< Job 12 >

1 Entonces Job respondió,
Jobu sì dáhùn, ó sì wí pé,
2 “Sin duda, pero vosotros sois el pueblo, y la sabiduría morirá contigo.
“Kò sí àní àní níbẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni àwọn ènìyàn náà, ọgbọ́n yóò sì kú pẹ̀lú yín!
3 Pero yo también tengo entendimiento como tú; No soy inferior a ti. Sí, ¿quién no sabe cosas como éstas?
Ṣùgbọ́n èmi ní ìyè nínú gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin; èmi kò kéré sí i yín. Àní, ta ni kò mọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí?
4 Soy como uno que es una broma para su vecino, Yo, que invoqué a Dios, y él me respondió. El hombre justo e irreprochable es una broma.
“Èmi dàbí ẹni tí a ń fi ṣe ẹlẹ́yà lọ́dọ̀ aládùúgbò rẹ̀, tí ó ké pe Ọlọ́run, tí ó sì dá a lóhùn, à ń fi olóòtítọ́ ẹni ìdúró ṣinṣin rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà!
5 En el pensamiento del que está tranquilo hay desprecio por la desgracia. Está preparado para los que resbalan con el pie.
Ó rọrùn fún ènìyàn láti fi ìbànújẹ́ ẹlòmíràn ṣe ẹlẹ́yà gẹ́gẹ́ bí ìpín àwọn ẹni tí ẹsẹ̀ wọn ṣetán láti yọ̀.
6 Las tiendas de los ladrones prosperan. Los que provocan a Dios están seguros, que llevan a su dios en sus manos.
Àgọ́ àwọn ìgárá ọlọ́ṣà wá láìní ìbẹ̀rù; àwọn tí ó sì ń mú Ọlọ́run bínú wà láìléwu, àwọn ẹni tí ó sì gbá òrìṣà mú ní ọwọ́ wọn.
7 “Pero pregunta ahora a los animales, y ellos te enseñarán; los pájaros del cielo, y ellos te lo dirán.
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí bí àwọn ẹranko léèrè, wọn o kọ́ ọ ní ẹ̀kọ́, àti ẹyẹ ojú ọ̀run, wọn ó sì sọ fún ọ.
8 O habla con la tierra, y ella te enseñará. Los peces del mar te declararán.
Tàbí ba ilẹ̀ ayé sọ̀rọ̀, yóò sì kọ́ ọ, àwọn ẹja inú òkun yóò sì sọ fún ọ.
9 ¿Quién no sabe que en todos estos, La mano de Yahvé ha hecho esto,
Ta ni kò mọ̀ nínú gbogbo nǹkan wọ̀nyí pé, ọwọ́ Olúwa ni ó ṣe nǹkan yìí?
10 en cuya mano está la vida de todo ser viviente, y el aliento de toda la humanidad?
Ní ọwọ́ ẹni tí ẹ̀mí ohun alààyè gbogbo gbé wà, àti ẹ̀mí gbogbo aráyé.
11 El oído no prueba las palabras, incluso cuando el paladar prueba su comida?
Etí kì í dán ọ̀rọ̀ wò bí tàbí adùn ẹnu kì í sì í tọ́ oúnjẹ rẹ̀ wò bí?
12 Con los ancianos está la sabiduría, en la duración de la comprensión de los días.
Àwọn arúgbó ni ọgbọ́n wà fún, àti nínú gígùn ọjọ́ ni òye.
13 “Con Dios está la sabiduría y la fuerza. Tiene consejo y comprensión.
“Ti Ọlọ́run ni ọgbọ́n àti agbára; òun ló ni ìmọ̀ àti òye.
14 He aquí que se rompe, y no se puede volver a construir. Encarcela a un hombre, y no puede ser liberado.
Kíyèsi i, ó bì wó, a kò sì lè gbe ró mọ́; Ó sé ènìyàn mọ́, kò sì sí ìtúsílẹ̀ kan.
15 He aquí que él retiene las aguas, y se secan. Una vez más, los envía, y vuelcan la tierra.
Kíyèsi i, ó dá àwọn omi dúró, wọ́n sì gbẹ; Ó sì rán wọn jáde, wọ́n sì ṣẹ̀ bo ilẹ̀ ayé yípo.
16 Con él está la fuerza y la sabiduría. El engañado y el engañador son suyos.
Tìrẹ ni agbára àti ìṣẹ́gun; ẹni tí ń ṣìnà àti ẹni tí ń mú ni ṣìnà, tirẹ̀ ni wọ́n ń ṣe.
17 Lleva a los consejeros despojados. Hace que los jueces sean tontos.
Ó mú àwọn ìgbìmọ̀ lọ ní ìhòhò a sì sọ àwọn onídàájọ́ di òmùgọ̀.
18 Él desata el vínculo de los reyes. Les ata la cintura con un cinturón.
Ó tú ìdè ọba ó sì fi àmùrè gbà wọ́n ní ọ̀já.
19 Lleva a los sacerdotes despojados, y derroca a los poderosos.
Ó mú àwọn àlùfáà lọ ní ìhòhò ó sì tẹ orí àwọn alágbára ba.
20 Elimina el discurso de los que se confían, y quita la comprensión de los ancianos.
Ó mú ọ̀rọ̀ ẹnu ẹni ìgbẹ́kẹ̀lé kúrò ó sì ra àwọn àgbàgbà ní iyè.
21 Derrama desprecio sobre los príncipes, y afloja el cinturón de los fuertes.
Ó bu ẹ̀gàn lu àwọn ọmọ ọlọ́lá ó sì tú àmùrè àwọn alágbára.
22 Él descubre las cosas profundas de la oscuridad, y saca a la luz la sombra de la muerte.
Ó hú ìdí ohun ìjìnlẹ̀ jáde láti inú òkùnkùn wá ó sì mú òjìji ikú wá sínú ìmọ́lẹ̀.
23 El aumenta las naciones y las destruye. Él engrandece a las naciones, y las lleva cautivas.
Òun a mú orílẹ̀-èdè bí sí i, a sì run wọ́n; òun a sọ orílẹ̀-èdè di ńlá, a sì tún ṣẹ̀ wọn kù.
24 Quita el entendimiento a los jefes de los pueblos de la tierra, y les hace vagar por un desierto donde no hay camino.
Òun a gba òye àwọn olórí àwọn ènìyàn aráyé, a sì máa mú wọn rin kiri nínú ijù níbi tí ọ̀nà kò sí.
25 Andan a tientas en la oscuridad sin luz. Les hace tambalearse como un borracho.
Wọn a máa fi ọwọ́ ta ilẹ̀ nínú òkùnkùn níbi tí kò sí ìmọ́lẹ̀; òun a sì máa mú ìrìn ìsìn wọn bí ọ̀mùtí.

< Job 12 >