< Salmos 126 >

1 Una canción de ascensos. Cuando Yahvé hizo volver a los que regresaron a Sión, éramos como los que sueñan.
Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
2 Entonces se nos llenó la boca de risa, y nuestra lengua con el canto. Entonces dijeron entre las naciones, “Yahvé ha hecho grandes cosas por ellos”.
Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
3 Yahvé ha hecho grandes cosas por nosotros, y nos alegramos.
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
4 Restablece nuestra suerte, Yahvé, como los arroyos del Néguev.
Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
5 Los que siembran con lágrimas cosecharán con alegría.
Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
6 El que sale llorando, llevando semilla para sembrar, ciertamente volverá con alegría, llevando sus gavillas.
Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.

< Salmos 126 >