< Salmos 29 >

1 Un salmo de David. Atribuid a Yahvé, hijos de los poderosos, atribuir a Yahvé la gloria y la fuerza.
Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
2 Atribuye a Yahvé la gloria que merece su nombre. Adoren a Yahvé en forma sagrada.
Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
3 La voz de Yahvé está sobre las aguas. El Dios de la gloria truena, Yahvé sobre muchas aguas.
Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
4 La voz de Yahvé es poderosa. La voz de Yahvé está llena de majestad.
Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5 La voz de Yahvé rompe los cedros. Sí, Yahvé rompe en pedazos los cedros del Líbano.
Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6 También los hace saltar como un ternero; Líbano y Sirión como un buey joven y salvaje.
Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7 La voz de Yahvé golpea con relámpagos.
Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
8 La voz de Yahvé sacude el desierto. Yahvé sacude el desierto de Cades.
Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9 La voz de Yahvé hace parir a los ciervos, y desnuda los bosques. En su templo todo dice: “¡Gloria!”
Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
10 Yahvé se sentó entronizado en el Diluvio. Sí, Yahvé se sienta como Rey para siempre.
Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
11 Yahvé dará fuerza a su pueblo. Yahvé bendecirá a su pueblo con la paz.
Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.

< Salmos 29 >