< Nehemías 10 >
1 Los que sellaron fueron: Nehemías, el gobernador, hijo de Hacalías, y Sedequías,
Àwọn tí ó fi èdìdì dì í ni: Nehemiah baálẹ̀, ọmọ Hakaliah. Sedekiah
2 Seraías, Azarías, Jeremías,
Seraiah, Asariah, Jeremiah,
3 Pashur, Amarías, Malquías,
Paṣuri, Amariah, Malkiah,
4 Hattush, Sebanías, Malluch,
Hattusi, Ṣebaniah, Malluki,
5 Harim, Meremot, Abdías,
Harimu, Meremoti, Obadiah,
6 Daniel, Ginetón, Baruc,
Daniẹli, Ginetoni, Baruku,
7 Mesulam, Abías, Mijamín,
Meṣullamu, Abijah, Mijamini,
8 Maazías, Bilgai y Semaías. Estos eran los sacerdotes.
Maasiah, Bilgai àti Ṣemaiah. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà.
9 Los levitas: Jesúa hijo de Azanías, Binúi de los hijos de Henadad, Cadmiel;
Àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua ọmọ Asaniah, Binnui ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Henadadi, Kadmieli,
10 y sus hermanos, Sebanías, Hodías, Kelita, Pelaías, Hanán,
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn: Ṣebaniah, Hodiah, Kelita, Pelaiah, Hanani,
11 Mica, Rehob, Hasabías,
Mika, Rehobu, Haṣabiah,
12 Zaccur, Serebías, Sebanías,
Sakkuri, Ṣerebiah, Ṣebaniah,
13 Hodías, Baní y Beninú.
Hodiah, Bani àti Beninu.
14 Los jefes del pueblo: Parosh, Pahathmoab, Elam, Zattu, Bani,
Àwọn olórí àwọn ènìyàn: Paroṣi, Pahati-Moabu, Elamu, Sattu, Bani,
16 Adonías, Bigvai, Adin,
Adonijah, Bigfai, Adini,
17 Ater, Ezequías, Azzur,
Ateri, Hesekiah, Assuri,
18 Hodías, Hashum, Bezai,
Hodiah, Haṣumu, Besai,
19 Hariph, Anathoth, Nobai,
Harifu, Anatoti, Nebai,
20 Magpiash, Meshullam, Hezir,
Magpiaṣi, Meṣullamu, Hesiri
21 Meshezabel, Zadok, Jaddua,
Meṣesabeli, Sadoku, Jaddua
22 Pelatiah, Hanan, Anaiah,
Pelatiah, Hanani, Anaiah,
23 Hoshea, Hananiah, Hasshub,
Hosea, Hananiah, Haṣubu,
24 Hallohesh, Pilha, Shobek,
Halloheṣi, Pileha, Ṣobeki,
25 Rehum, Hashabnah, Maaseiah,
Rehumu, Haṣabna, Maaseiah,
27 Malluch, Harim y Baanah.
Malluki, Harimu, àti Baanah.
28 El resto del pueblo, los sacerdotes, los levitas, los porteros, los cantores, los servidores del templo, y todos los que se habían apartado de los pueblos de las tierras a la ley de Dios, sus esposas, sus hijos y sus hijas — todos los que tenían conocimiento y entendimiento —
“Àwọn ènìyàn tókù—àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn aṣọ́nà, àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti gbogbo àwọn tí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ènìyàn àjèjì nítorí òfin Ọlọ́run, papọ̀ pẹ̀lú ìyàwó wọn, gbogbo ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, tí òye yé
29 se unieron a sus hermanos sus nobles, y entraron en una maldición y en un juramento, para andar en la ley de Dios, que fue dada por Moisés el siervo de Dios, y para observar y hacer todos los mandamientos de Yahvé nuestro Señor, y sus ordenanzas y sus estatutos;
gbogbo wọn fi ara mọ́ àwọn arákùnrin wọn, àwọn ọlọ́lá, wọ́n sì fi ègún àti ìbúra dé ara wọn láti máa tẹ̀lé òfin Ọlọ́run tí a fi fún wọn ní ipasẹ̀ Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti láti pa gbogbo àṣẹ, ìlànà àti òfin Olúwa, wa mọ́ dáradára.
30 y que no daríamos nuestras hijas a los pueblos de la tierra, ni tomaríamos sus hijas para nuestros hijos;
“A ti ṣe ìlérí pé, a kò ní fi àwọn ọmọbìnrin wa fún àwọn tí wọ́n wà ní àyíká wa bí ìyàwó, tàbí fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin wa.
31 y que si los pueblos de la tierra trajeran mercancías o algún grano en el día de reposo para vender, no les compraríamos en el día de reposo, ni en un día santo; y que renunciaríamos a las cosechas del séptimo año y a la exacción de toda deuda.
“Nígbà tí àwọn ènìyàn àdúgbò bá mú ọjà tàbí oúnjẹ wá ní ọjọ́ ìsinmi láti tà, àwa kò ní rà á ní ọwọ́ wọn ní ọjọ́ ìsinmi tàbí ní ọjọ́ mímọ́ kankan. Ní gbogbo ọdún keje àwa kò ní ro ilẹ̀ náà, a ó sì pa gbogbo àwọn gbèsè rẹ́.
32 Además, nos hemos impuesto la obligación de cobrar anualmente la tercera parte de un siclo para el servicio de la casa de nuestro Dios:
“Àwa gbà ojúṣe láti máa pa àṣẹ mọ́ pé, a ó máa san ìdámẹ́ta ṣékélì ní ọdọọdún fún iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa:
33 para el pan de la proposición, para la ofrenda continua, para el holocausto continuo, para los sábados, para las lunas nuevas, para las fiestas, para las cosas santas, para las ofrendas por el pecado para hacer expiación por Israel, y para toda la obra de la casa de nuestro Dios.
nítorí oúnjẹ tí ó wà lórí tábìlì; nítorí ọrẹ ohun jíjẹ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo; nítorí ọrẹ ọjọ́ ìsinmi, ti àyajọ́ oṣù tuntun àti àjọ̀dún tí a yàn; nítorí ọrẹ mímọ́; nítorí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣe ètùtù fún Israẹli; àti fún gbogbo iṣẹ́ ilé Ọlọ́run wa.
34 Nosotros, los sacerdotes, los levitas y el pueblo, echamos suertes sobre la ofrenda de leña, para traerla a la casa de nuestro Dios, según las casas de nuestros padres, en los tiempos señalados de año en año, para quemarla en el altar de Yahvé nuestro Dios, como está escrito en la ley;
“Àwa, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi àti àwọn ènìyàn náà ti dìbò láti pinnu ìgbà tí olúkúlùkù àwọn ìdílé yóò mú ọrẹ igi wá láti sun lọ́ríi pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa sí ilé Ọlọ́run wa, ní àkókò tí a yàn ní ọdọọdún. Gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin.
35 y para traer las primicias de nuestra tierra y las primicias de todos los frutos de toda clase de árboles, de año en año, a la casa de Yahvé;
“Àwa tún gbà ojúṣe láti mú àkọ́so àwọn èso wa wá àti gbogbo èso igi wá ní ilé Olúwa.
36 también los primogénitos de nuestros hijos y de nuestros ganados, como está escrito en la ley, y los primogénitos de nuestras vacas y de nuestros rebaños, para llevarlos a la casa de nuestro Dios, a los sacerdotes que sirven en la casa de nuestro Dios
“Gẹ́gẹ́ bí a sì ti kọ ọ́ sínú ìwé òfin, àwa yóò mú àkọ́bí àwọn ọmọkùnrin wa, ti ohun ọ̀sìn wa, ti àwọn abo màlúù àti ti àwọn àgùntàn wa, wá sí ilé Ọlọ́run wa, fún àwọn àlùfáà tí ń ṣiṣẹ́ níbẹ̀.
37 y que traigamos las primicias de nuestra masa, nuestras ofrendas de ondas, el fruto de toda clase de árboles, el vino nuevo y el aceite, a los sacerdotes, a las salas de la casa de nuestro Dios; y los diezmos de nuestra tierra a los levitas; porque ellos, los levitas, toman los diezmos en todas nuestras aldeas agrícolas.
“Síwájú sí i, àwa yóò mú àkọ́so oúnjẹ ilẹ̀ wa ti ọrẹ oúnjẹ, ti gbogbo èso àwọn igi àti ti wáìnì tuntun wa àti ti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ilé Ọlọ́run wa àti fún àwọn àlùfáà. Àwa yóò sì mú ìdámẹ́wàá ohun ọ̀gbìn wá fún àwọn ọmọ Lefi, nítorí àwọn ọmọ Lefi ni ó ń gba ìdámẹ́wàá ní gbogbo àwọn ìlú tí a ti ń ṣiṣẹ́.
38 El sacerdote, descendiente de Aarón, estará con los levitas cuando éstos tomen los diezmos. Los levitas llevarán el diezmo de los diezmos a la casa de nuestro Dios, a las habitaciones, a la casa del tesoro.
Àlùfáà tí o ti ìdílé Aaroni wá ni yóò wá pẹ̀lú àwọn ọmọ Lefi nígbà tí wọ́n bá ń gba ìdámẹ́wàá, àwọn ọmọ Lefi yóò sì mú ìdámẹ́wàá ti ìdámẹ́wàá náà wá sí ilé Ọlọ́run, sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí inú ilé ìṣúra.
39 Porque los hijos de Israel y los hijos de Leví llevarán la ofrenda mecida del grano, del vino nuevo y del aceite, a las habitaciones donde están los utensilios del santuario y los sacerdotes que ministran, con los porteros y los cantores. No abandonaremos la casa de nuestro Dios.
Àwọn ènìyàn Israẹli, àti àwọn ọmọ Lefi gbọdọ̀ mú ọrẹ oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró wá sí yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí níbi tí a pa ohun èlò ibi mímọ́ mọ́ sí àti ibi tí àwọn àlùfáà tí ń ṣe ìránṣẹ́ lọ́wọ́, àwọn aṣọ́nà àti àwọn akọrin máa ń dúró sí. “Àwa kì yóò gbàgbé tàbí ṣe àìbìkítà nípa ilé Ọlọ́run wa.”