< Josué 18 >

1 Toda la congregación de los hijos de Israel se reunió en Silo y levantó allí la Tienda del Encuentro. La tierra fue sometida ante ellos.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
2 Quedaban siete tribus entre los hijos de Israel, que aún no habían repartido su herencia.
ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
3 Josué dijo a los hijos de Israel: “¿Hasta cuándo dejaréis de entrar a poseer la tierra que el Señor, el Dios de vuestros padres, os ha dado?
Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
4 Designen para ustedes tres hombres de cada tribu. Yo los enviaré, y ellos se levantarán, recorrerán la tierra y la describirán según su herencia; luego vendrán a mí.
Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
5 La dividirán en siete porciones. Judá vivirá en sus límites al sur, y la casa de José vivirá en sus límites al norte.
Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
6 Ustedes harán un reconocimiento de la tierra en siete partes, y me traerán la descripción aquí; y yo les echaré suertes aquí, delante de Yahvé, nuestro Dios.
Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
7 Sin embargo, los levitas no tienen parte entre ustedes, pues el sacerdocio de Yahvé es su herencia. Gad, Rubén y la media tribu de Manasés han recibido su herencia al este del Jordán, que les dio Moisés, siervo de Yahvé.”
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
8 Los hombres se levantaron y se fueron. Josué ordenó a los que fueron a reconocer la tierra, diciendo: “Vayan a recorrer la tierra, a reconocerla, y vuelvan a mí. Yo les echaré suertes aquí, ante Yahvé, en Silo”.
Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
9 Los hombres recorrieron la tierra, y la inspeccionaron por ciudades en siete porciones en un libro. Llegaron a Josué al campamento de Silo.
Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
10 Josué les echó suertes en Silo ante el Señor. Allí Josué repartió la tierra a los hijos de Israel según sus divisiones.
Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
11 La suerte de la tribu de los hijos de Benjamín salió según sus familias. El límite de su suerte salió entre los hijos de Judá y los hijos de José.
Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
12 Su límite en la parte norte era desde el Jordán. La frontera llegaba hasta el lado de Jericó, al norte, y subía por la región montañosa hacia el oeste. Terminaba en el desierto de Bet-Aven.
Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
13 La frontera pasaba desde allí hasta Luz, al lado de Luz (también llamada Betel), hacia el sur. La frontera bajaba hasta Atarot Addar, junto al monte que está al sur de Bet Horón el de abajo.
Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
14 La frontera se extendía y daba la vuelta por el barrio occidental hacia el sur, desde el monte que está frente a Bet Horón hacia el sur, y terminaba en Quiriat Baal (también llamada Quiriat Jearim), ciudad de los hijos de Judá. Este era el barrio oeste.
Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
15 El barrio sur se extendía desde la parte más lejana de Quiriat Jearim. La frontera salía hacia el oeste y llegaba hasta el manantial de las aguas de Neftoa.
Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
16 El límite descendía hasta la parte más lejana del monte que está frente al valle del hijo de Hinom, que está en el valle de Refaim hacia el norte. Bajaba hasta el valle de Hinom, al lado del jebuseo hacia el sur, y descendía hasta En Rogel.
Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
17 Se extendía hacia el norte, salía a En Shemesh y salía a Geliloth, que está frente a la subida de Adummim. Bajaba hasta la piedra de Bohán, hijo de Rubén.
Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
18 Pasaba por el lado opuesto al Arabá, hacia el norte, y bajaba hasta el Arabá.
Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
19 La frontera pasaba por el lado de Bet Hogá hacia el norte, y terminaba en la bahía norte del Mar Salado, en el extremo sur del Jordán. Esta era la frontera sur.
Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
20 El Jordán era su frontera por la parte oriental. Esta era la herencia de los hijos de Benjamín, por los límites que la rodeaban, según sus familias.
Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
21 Las ciudades de la tribu de los hijos de Benjamín, según sus familias, eran Jericó, Bet Hoglah, Emek Keziz,
Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
22 Bet Araba, Zemaraim, Betel,
Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
23 Avvim, Pará, Ofra,
Affimu, Para, Ofira
24 Chefar Ammoni, Ofni y Geba; doce ciudades con sus aldeas.
Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
25 Gabaón, Ramá, Beerot,
Gibeoni, Rama, Beeroti,
26 Mizpá, Quifira, Moza,
Mispa, Kefira, Mosa,
27 Rekem, Irpeel, Taralá,
Rekemu, Irpeeli, Tarala,
28 Zelá, Elef, la Jebusita (también llamada Jerusalén), Gibeat y Quiriat; catorce ciudades con sus aldeas. Esta es la herencia de los hijos de Benjamín según sus familias.
Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.

< Josué 18 >