< Isaías 3 >

1 Porque, he aquí, el Señor, Yahvé de los Ejércitos, quita a Jerusalén y a Judá el suministro y el apoyo, todo el suministro de pan, y todo el suministro de agua;
Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
2 el hombre poderoso, el hombre de la guerra, el juez, el profeta, el adivino, el mayor,
Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
3 el capitán de cincuenta, el hombre honorable, el consejero, el artesano experto, y el inteligente hechicero.
balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
4 Daré muchachos para que sean sus príncipes, y los niños gobernarán sobre ellos.
“Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
5 El pueblo será oprimido, todos por otro, y cada uno por su vecino. El niño se comportará con orgullo frente al anciano, y los malvados contra los honorables.
Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
6 En efecto, un hombre se apoderará de su hermano en la casa de su padre, diciendo, “Tienes ropa, serás nuestro gobernante, y que esta ruina esté bajo tu mano”.
Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
7 En ese día gritará diciendo: “No seré un sanador; porque en mi casa no hay ni pan ni ropa. No me harás gobernante del pueblo”.
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
8 Porque Jerusalén está arruinada y Judá ha caído; porque su lengua y sus acciones son contra Yahvé, para provocar los ojos de su gloria.
Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
9 La mirada de sus rostros atestigua contra ellos. Hacen alarde de su pecado como Sodoma. No lo ocultan. ¡Ay de su alma! Porque ellos mismos han provocado el desastre.
Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
10 Di a los justos que les irá bien, porque comerán el fruto de sus actos.
Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 ¡Ay de los malvados! El desastre está sobre ellos, porque las obras de sus manos les serán devueltas.
Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
12 En cuanto a mi pueblo, los niños son sus opresores, y las mujeres gobiernan sobre ellos. Pueblo mío, los que te dirigen te hacen errar, y destruir el camino de tus senderos.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
13 Yahvé se levanta para contender, y está en pie para juzgar a los pueblos.
Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 El Señor entrará en juicio con los ancianos de su pueblo y sus líderes: “Sois vosotros los que os habéis comido la viña. El botín de los pobres está en vuestras casas.
Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 ¿Qué quieres decir con que aplastas a mi pueblo, y moler la cara de los pobres?” dice el Señor, Yahvé de los Ejércitos.
Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 Además, Yahvé dijo: “Porque las hijas de Sion son arrogantes, y caminan con el cuello extendido y los ojos coquetos, caminando con delicadeza a medida que avanzan, adornos tintineantes en sus pies;
Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 por lo tanto, el Señor hace aparecer llagas en la coronilla de las mujeres de Sión, y Yahvé les dejará el cuero cabelludo calvo”.
Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
18 En aquel día el Señor les quitará la belleza de las tobilleras, las diademas, los collares de media luna,
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
19 los pendientes, los brazaletes, los velos,
gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
20 los tocados, las cadenas de los tobillos, las fajas, los recipientes de perfume, los amuletos,
gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
21 los anillos de sello, los narigueros,
òrùka ọwọ́ àti ti imú,
22 las túnicas finas, las capas, los bolsos,
àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
23 los espejos de mano, los vestidos de lino fino, las diademas y los chales.
dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
24 Sucederá que en lugar de especias dulces, habrá podredumbre; en lugar de un cinturón, una cuerda; en lugar de un pelo bien cuajado, la calvicie; en lugar de una túnica, una vestimenta de arpillera; y la marca en lugar de la belleza.
Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Tus hombres caerán por la espada, y su poderío en la guerra.
Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Suspuertas se lamentarán y llorarán. Será desolada y se sentará en el suelo.
Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.

< Isaías 3 >