< Josué 13 >

1 Josué era ya viejo y de edad avanzada. Yahvé le dijo: “Eres viejo y avanzado en años, y aún queda mucha tierra por poseer.
Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
2 “Esta es la tierra que aún queda todas las regiones de los filisteos, y todos los guesuritas;
“Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
3 desde el Shihor, que está delante de Egipto, hasta la frontera de Ecrón hacia el norte, que se cuenta como cananea; los cinco señores de los filisteos: los gazitas, los asdoditas, los ascalonitas, los gittitas y los ecronitas; también los avvim,
láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
4 al sur; toda la tierra de los cananeos, y Meará que pertenece a los sidonios, hasta Afec, hasta la frontera de los amorreos;
láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
5 y la tierra de los gebalitas, y todo el Líbano, hacia la salida del sol, desde Baal Gad bajo el monte Hermón hasta la entrada de Hamat;
àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
6 todos los habitantes de la región montañosa desde el Líbano hasta Misrefot Maim, todos los sidonios. Los expulsaré de delante de los hijos de Israel. Sólo asigna a Israel como herencia, como te he ordenado.
“Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
7 Ahora, pues, reparte esta tierra en herencia a las nueve tribus y a la media tribu de Manasés.”
pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
8 Con él, los rubenitas y los gaditas recibieron la herencia que les dio Moisés, al otro lado del Jordán, hacia el este, tal como se la dio Moisés, siervo de Yahvé:
Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
9 desde Aroer, que está al borde del valle de Arnón, y la ciudad que está en medio del valle, y toda la llanura de Medeba hasta Dibón;
Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
10 y todas las ciudades de Sehón, rey de los amorreos, que reinaba en Hesbón, hasta el límite de los hijos de Amón
Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
11 y Galaad, y el límite de los guesuritas y maacatitas, y todo el monte Hermón, y todo Basán hasta Salecá;
Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
12 todo el reino de Og en Basán, que reinaba en Astarot y en Edrei (que quedó del resto de los refaítas); porque Moisés atacó a éstos y los expulsó.
ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
13 Sin embargo, los hijos de Israel no expulsaron a los guesuritas ni a los maacatíes, sino que Guesur y Maacat viven dentro de Israel hasta el día de hoy.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
14 Sólo que no dio herencia a la tribu de Leví. Las ofrendas a Yahvé, el Dios de Israel, hechas por fuego, son su herencia, como él le dijo.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
15 Moisés dio a la tribu de los hijos de Rubén según sus familias.
Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
16 Su frontera fue desde Aroer, que está a la orilla del valle de Arnón, y la ciudad que está en medio del valle, y toda la llanura junto a Medeba;
láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
17 Hesbón, y todas sus ciudades que están en la llanura; Dibón, Bamoth Baal, Beth Baal Meón,
sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
18 Jahaz, Kedemoth, Mephaath,
Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
19 Kiriathaim, Sibmah, Zereth Shahar en el monte del valle,
Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
20 Beth Peor, las laderas de Pisga, Beth Jeshimoth,
Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
21 todas las ciudades de la llanura, y todo el reino de Sehón, rey de los amorreos, que reinaba en Hesbón, a quien Moisés hirió con los jefes de Madián, Evi, Rekem, Zur, Hur y Reba, príncipes de Sehón, que vivían en la tierra.
gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
22 Los hijos de Israel también mataron a espada a Balaam, hijo de Beor, el adivino, entre el resto de sus muertos.
Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
23 El límite de los hijos de Rubén era la ribera del Jordán. Esta fue la herencia de los hijos de Rubén según sus familias, las ciudades y sus aldeas.
Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
24 Moisés dio a la tribu de Gad, a los hijos de Gad, según sus familias.
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
25 Su límite fue Jazer, y todas las ciudades de Galaad, y la mitad de la tierra de los hijos de Amón, hasta Aroer que está cerca de Rabá;
Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
26 y desde Hesbón hasta Ramat Mizpa, y Betonim; y desde Mahanaim hasta el límite de Debir
àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
27 y en el valle, Bet Haram, Bet Nimra, Sucot y Zafón, el resto del reino de Sehón, rey de Hesbón, la ribera del Jordán, hasta el extremo del mar de Cineret, al otro lado del Jordán, hacia el este.
àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
28 Esta es la herencia de los hijos de Gad según sus familias, las ciudades y sus aldeas.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
29 Moisés dio una herencia a la media tribu de Manasés. Fue para la media tribu de los hijos de Manasés según sus familias.
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
30 Su frontera era desde Mahanaim, todo Basán, todo el reino de Og, rey de Basán, y todas las aldeas de Jair, que están en Basán, sesenta ciudades.
Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
31 La mitad de Galaad, Astarot y Edrei, ciudades del reino de Og en Basán, eran para los hijos de Maquir hijo de Manasés, para la mitad de los hijos de Maquir según sus familias.
ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
32 Estas son las herencias que Moisés repartió en las llanuras de Moab, al otro lado del Jordán, en Jericó, hacia el este.
Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
33 Pero Moisés no dio ninguna herencia a la tribu de Leví. Yahvé, el Dios de Israel, es su herencia, como él les habló.
Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.

< Josué 13 >