< Jeremías 50 >

1 La palabra que Yahvé habló sobre Babilonia, sobre la tierra de los caldeos, por medio del profeta Jeremías.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 “Anunciad entre las naciones y publicad, y establecer una norma; publicar, y no ocultar; dicen, ‘Babilonia ha sido tomada, Bel está decepcionada, ¡Merodach está consternado! Sus imágenes son decepcionantes. Sus ídolos están consternados’.
“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 Porque una nación sube del norte contra ella, que hará que su tierra quede desolada, y nadie habitará en ella. Han huido. Se han ido, tanto del hombre como del animal.
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
4 “En aquellos días y en aquel tiempo”, dice Yahvé, “Los hijos de Israel vendrán, ellos y los hijos de Judá juntos; seguirán su camino llorando, y buscarán a Yahvé, su Dios.
“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
5 Preguntarán por Sión con el rostro vuelto hacia ella, diciendo: “Venid y uníos a Yahvé en un pacto eterno que no será olvidado”.
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
6 Mi pueblo ha sido una oveja perdida. Sus pastores les han hecho extraviarse. Los han rechazado en las montañas. Han pasado de la montaña a la colina. Han olvidado su lugar de descanso.
“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 Todos los que los encontraron los devoraron. Sus adversarios dijeron: ‘No somos culpables’, porque han pecado contra Yahvé, la morada de la justicia, el Señor, la esperanza de sus padres”.
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
8 “¡Huye de en medio de Babilonia! Sal de la tierra de los caldeos, y ser como los machos cabríos ante los rebaños.
“Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
9 Porque, he aquí que voy a suscitar y haz subir contra Babilonia una compañía de grandes naciones del país del norte; y se pondrán en fila contra ella. Se la llevarán de allí. Sus flechas serán como las de un poderoso experto. Ninguno de ellos volverá en vano.
Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
10 Caldea será una presa. Todos los que se aprovechan de ella quedarán satisfechos”, dice Yahvé.
A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
11 “Porque te alegras, porque te alegras, Oh, tú que saqueas mi herencia, porque eres licenciosa como una vaquilla que pisa el grano, y relinchar como caballos fuertes,
“Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 tu madre estará totalmente decepcionada. La que te parió será confundida. He aquí que ella será la más pequeña de las naciones, un desierto, una tierra árida y una zona desértica.
Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 A causa de la ira de Yahvé no será habitada, pero estará totalmente desolada. Todos los que pasen por Babilonia se quedarán asombrados, y sisea en todas sus plagas.
Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
14 Poneos en guardia contra Babilonia por todas partes, a todos los que doblan el arco; disparar contra ella. No escatimes en flechas, porque ha pecado contra Yahvé.
“Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Griten contra ella todos. Se ha sometido a sí misma. Sus baluartes han caído. Sus muros han sido derribados, porque es la venganza de Yahvé. Véngate de ella. Como ella ha hecho, hazle a ella.
Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Corta el sembrador de Babilonia, y el que maneja la hoz en el tiempo de la cosecha. Por miedo a la espada opresora, cada uno de ellos regresará a su propio pueblo, y cada uno huirá a su tierra.
Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
17 “Israel es una oveja cazada. Los leones lo han ahuyentado. Primero, el rey de Asiria lo devoró, y ahora por fin Nabucodonosor, rey de Babilonia, le ha roto los huesos”.
“Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
18 Por eso dice el Señor de los Ejércitos, el Dios de Israel: “He aquí que yo castigaré al rey de Babilonia y a su tierra, como he castigado al rey de Asiria.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 Volveré a llevar a Israel a sus pastos, y se alimentará del Carmelo y del Basán. Su alma será satisfecha en las colinas de Efraín y en Galaad.
Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
20 En aquellos días y en aquel tiempo”, dice Yahvé, “la iniquidad de Israel será buscada, y no habrá ninguno, también los pecados de Judá, y no se encontrarán; porque yo perdonaré a los que deje como remanente.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
21 “Sube contra la tierra de Merathaim, incluso contra ella, y contra los habitantes de Pekod. Maten y destruyan por completo después de ellos”, dice Yahvé, “y haced todo lo que os he mandado.
“Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 Un sonido de batalla está en la tierra, y de gran destrucción.
Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 ¡Cómo se corta y se rompe el martillo de toda la tierra! ¡Cómo se ha convertido Babilonia en una desolación entre las naciones!
Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 Te he tendido una trampa, y tú también estás tomada, Babilonia, y tú no eras consciente. Te han encontrado, y también se ha capturado, porque has luchado contra Yahvé.
Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 Yahvé ha abierto su arsenal, y ha sacado las armas de su indignación; porque el Señor, Yahvé de los Ejércitos, tiene una obra que hacer en la tierra de los caldeos.
Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Vengan contra ella desde la frontera más lejana. Abre sus almacenes. Echadla como si fuera un montón. Destrúyela por completo. Que no quede nada de ella.
Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Mata a todos sus toros. Que vayan al matadero. ¡Ay de ellos! Porque su día ha llegado, el momento de su visita.
Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 Escucha a los que huyen y escapan de la tierra de Babilonia, para anunciar en Sión la venganza de Yahvé, nuestro Dios, la venganza de su templo.
Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
29 “Convoca a los arqueros contra Babilonia, todos los que doblan el arco. Acampa contra ella por todos lados. Que no se le escape nada. Págale de acuerdo a su trabajo. De acuerdo con todo lo que ha hecho, hazle; porque se ha ensoberbecido contra Yahvé, contra el Santo de Israel.
“Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Por eso sus jóvenes caerán en sus calles. Todos sus hombres de guerra serán silenciados en ese día”, dice Yahvé.
Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
31 “He aquí que estoy contra ti, soberbio”, dice el Señor, Yahvé de los Ejércitos; “porque su día ha llegado, la hora en que te visitaré.
“Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 El orgulloso tropezará y caerá, y nadie lo levantará. Encenderé un fuego en sus ciudades, y devorará a todos los que estén a su alrededor”.
Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
33 El Señor de los Ejércitos dice: “Los hijos de Israel y los hijos de Judá están oprimidos juntos. Todos los que los tomaron cautivos los retienen. Se niegan a dejarlos ir.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Su Redentor es fuerte. Yahvé de los Ejércitos es su nombre. Defenderá a fondo su causa, para dar descanso a la tierra, y perturbar a los habitantes de Babilonia.
Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
35 “Una espada está sobre los caldeos”, dice Yahvé, “y sobre los habitantes de Babilonia, en sus príncipes, y en sus sabios.
“Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 Una espada está sobre los fanfarrones, y se convertirán en tontos. Una espada está sobre sus poderosos hombres, y estarán consternados.
Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Una espada está sobre sus caballos, en sus carros, y en todas las personas mixtas que están en medio de ella; y se convertirán en mujeres. Una espada está en sus tesoros, y serán robados.
Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Una sequía está sobre sus aguas, y se secarán; porque es una tierra de imágenes grabadas, y están locos por los ídolos.
Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
39 Por eso los animales salvajes del desierto con los lobos morarán allí. Las avestruces habitarán en ella. Ya no será habitada para siempre, tampoco se vivirá de generación en generación.
“Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Como cuando Dios derribó a Sodoma y Gomorra y a sus ciudades vecinas”, dice Yahvé, “para que ningún hombre habite allí, ni ningún hijo de hombre vivirá en ella.
Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
41 “He aquí que un pueblo viene del norte. Una gran nación y muchos reyes serán levantados desde los confines de la tierra.
“Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Toman el arco y la lanza. Son crueles y no tienen piedad. Su voz ruge como el mar. Van a caballo, todo el mundo se pone en matriz, como un hombre a la batalla, contra ti, hija de Babilonia.
Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 El rey de Babilonia ha oído las noticias de ellos, y sus manos se vuelven débiles. La angustia se ha apoderado de él, dolores como los de una mujer de parto.
Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 He aquí que el enemigo subirá como un león de la espesura del Jordán contra la fuerte morada; porque de repente haré que huyan de ella. Quienquiera que sea elegido, Lo nombraré por encima, porque ¿quién es como yo? ¿Quién me designará una hora? ¿Quién es el pastor que puede estar delante de mí?”
Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
45 Escucha, pues, el consejo de Yahvé que ha tomado contra Babilonia; y sus propósitos que se ha propuesto contra la tierra de los caldeos: Seguramente los arrastrarán, incluso a los pequeños del rebaño. Seguramente hará que su morada quede desolada sobre ellos.
Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
46 La tierra tiembla por el ruido de la toma de Babilonia. El grito se escucha entre las naciones.
Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Jeremías 50 >