< Josué 15 >

1 La suerte de la tribu de los hijos de Judá, según sus familias, fue hasta el límite de Edom, hasta el desierto de Zin hacia el sur, en el extremo del sur.
Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
2 Su límite sur era desde el extremo del Mar Salado, desde la bahía que mira hacia el sur;
Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
3 y salía hacia el sur de la subida de Akrabbim, y pasaba por Zin, y subía por el sur de Cades Barnea, y pasaba por Esrom, subía por Addar, y se volvía hacia Karka;
ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
4 y pasaba por Azmón, salía por el arroyo de Egipto; y el límite terminaba en el mar. Esta será su frontera sur.
Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
5 El límite oriental era el Mar Salado, hasta el final del Jordán. El límite del norte era desde la bahía del mar hasta el final del Jordán.
Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
6 El límite subía hasta Bet Hogá, y pasaba por el norte de Bet Araba; y el límite subía hasta la piedra de Bohán, hijo de Rubén.
ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
7 La frontera subía hasta Debir desde el valle de Acor, y así hacia el norte, mirando hacia Gilgal, que está frente a la subida de Adummim, que está al lado sur del río. La frontera pasaba hasta las aguas de En Shemesh, y terminaba en En Rogel.
Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
8 La frontera subía por el valle del hijo de Hinom hasta el lado del jebuseo (también llamado Jerusalén) hacia el sur; y la frontera subía hasta la cima del monte que está frente al valle de Hinom hacia el oeste, que está en la parte más lejana del valle de Refaim hacia el norte.
Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
9 La frontera se extendía desde la cima del monte hasta el manantial de las aguas de Neftoa, y salía a las ciudades del monte Efrón; y la frontera se extendía hasta Baalá (también llamada Quiriat Jearim);
Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
10 y la frontera giraba desde Baalá hacia el oeste, hacia el monte Seir, y pasaba al lado del monte Jearim (también llamado Cesalón), al norte, y bajaba a Bet Semes, y pasaba junto a Timná;
Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
11 y la frontera salía al lado de Ecrón hacia el norte; y la frontera se extendía hasta Siquerón, y pasaba por el monte Baalá, y salía por Jabneel; y las salidas de la frontera estaban en el mar.
Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
12 El límite occidental llegaba hasta la orilla del gran mar. Esta es la frontera de los hijos de Judá según sus familias.
Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
13 Le dio a Caleb, hijo de Jefone, una porción entre los hijos de Judá, según el mandato de Yahvé a Josué, hasta Quiriat Arba, llamada así por el padre de Anac (también llamada Hebrón).
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
14 Caleb expulsó a los tres hijos de Anac Sesai, Ahiman y Talmai, hijos de Anac.
Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
15 Subió contra los habitantes de Debir, que antes se llamaba Kiriath Sepher.
Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
16 Caleb dijo: “Al que ataque a Quiriat-Sfer y lo tome, le daré a mi hija Acsa como esposa”.
Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
17 La tomó Othniel, hijo de Kenaz, hermano de Caleb, y le dio a Acsa, su hija, como esposa.
Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
18 Cuando ella llegó, le hizo pedir a su padre un campo. Ella se bajó del asno, y Caleb le dijo: “¿Qué quieres?”
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
19 Ella dijo: “Dame una bendición. Ya que me has puesto en la tierra del Sur, dame también manantiales de agua”. Así que le dio los muelles superiores y los inferiores.
Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
20 Esta es la herencia de la tribu de los hijos de Judá según sus familias.
Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
21 Las ciudades más lejanas de la tribu de los hijos de Judá hacia la frontera de Edom, en el sur, fueron Kabzeel, Eder, Jagur,
Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
22 Kinah, Dimonah, Adadah,
Kina, Dimona, Adada,
23 Kedesh, Hazor, Ithnan,
Kedeṣi, Hasori, Itina,
24 Ziph, Telem, Bealoth,
Sifi, Telemu, Bealoti,
25 Hazor Hadattah, Kerioth Hezron (también llamada Hazor),
Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
26 Amam, Shema, Moladah,
Amamu, Ṣema, Molada,
27 Hazar Gaddah, Heshmon, Beth Pelet,
Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
28 Hazar Shual, Beersheba, Biziothiah,
Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
29 Baalah, Iim, Ezem,
Baalahi, Limu, Esemu,
30 Eltolad, Chesil, Hormah,
Eltoladi, Kesili, Horma,
31 Ziklag, Madmannah, Sansannah,
Siklagi, Madmana, Sansanna,
32 Lebaoth, Shilhim, Ain y Rimmon. Todas las ciudades son veintinueve, con sus aldeas.
Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
33 En la tierra baja, Eshtaol, Zorah, Ashnah,
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
34 Zanoah, En Gannim, Tappuah, Enam,
Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
35 Jarmuth, Adullam, Socoh, Azekah,
Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
36 Shaaraim, Adithaim y Gederah (o Gederothaim); catorce ciudades con sus aldeas.
Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
37 Zenan, Hadashah, Migdal Gad,
Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
38 Dilean, Mizpa, Joktheel,
Dileani, Mispa, Jokteeli,
39 Lachish, Bozkath, Eglon,
Lakiṣi, Boskati, Egloni,
40 Cabbon, Lahmam, Chitlish,
Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
41 Gederoth, Beth Dagon, Naamah, y Makkedah; dieciséis ciudades con sus aldeas.
Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
42 Libná, Éter, Asán,
Libina, Eteri, Aṣani,
43 Ifá, Asná, Nezib,
Hifita, Aṣna, Nesibu,
44 Keilá, Achzib y Maresá; nueve ciudades con sus aldeas.
Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
45 Ecrón, con sus ciudades y sus aldeas;
Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
46 desde Ecrón hasta el mar, todos los que estaban junto a Asdod, con sus aldeas.
ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
47 Asdod, sus ciudades y sus aldeas; Gaza, sus ciudades y sus aldeas; hasta el arroyo de Egipto, y el gran mar con su costa.
Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
48 En la región de las colinas, Shamir, Jattir, Socoh,
Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
49 Dannah, Kiriath Sannah (que es Debir),
Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
50 Anab, Eshtemoh, Anim,
Anabu, Eṣitemo, Animu,
51 Goshen, Holon y Giloh; once ciudades con sus aldeas.
Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
52 Arab, Dumah, Eshan,
Arabu, Duma, Eṣani,
53 Janim, Beth Tappuah, Aphekah,
Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
54 Humtah, Kiriath Arba (también llamada Hebrón) y Zior; nueve ciudades con sus aldeas.
Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
55 Maón, Carmelo, Zif, Jutah,
Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
56 Jezreel, Jocdeam, Zanoa,
Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
57 Caín, Guibeá y Timná; diez ciudades con sus aldeas.
Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
58 Halhul, Beth Zur, Gedor,
Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
59 Maarath, Beth Anoth y Eltekon; seis ciudades con sus aldeas.
Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
60 Kiriath Baal (también llamada Kiriath Jearim), y Rabbah; dos ciudades con sus aldeas.
Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
61 En el desierto, Bet Araba, Middin, Secacah,
Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
62 Nibshan, la Ciudad de la Sal y En Gedi; seis ciudades con sus aldeas.
Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
63 En cuanto a los jebuseos, habitantes de Jerusalén, los hijos de Judá no pudieron expulsarlos; pero los jebuseos viven con los hijos de Judá en Jerusalén hasta el día de hoy.
Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.

< Josué 15 >