< Amós 1 >

1 Las palabras de Amós, que estaba entre los pastores de Tecoa, que vio sobre Israel en los días de Uzías, rey de Judá, y en los días de Jeroboam, hijo de Joás, rey de Israel, dos años antes del terremoto.
Àwọn ọ̀rọ̀ Amosi, ọ̀kan lára àwọn olùṣọ́-àgùntàn Tekoa; ohun tí o rí nípa Israẹli ní ọdún méjì ṣáájú ilẹ̀-rírì, nígbà tí Ussiah ọba Juda àti Jeroboamu ọmọ Jehoaṣi jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Israẹli.
2 Dijo: “Yahvé rugirá desde Sión, y pronuncie su voz desde Jerusalén; y los pastos de los pastores estarán de luto, y la cima del Carmelo se marchitará”.
Ó wí pé, “Olúwa yóò bú jáde láti Sioni, ohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jerusalẹmu wá; ibùgbé àwọn olùṣọ́-àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀, orí òkè Karmeli yóò sì rọ.”
3 Yahvé dice: “Por tres transgresiones de Damasco, sí, por cuatro, No rechazaré su castigo, porque han trillado Galaad con trillos de hierro;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Damasku, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gileadi. Pẹ̀lú ohun èlò irin tí ó ní eyín mímú,
4 pero enviaré fuego a la casa de Hazael, y devorará los palacios de Ben Hadad.
Èmi yóò rán iná sí ilé Hasaeli, èyí ti yóò jó àwọn ààfin Beni-Hadadi run.
5 Romperé la barra de Damasco, y cortar el habitante del valle de Aven, y el que tiene el cetro de la casa del Edén; y el pueblo de Siria irá en cautiverio a Kir,” dice Yahvé.
Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdábùú Damasku; Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní àfonífojì Afeni run àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Beti-Edeni. Àwọn ará a Aramu yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kiri,” ni Olúwa wí.
6 Yahvé dice: “Por tres transgresiones de Gaza, sí, por cuatro, No rechazaré su castigo, porque se llevaron cautiva a toda la comunidad, para entregarlos a Edom;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gasa, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Gẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú, ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbèkùn. Ó sì tà wọ́n fún Edomu,
7 pero enviaré un fuego sobre el muro de Gaza, y devorará sus palacios.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Gasa tí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run.
8 Cortaré al habitante de Asdod, y el que tiene el cetro de Ashkelon; y volveré mi mano contra Ecrón; y el remanente de los filisteos perecerá”. dice el Señor Yahvé.
Èmi yóò ké àwọn olùgbé Aṣdodu kúrò, ti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Aṣkeloni mú. Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ekroni títí tí ìyókù Filistini yóò fi ṣègbé,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Yahvé dice: “Por tres transgresiones de Tiro, sí, por cuatro, No rechazaré su castigo; porque entregaron toda la comunidad a Edom, y no recordaba el pacto entre hermanos;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tire àní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbèkùn fún Edomu. Wọn kò sì náání májẹ̀mú ọbàkan,
10 pero enviaré un fuego sobre el muro de Tiro, y devorará sus palacios”.
Èmi yóò rán iná sí ara odi Tire, tí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”
11 Yahvé dice: “Por tres transgresiones de Edom, sí, por cuatro, No rechazaré su castigo, porque persiguió a su hermano con la espada y desechar toda piedad, y su cólera no cesaba, y guardó su ira para siempre;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Edomu, àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀, Ó sì gbé gbogbo àánú sọnù, ìbínú rẹ̀ sì ń faniya títí, ó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́,
12 pero enviaré un fuego sobre Temán, y devorará los palacios de Bozra”.
Èmi yóò rán iná sí orí Temani, tí yóò jó gbogbo ààfin Bosra run.”
13 Yahvé dice: “Por tres transgresiones de los hijos de Amón, sí, por cuatro, No rechazaré su castigo, porque han desgarrado a las mujeres embarazadas de Galaad, para que puedan ampliar su frontera.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Ammoni, àní mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti la inú àwọn aboyún Gileadi kí wọ́n ba à lè fẹ ilẹ̀ wọn sẹ́yìn.
14 Pero yo encenderé un fuego en el muro de Rabá, y devorará sus palacios, con gritos en el día de la batalla, con una tormenta en el día del torbellino;
Èmi yóò rán iná sí ara odi Rabba èyí tí yóò jó àwọn ààfin rẹ̀ run pẹ̀lú ìhó ayọ̀ ní ọjọ́ ogun, pẹ̀lú ìjì líle ni ọjọ́ àjà.
15 y su rey irán al cautiverio, él y sus príncipes juntos,” dice Yahvé.
Ọba wọn yóò sì lọ sí ìgbèkùn, òun àti àwọn ọmọ-aládé rẹ̀ lápapọ̀,” ni Olúwa wí.

< Amós 1 >