< Salmos 33 >

1 ¡Alégrense en Yahvé, justos! La alabanza es propia de los rectos.
Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
2 Da gracias a Yahvé con la lira. Cántale alabanzas con el arpa de diez cuerdas.
Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
3 Cántale una nueva canción. ¡Juega con habilidad y con un grito de alegría!
Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
4 Porque la palabra de Yahvé es justa. Todo su trabajo se realiza con fidelidad.
Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
5 Ama la rectitud y la justicia. La tierra está llena de la bondad amorosa de Yahvé.
Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
6 Por la palabra de Yahvé se hicieron los cielos: todo su ejército por el aliento de su boca.
Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
7 Reúne las aguas del mar como un montón. Él guarda las profundidades en almacenes.
Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
8 Que toda la tierra tema a Yahvé. Que todos los habitantes del mundo le teman.
Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
9 Porque él habló, y fue hecho. Lo ordenó, y se mantuvo firme.
Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
10 Yahvé hace fracasar el consejo de las naciones. Hace que los pensamientos de los pueblos no tengan efecto.
Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
11 El consejo de Yahvé se mantiene firme para siempre, los pensamientos de su corazón a todas las generaciones.
Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
12 Bendita es la nación cuyo Dios es Yahvé, el pueblo que ha elegido para su propia herencia.
Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
13 Yahvé mira desde el cielo. Él ve a todos los hijos de los hombres.
Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
14 Desde el lugar de su morada mira a todos los habitantes de la tierra,
Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
15 el que modela todos sus corazones; y considera todas sus obras.
ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
16 No hay rey que se salve por la multitud de un ejército. Un hombre poderoso no se libra por su gran fuerza.
A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
17 Un caballo es una cosa vana para la seguridad, ni libera a ninguno por su gran poder.
Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
18 He aquí que el ojo de Yahvé está sobre los que le temen, a los que esperan en su amorosa bondad,
Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
19 para librar su alma de la muerte, para mantenerlos vivos en la hambruna.
Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
20 Nuestra alma ha esperado a Yahvé. Él es nuestra ayuda y nuestro escudo.
Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
21 Porque nuestro corazón se regocija en él, porque hemos confiado en su santo nombre.
Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
22 Que tu bondad sea con nosotros, Yahvé, ya que hemos esperado en ti.
Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.

< Salmos 33 >