< Rut 4 >
1 Booz subió a la puerta y se sentó allí. He aquí que el pariente cercano del que hablaba Booz pasaba por allí. Booz le dijo: “¡Ven aquí, amigo, y siéntate!”. Se acercó y se sentó.
Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
2 Booz tomó a diez hombres de los ancianos de la ciudad y les dijo: “Siéntate aquí”, y se sentaron.
Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
3 Le dijo al pariente cercano: “Noemí, que ha vuelto del país de Moab, está vendiendo la parcela que era de nuestro hermano Elimelec.
ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
4 Pensé que debía decírtelo, diciendo: ‘Cómpralo ante los que están aquí sentados y ante los ancianos de mi pueblo’. Si quieres redimirla, redímela; pero si no quieres redimirla, dímelo para que lo sepa. Porque no hay nadie que la redima aparte de ti; y yo estoy detrás de ti”. Dijo: “Lo redimiré”.
Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
5 Entonces Booz dijo: “El día que compres el campo de la mano de Noemí, deberás comprárselo también a Rut la moabita, la mujer del muerto, para levantar el nombre del muerto sobre su herencia.”
Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
6 El pariente cercano dijo: “No puedo redimirlo por mí mismo, para no poner en peligro mi propia herencia. Toma para ti mi derecho de redención, pues no puedo redimirlo”.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
7 Esta era la costumbre de antaño en Israel en cuanto al rescate y al intercambio, para confirmar todas las cosas: un hombre se quitaba la sandalia y se la daba a su vecino; y esta era la manera de formalizar las transacciones en Israel.
Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
8 Entonces el pariente cercano dijo a Booz: “Cómpralo para ti”, y se quitó la sandalia.
Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
9 Booz dijo a los ancianos y a todo el pueblo: “Vosotros sois testigos hoy de que he comprado todo lo que era de Elimelec, y todo lo que era de Quelión y de Mahlón, de la mano de Noemí.
Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
10 Además, a Rut la moabita, esposa de Mahlón, la he comprado para que sea mi esposa, para levantar el nombre del muerto en su herencia, para que el nombre del muerto no sea cortado de entre sus hermanos y de la puerta de su lugar. Vosotros sois hoy testigos”.
Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
11 Todo el pueblo que estaba en la puerta, y los ancianos, dijeron: “Somos testigos. Que el Señor haga que la mujer que ha entrado en tu casa sea como Raquel y como Lea, que ambas edificaron la casa de Israel; y que te trate dignamente en Efrata, y que seas famosa en Belén.
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
12 Que tu casa sea como la casa de Fares, que Tamar dio a Judá, de la descendencia que Yahvé te dará por esta joven.”
Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
13 Booz tomó a Rut y ella se convirtió en su esposa; se acercó a ella, y el Señor le permitió concebir, y dio a luz un hijo.
Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
14 Las mujeres dijeron a Noemí: “Bendito sea Yahvé, que no te ha dejado hoy sin pariente cercano. Que su nombre sea famoso en Israel.
Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
15 Él será para ti un restaurador de la vida y te sostendrá en tu vejez; porque tu nuera, que te ama, que es mejor para ti que siete hijos, lo ha dado a luz.”
Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
16 Noemí tomó al niño, lo puso en su seno y lo amamantó.
Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
17 Las mujeres, sus vecinas, le pusieron un nombre, diciendo: “Le ha nacido un hijo a Noemí”. Le pusieron el nombre de Obed. Es el padre de Isaí, el padre de David.
Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
18 Esta es la historia de las generaciones de Fares: Fares fue padre de Esrom,
Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
19 y Esrom fue padre de Rama, y Rama fue padre de Aminadab,
Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
20 y Aminadab fue padre de Nashón, y Nashón fue padre de Salmón,
Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
21 y Salmón fue padre de Booz, y Booz fue padre de Obed,
Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
22 y Obed fue padre de Isaí, y Isaí fue padre de David.
Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.