< Proverbios 11 >

1 Un balance falso es una abominación para Yahvé, pero las pesas precisas son su deleite.
Olúwa kórìíra òsùwọ̀n èké, ṣùgbọ́n òsùwọ̀n òtítọ́ jẹ́ inú dídùn un rẹ̀.
2 Cuando llega el orgullo, llega la vergüenza, pero con la humildad viene la sabiduría.
Nígbà tí ìgbéraga bá dé, nígbà náà ni ìdójútì dé, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìrẹ̀lẹ̀ ni ọgbọ́n ń wá.
3 La integridad de los rectos los guiará, pero la perversidad de los traidores los destruirá.
Òtítọ́ inú ẹni dídúró ṣinṣin ń ṣe amọ̀nà rẹ̀, ṣùgbọ́n aláìṣòótọ́ yóò parun nípasẹ̀ àìṣòótọ́ wọn.
4 Las riquezas no aprovechan en el día de la ira, pero la justicia libra de la muerte.
Ọ̀rọ̀ kò níláárí ní ọjọ́ ìbínú, ṣùgbọ́n òdodo a máa gbani lọ́wọ́ ikú.
5 La justicia del intachable dirigirá su camino, pero el impío caerá por su propia maldad.
Òdodo aláìlẹ́gàn ṣe ọ̀nà tààrà fún wọn, ṣùgbọ́n ìwà búburú ènìyàn búburú yóò fà á lulẹ̀.
6 La justicia de los rectos los librará, pero los infieles quedarán atrapados por los malos deseos.
Òdodo ẹni ìdúró ṣinṣin gbà wọ́n là, ṣùgbọ́n ìdẹ̀kùn ètè búburú mú aláìṣòótọ́.
7 Cuando un malvado muere, la esperanza perece, y la expectativa de poder se queda en nada.
Nígbà tí ènìyàn búburú bá kú, ìrètí rẹ̀ a parun; gbogbo ohun tó ń fojú ṣọ́nà fún nípa agbára rẹ̀ já ṣófo.
8 El justo es liberado de la angustia, y el malvado ocupa su lugar.
A gba olódodo kúrò lọ́wọ́ ibi dípò o rẹ̀, ibi wá sórí ènìyàn búburú.
9 Con su boca el impío destruye a su prójimo, pero los justos serán liberados a través del conocimiento.
Aláìmọ Ọlọ́run fi ẹnu rẹ̀ ba aládùúgbò rẹ̀ jẹ́, ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ìmọ̀ olódodo sá àsálà.
10 Cuando le va bien al justo, la ciudad se alegra. Cuando los malvados perecen, hay gritos.
Nígbà tí olódodo ń gbèrú, ìlú a yọ̀; nígbà tí ènìyàn búburú parun, ariwo ayọ̀ gba ìlú kan.
11 Por la bendición de los rectos, la ciudad es exaltada, pero es derribado por la boca de los malvados.
Nípasẹ̀ ìbùkún, olódodo a gbé ìlú ga: ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ẹnu ènìyàn búburú, a pa ìlú run.
12 El que desprecia a su prójimo está vacío de sabiduría, pero un hombre comprensivo mantiene su paz.
Ẹni tí kò gbọ́n fojú kékeré wo aládùúgbò rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó ní òye pa ẹnu rẹ̀ mọ́.
13 El que trae chismes traiciona una confianza, pero el que tiene un espíritu de confianza es el que guarda un secreto.
Olófòófó tú àṣírí ìkọ̀kọ̀ ṣùgbọ́n ẹni tó ṣe é gbẹ́kẹ̀lé a pa àṣírí mọ́.
14 Donde no hay una guía sabia, la nación cae, pero en la multitud de consejeros está la victoria.
Nítorí àìní ìtọ́sọ́nà orílẹ̀-èdè ṣubú ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn ìṣẹ́gun dájú.
15 El que es garante de un extraño sufrirá por ello, pero el que rechaza las prendas de garantía está seguro.
Ẹni tí ó ṣe onígbọ̀wọ́ fún àlejò yóò rí ìyọnu, ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó kọ̀ láti ṣe onígbọ̀wọ́ yóò wà láìléwu.
16 Una mujer con gracia obtiene honor, pero los hombres violentos obtienen riquezas.
Obìnrin oníwà rere gba ìyìn ṣùgbọ́n alágbára aláìbìkítà ènìyàn gba ọrọ̀ nìkan.
17 El hombre misericordioso hace el bien a su propia alma, pero el que es cruel molesta a su propia carne.
Ènìyàn rere ń ṣe ara rẹ̀ lóore ṣùgbọ́n ènìyàn ìkà ń mú ìyọnu wá sórí ara rẹ̀.
18 Los malvados ganan sueldos engañosos, pero el que siembra justicia cosecha una recompensa segura.
Ènìyàn búburú gba èrè ìtànjẹ ṣùgbọ́n ẹni tó fúnrúgbìn òdodo yóò gba èrè tó dájú.
19 El que es verdaderamente justo obtiene la vida. El que persigue el mal obtiene la muerte.
Olódodo tòótọ́ rí ìyè ṣùgbọ́n ẹni tí ń lépa ibi lé e sí ibi ikú ara rẹ̀.
20 Los perversos de corazón son una abominación para Yahvé, pero aquellos cuyos caminos son intachables son su deleite.
Olúwa kórìíra àwọn ènìyàn ọlọ́kàn búburú ṣùgbọ́n ó ní inú dídùn sí àwọn tí ọ̀nà wọn kò lábùkù.
21 Ciertamente, el hombre malo no quedará impune, pero la descendencia de los justos será liberada.
Mọ èyí dájú pé, ènìyàn búburú kì yóò lọ láìjìyà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo yóò lọ láìjìyà.
22 Como un anillo de oro en el hocico de un cerdo, es una hermosa mujer que carece de discreción.
Bí òrùka wúrà ní imú ẹlẹ́dẹ̀ ni arẹwà obìnrin tí kò lọ́gbọ́n.
23 El deseo de los justos es sólo bueno. La expectativa de los malvados es la ira.
Ìfẹ́ inú olódodo yóò yọrí sí ohun rere ṣùgbọ́n ìrètí ènìyàn búburú yóò yọrí sí ìbínú.
24 Hay uno que dispersa y aumenta aún más. Hay uno que retiene más de lo debido, pero gana la pobreza.
Ènìyàn kan ń fún ni lọ́fẹ̀ẹ́, síbẹ̀ ó ń ní sí i; òmíràn ń háwọ́ ju bí ó ti yẹ ṣùgbọ́n ó di aláìní.
25 El alma liberal será engordada. El que riega será también regado.
Ẹni tí ń ṣoore yóò máa gbèrú sí i; ẹni tí ó tu ẹlòmíràn lára yóò ní ìtura.
26 La gente maldice a quien retiene el grano, pero la bendición caerá sobre la cabeza de quien lo venda.
Àwọn ènìyàn a ṣẹ́ èpè lé ènìyàn tí ń kó oúnjẹ pamọ́ ṣùgbọ́n ìbùkún a máa wá sórí ẹni tí ó ṣetán láti tà.
27 El que busca diligentemente el bien, busca el favor, pero el que busca el mal, éste vendrá a él.
Ẹni tí ń lépa ohun rere yóò rí ohun rere ṣùgbọ́n ibi yóò dé bá ẹni tí ń lépa ibi.
28 El que confía en sus riquezas caerá, pero el justo florecerá como la hoja verde.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ rẹ̀ yóò ṣubú; ṣùgbọ́n olódodo yóò gbilẹ̀ bí i koríko tútù.
29 El que molesta a su propia casa heredará el viento. El necio servirá al sabio de corazón.
Ẹni tí ó ń mú ìdààmú dé bá ìdílé rẹ̀ yóò jogún afẹ́fẹ́ lásán aláìgbọ́n yóò sì máa ṣe ìránṣẹ́ fún ọlọ́gbọ́n.
30 El fruto del justo es un árbol de vida. El que es sabio gana almas.
Èso òdodo ni igi ìyè ẹni tí ó sì jèrè ọkàn jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
31 He aquí que los justos serán recompensados en la tierra, ¡cuanto más el malvado y el pecador!
Bí àwọn olódodo bá gba ìpín wọn lórí ilẹ̀ ayé mélòó mélòó ni ènìyàn búburú àti àwọn tó dẹ́ṣẹ̀!

< Proverbios 11 >