< Salmos 105 >

1 ¡Den gracias a Yahvé! ¡Invoca su nombre! Haz que se conozcan sus actos entre los pueblos.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 ¡Cantadle, cantadle alabanzas! Cuenta todas sus maravillosas obras.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Gloria a su santo nombre. Que se alegre el corazón de los que buscan a Yahvé.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Busca a Yahvé y su fuerza. Busca su rostro para siempre.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Acuérdate de las maravillas que ha hecho: sus maravillas, y los juicios de su boca,
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 tú, descendiente de Abraham, su siervo, vosotros, hijos de Jacob, sus elegidos.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Él es Yahvé, nuestro Dios. Sus juicios están en toda la tierra.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Se ha acordado de su pacto para siempre, la palabra que ordenó a mil generaciones,
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 el pacto que hizo con Abraham, su juramento a Isaac,
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 y se lo confirmó a Jacob por un estatuto; a Israel por un pacto eterno,
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 diciendo: “A ti te daré la tierra de Canaán, el lote de tu herencia”.
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 cuando no eran más que unos pocos hombres, sí, muy pocos, y extranjeros en ella.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Iban de nación en nación, de un reino a otro pueblo.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 No permitió que nadie les hiciera mal. Sí, reprendió a los reyes por su bien,
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 “¡No toquen a mis ungidos! No hagas daño a mis profetas”.
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Convocó una hambruna en la tierra. Destruyó los suministros de alimentos.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Envió a un hombre delante de ellos. José fue vendido como esclavo.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Le magullaron los pies con grilletes. Su cuello fue encerrado con grilletes,
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 hasta el momento en que ocurrió su palabra, y la palabra de Yahvé le dio la razón.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 El rey envió y lo liberó, incluso el gobernante de los pueblos, y déjalo libre.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Lo hizo señor de su casa, y gobernante de todas sus posesiones,
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 para disciplinar a sus príncipes a su antojo, y para enseñar la sabiduría a sus mayores.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Israel también llegó a Egipto. Jacob vivía en la tierra de Cam.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Aumentó su pueblo en gran medida, y los hizo más fuertes que sus adversarios.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Hizo que su corazón se volviera a odiar a su pueblo, para conspirar contra sus sirvientes.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Envió a Moisés, su siervo, y Aarón, a quienes había elegido.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Hicieron milagros entre ellos, y maravillas en la tierra de Jamón.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Envió las tinieblas y las hizo oscuras. No se rebelaron contra sus palabras.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Convirtió sus aguas en sangre, y mató a sus peces.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Su tierra se llenó de ranas, incluso en las habitaciones de sus reyes.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Habló, y vinieron enjambres de moscas, y piojos en todas sus fronteras.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Les dio granizo como lluvia, con un rayo en su tierra.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Hirió sus vides y también sus higueras, y destrozaron los árboles de su país.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Él habló, y las langostas vinieron con los saltamontes, sin número.
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 Se comieron todas las plantas de su tierra, y comieron el fruto de su tierra.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 También hirió a todos los primogénitos de su tierra, las primicias de toda su hombría.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Los sacó con plata y oro. No había una sola persona débil entre sus tribus.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Egipto se alegró cuando partieron, porque el miedo a ellos había caído sobre ellos.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Extendió una nube como cobertura, fuego para dar luz en la noche.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Le pidieron, y trajo codornices, y los satisfizo con el pan del cielo.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Abrió la roca y las aguas brotaron. Corrían como un río en los lugares secos.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Porque se acordó de su santa palabra, y Abraham, su siervo.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Sacó a su pueblo con alegría, su elegido con el canto.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 Les dio las tierras de las naciones. Tomaron el trabajo de los pueblos en posesión,
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 para que cumplan sus estatutos, y observar sus leyes. ¡Alabado sea Yah!
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Salmos 105 >