< Isaías 46 >

1 Bel se inclina. Nebo se inclina. Sus ídolos son llevados por animales, y en el ganado. Las cosas que llevabas son cargas pesadas, una carga para los cansados.
Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀; àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù. Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di àjàgà sí wọn lọ́rùn, ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
2 Se agachan y se inclinan juntos. No pudieron entregar la carga, pero han ido al cautiverio.
Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀; wọn kò lè gba ẹrù náà, àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
3 “Escúchame, casa de Jacob, y todo el resto de la casa de Israel, que llevan desde su nacimiento, que se han llevado desde el vientre materno.
“Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu, gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli, ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún, tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
4 Hasta la vejez soy yo, y hasta las canas te llevaré. He hecho, y soportaré. Sí, llevaré y entregaré.
Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín, Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró. Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ; Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
5 “¿Con quién me compararás y me considerarás igual? y compararme, como si fuéramos iguales?
“Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba? Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
6 Algunos vierten oro de la bolsa, y pesa la plata en la balanza. Contratan a un orfebre, y lo convierte en un dios. Se caen... sí, adoran.
Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n; wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà, wọn sì tẹríba láti sìn ín.
7 Lo llevan al hombro. Lo llevan y lo colocan en su sitio, y allí se queda. No puede moverse de su sitio. Sí, se le puede gritar, pero no puede responder. No puede salvarle de su problema.
Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n, wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí. Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà. Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn; òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
8 “Recordad esto y mostraos como hombres. Recuérdenlo, transgresores.
“Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ, fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
9 Acuérdate de las cosas antiguas; porque yo soy Dios y no hay otro. Yo soy Dios, y no hay nadie como yo.
Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́; Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn; Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
10 Declaro el fin desde el principio, y de los tiempos antiguos las cosas que aún no se han hecho. Yo digo: Mi consejo se mantendrá, y haré todo lo que me plazca.
Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá. Mo wí pé, Ète mi yóò dúró, àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
11 Llamo a un pájaro voraz del este, el hombre de mi consejo desde un país lejano. Sí, he hablado. Yo también lo llevaré a cabo. Lo he planeado. Yo también lo haré.
Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá; láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ. Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ; èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
12 Escúchame, terco de corazón, ¡que están lejos de la justicia!
Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn, ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
13 Acerco mi justicia. No está lejos, y mi salvación no esperará. Yo concederé la salvación a Sión, mi gloria a Israel.
Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí, kò tilẹ̀ jìnnà rárá; àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró. Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà ògo mi fún Israẹli.

< Isaías 46 >