puerta. Los jóvenes abandonaron su música.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 Cesó la alegría de nuestros corazones. Nuestra danza se convirtió en duelo,
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 La corona cayó de nuestra cabeza. ¡Ay de nosotros, porque pecamos!
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 A causa de esto nuestro corazón está enfermo. A causa de estas cosas se nublan nuestros ojos.
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 Porque la Montaña Sion está desolada, Y las zorras se pasean por ella.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Sin embargo Tú, oh Yavé, permaneces para siempre. Tu trono es de generación en generación.
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 ¿Te olvidarás para siempre de nosotros? ¿Nos abandonarás tanto tiempo?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Oh Yavé, devuélvenos a Ti, Y seremos restaurados. Renueva nuestros días para que sean como los de antaño.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 A menos que nos hayas desechado por completo, Y estés sumamente airado contra nosotros.
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.