< 1 Samuel 14 >

1 Sucedió un día que Jonatán, hijo de Saúl, dijo al joven que llevaba su armadura: “¡Ven! Vamos a la guarnición de los filisteos que está al otro lado”. Pero no se lo dijo a su padre.
Ní ọjọ́ kan, Jonatani ọmọ Saulu wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Filistini tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.
2 Saúl se quedó en el extremo de Guibeá, bajo el granado que está en Migrón; y la gente que estaba con él era como seiscientos hombres,
Saulu sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gibeah lábẹ́ igi pomegiranate èyí tí ó wà ní Migroni. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
3 incluyendo a Ajías, hijo de Ajitub, hermano de Icabod, hijo de Finehas, hijo de Elí, sacerdote de Yahvé en Silo, que llevaba un efod. El pueblo no sabía que Jonatán se había ido.
lára wọn ni Ahijah, tí ó wọ efodu. Òun ni ọmọ arákùnrin Ikabodu Ahitubu, ọmọ Finehasi, ọmọ Eli, àlùfáà Olúwa ní Ṣilo kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jonatani ti lọ.
4 Entre los pasos por los que Jonatán pretendía pasar a la guarnición de los filisteos, había un peñasco a un lado y otro peñasco al otro lado; el nombre del uno era Bozez, y el del otro Seneh.
Ní ọ̀nà tí Jonatani ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Filistini, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkínní sì ń jẹ́ Bosesi, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sene.
5 Un peñasco se levantaba al norte, frente a Micmas, y el otro al sur, frente a Geba.
Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Mikmasi, èkejì sì wà ní gúúsù ní ìhà Gibeah.
6 Jonatán dijo al joven que llevaba su armadura: “¡Ven! Vamos a la guarnición de estos incircuncisos. Puede ser que Yahvé actúe a nuestro favor, pues no hay freno para que Yahvé salve por muchos o por pocos.”
Jonatani sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlú olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípasẹ̀ púpọ̀ tàbí nípasẹ̀ díẹ̀.”
7 El portador de su armadura le dijo: “Haz todo lo que está en tu corazón. Ve, y he aquí que yo estoy contigo según tu corazón”.
Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀síwájú, Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”
8 Entonces Jonatán dijo: “He aquí que pasaremos a los hombres y nos revelaremos a ellos.
Jonatani sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.
9 Si nos dicen esto: ‘Esperen hasta que lleguemos a ustedes’, nos quedaremos quietos en nuestro lugar y no subiremos a ellos.
Bí wọ́n bá sọ fún wa pé, ‘Ẹ dúró títí àwa yóò fi tọ̀ yín wá,’ àwa yóò dúró sí ibi tí a wà, àwa kì yóò sì gòkè tọ̀ wọ́n lọ.
10 Pero si nos dicen esto: “¡Suban a nosotros!”, entonces subiremos, porque el Señor los ha entregado en nuestra mano. Esta será la señal para nosotros”.
Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá wí pé, ‘Ẹ gòkè tọ̀ wá wá,’ àwa yóò gòkè lọ, nítorí èyí ni yóò jẹ́ àmì fún wa pé Olúwa ti fi wọ́n lé wa lọ́wọ́.”
11 Ambos se revelaron ante la guarnición de los filisteos, y éstos dijeron: “¡Mira que los hebreos salen de los agujeros donde se habían escondido!”
Báyìí ní àwọn méjèèjì sì fi ara wọn hàn fún ìlú olódi Filistini. Àwọn Filistini sì wí pé, “Wò ó! Àwọn Heberu ń yọ jáde wá láti inú ihò tí wọ́n fi ara wọn pamọ́ sí.”
12 Los hombres de la guarnición respondieron a Jonatán y a su portador de armadura y les dijeron: “¡Suban a nosotros y les mostraremos algo!” Jonatán dijo a su portador de armadura: “Sube detrás de mí, porque Yahvé los ha entregado en manos de Israel”.
Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.” Jonatani sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́.”
13 Jonatán subió sobre sus manos y sus pies, y su escudero tras él, y ellos cayeron ante Jonatán; y su escudero los mató tras él.
Jonatani lo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Filistini sì ṣubú níwájú Jonatani ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
14 Aquella primera matanza que hicieron Jonatán y su portador de armadura fue de unos veinte hombres, dentro de la longitud de medio surco en un acre de tierra.
Ní ìkọlù èkínní yìí, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbègbè tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sáré ilẹ̀.
15 Hubo un temblor en el campamento, en el campo y en todo el pueblo; la guarnición y los asaltantes también temblaron, y la tierra se estremeció, por lo que hubo un temblor sumamente grande.
Nígbà náà ni ìbẹ̀rùbojo bá àwọn ọmọ-ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
16 Los centinelas de Saúl en Gabaa de Benjamín miraron, y he aquí que la multitud se desvaneció y se dispersó.
Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Saulu ní Gibeah ti Benjamini sì rí àwọn ọmọ-ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.
17 Entonces Saúl dijo al pueblo que estaba con él: “Contad ahora y ved quién falta de nosotros.” Cuando hubieron contado, he aquí que Jonatán y su portador de armadura no estaban allí.
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ ka àwọn ènìyàn kí ẹ sì mọ ẹni tí ó jáde kúrò nínú wa.” Nígbà tí wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, sì wò ó, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ni kò sì sí níbẹ̀.
18 Saúl dijo a Ahías: “Trae aquí el arca de Dios”. Pues el arca de Dios estaba con los hijos de Israel en ese momento.
Saulu sì wí fún Ahijah pé, “Gbé àpótí Ọlọ́run wá.” Àpótí Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní ìgbà náà.
19 Mientras Saúl hablaba con el sacerdote, el tumulto que había en el campamento de los filisteos continuaba y aumentaba, y Saúl le dijo al sacerdote: “¡Retírate!”
Nígbà tí Saulu sì ń bá àlùfáà sọ̀rọ̀, ariwo ní ibùdó àwọn Filistini sì ń pọ̀ síwájú sí. Saulu sì wí fún àlùfáà pé, “Dá ọwọ́ rẹ dúró.”
20 Saúl y todo el pueblo que estaba con él se reunieron y vinieron a la batalla; y he aquí que todos se golpeaban con sus espadas en una gran confusión.
Saulu àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ sì péjọ, wọ́n sì lọ sí ojú ìjà. Wọ́n sì bá gbogbo àwọn Filistini ní ìdàrúdàpọ̀ ńlá, idà olúkúlùkù sì wà lára ọmọ ẹnìkejì rẹ̀.
21 Los hebreos que antes estaban con los filisteos y que subieron con ellos al campamento desde todos los alrededores, también se volvieron para estar con los israelitas que estaban con Saúl y Jonatán.
Àwọn Heberu tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Filistini tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani.
22 Asimismo, todos los hombres de Israel que se habían escondido en la región montañosa de Efraín, cuando oyeron que los filisteos habían huido, también los siguieron con ahínco en la batalla.
Nígbà tí gbogbo àwọn Israẹli tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Efraimu gbọ́ pé àwọn Filistini sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.
23 Así salvó Yahvé a Israel aquel día, y la batalla pasó junto a Bet-Aven.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Israẹli ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Beti-Afeni.
24 Aquel día los hombres de Israel estaban angustiados, pues Saúl había conjurado al pueblo diciendo: “Maldito el hombre que coma cualquier alimento hasta que anochezca, y me vengue de mis enemigos.” Así que nadie del pueblo probó alimento.
Gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Saulu ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀tá mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.
25 Todo el pueblo entró en el bosque, y había miel en el suelo.
Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.
26 Cuando el pueblo llegó al bosque, he aquí que la miel goteaba, pero nadie se llevó la mano a la boca, porque el pueblo temía el juramento.
Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ síbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.
27 Pero Jonatán no escuchó cuando su padre ordenó al pueblo con el juramento. Por eso sacó la punta de la vara que tenía en la mano y la mojó en el panal, y se llevó la mano a la boca; y sus ojos se iluminaron.
Ṣùgbọ́n Jonatani kò gbọ́ pé baba rẹ̀ ti fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn náà, bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ orí ọ̀pá tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀ bọ afárá oyin náà, ó sì fi sí ẹnu rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dán.
28 Entonces respondió uno del pueblo y dijo: “Tu padre ordenó directamente al pueblo con un juramento, diciendo: “Maldito el hombre que hoy coma comida””. Entonces el pueblo se desmayó.
Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun sọ fún un pé, “Baba rẹ fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ ní òní!’ Ìdí nìyìí tí àárẹ̀ fi mú àwọn ènìyàn.”
29 Entonces Jonatán dijo: “Mi padre ha turbado la tierra. Por favor, mira cómo se han iluminado mis ojos porque he probado un poco de esta miel.
Jonatani sì wí pé, “Baba mi ti mú ìdààmú bá ìlú, wò ó bí ojú mi ti dán nígbà tí mo fi ẹnu kan oyin yìí.
30 ¿Cuánto más, si acaso el pueblo hubiera comido hoy libremente del botín de sus enemigos que encontró? Porque ahora no ha habido gran matanza entre los filisteos”.
Báwo ni kò bá ti dára tó bí àwọn ènìyàn bá ti jẹ nínú ìkógun àwọn ọ̀tá wọn lónìí, pípa àwọn Filistini ìbá ti pọ̀ tó?”
31 Aquel día atacaron a los filisteos desde Micmas hasta Ajalón. El pueblo estaba muy desmayado;
Ní ọjọ́ náà, lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti pa nínú àwọn Filistini láti Mikmasi dé Aijaloni, ó sì rẹ àwọn ènìyàn náà.
32 y el pueblo se abalanzó sobre el botín, y tomó ovejas, vacas y terneros, y los mató en el suelo; y el pueblo se los comió con la sangre.
Wọ́n sáré sí ìkógun náà, wọ́n sì mú àgùntàn. Màlúù àti ọmọ màlúù, wọ́n pa wọ́n sórí ilẹ̀, wọ́n sì jẹ wọ́n papọ̀ tẹ̀jẹ́tẹ̀jẹ̀.
33 Entonces se lo comunicaron a Saúl, diciendo: “He aquí que el pueblo peca contra Yahvé, pues come carne con la sangre.” Dijo: “Has hecho un trato traicionero. Hazme rodar hoy una gran piedra”.
Nígbà náà ni ẹnìkan sì wí fún Saulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn tí ń dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa jíjẹ ẹran tí ó ní ẹ̀jẹ̀ lára.” Ó sì wí pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti pọ̀jù, yí òkúta ńlá sí ibi nísinsin yìí.”
34 Saúl dijo: “Dispérsense entre el pueblo y díganle: “Cada uno traiga aquí su buey y cada uno su oveja, y mátenlos aquí y coman, y no pequen contra Yahvé comiendo carne con la sangre”.” Todo el pueblo trajo aquella noche cada uno su buey, y los mató allí.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Ẹ jáde lọ sáàrín àwọn ènìyàn náà kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Kí olúkúlùkù wọn mú màlúù àti àgùntàn tirẹ̀ tọ̀ mí wá, kí wọ́n sì pa wọ́n níhìn-ín, kí wọ́n sì jẹ́. Ẹ má ṣe ṣẹ̀ sí Olúwa, kí ẹ má ṣe jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ní olúkúlùkù mú màlúù tirẹ̀ wá ní alẹ́ ọjọ́ náà, wọ́n sì pa wọ́n níbẹ̀.
35 Saúl construyó un altar a Yahvé. Este fue el primer altar que construyó a Yahvé.
Nígbà náà Saulu kọ́ pẹpẹ kan fún Olúwa; èyí sì jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ ṣe èyí.
36 Saúl dijo: “Descendamos tras los filisteos de noche y saquemos provecho entre ellos hasta la luz de la mañana. No dejemos a ningún hombre de ellos”. Dijeron: “Haz lo que te parezca bien”. Entonces el sacerdote dijo: “Acerquémonos aquí a Dios”.
Saulu sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ tọ Filistini lọ ní òru, kí a bá wọn jà títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, kí a má ṣì ṣe dá ẹnìkankan sí nínú wọn.” Wọ́n sì wí pé, “Ṣe ohun tí ó bá dára ní ojú rẹ̀.” Ṣùgbọ́n àlùfáà wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Ọlọ́run níhìn-ín.”
37 Saúl pidió consejo a Dios: “¿Debo bajar tras los filisteos? ¿Los entregarás en manos de Israel?” Pero aquel día no le respondió.
Nígbà náà ni Saulu béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run pé, “Ṣé kí n sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn Filistini lọ bí? Ǹjẹ́ ìwọ yóò fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́ bí?” Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dá a lóhùn ní ọjọ́ náà.
38 Saúl dijo: “Acercaos aquí todos los jefes del pueblo, y sabed y ved en quién ha estado hoy este pecado.
Saulu sì wí pé, “Ẹ wá síyìn-ín ín, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olórí ogun, kí a ṣe ìwádìí irú ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ ti ṣẹ̀ lónìí.
39 Porque vive Yahvé, que salva a Israel, aunque sea en Jonatán, mi hijo, sin duda morirá.” Pero no hubo un solo hombre de todo el pueblo que le respondiera.
Bí Olúwa tí ó gba Israẹli là ti wà, bí ó bá ṣe pé a rí í lára Jonatani ọmọ mi, ó ní láti kú.” Ṣùgbọ́n ẹnìkankan nínú wọn kò sọ ọ̀rọ̀ kan.
40 Entonces dijo a todo Israel: “Vosotros estáis de un lado, y yo y Jonatán mi hijo estaremos del otro”. El pueblo le dijo a Saúl: “Haz lo que te parezca bien”.
Nígbà náà ni Saulu wí fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ lọ sí apá kan; èmi àti Jonatani ọmọ mi yóò lọ sí apá kan.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú rẹ.”
41 Por eso Saúl dijo a Yahvé, el Dios de Israel: “Muestra la derecha”. Jonatán y Saúl fueron elegidos, pero el pueblo escapó.
Nígbà náà ni Saulu gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli pé, “Fún mi ní ìdáhùn tí ó tọ́.” A sì mú Jonatani àti Saulu nípa ìbò dídì, àwọn ènìyàn náà sì yege.
42 Saúl dijo: “Echad suertes entre mi hijo y yo”. Jonathan fue seleccionado.
Saulu sì wí pé, “Ẹ dìbò láàrín èmi àti Jonatani ọmọ mi.” Ìbò náà sì mú Jonatani.
43 Entonces Saúl dijo a Jonatán: “¡Dime qué has hecho!” Jonatán se lo contó y dijo: “Ciertamente probé un poco de miel con la punta de la vara que tenía en la mano, y he de morir”.
Saulu sì wí fún Jonatani pé, “Sọ nǹkan tí ìwọ ṣe fún mi.” Jonatani sì sọ fún un pé, “Mo kàn fi orí ọ̀pá mi tọ́ oyin díẹ̀ wò. Nísinsin yìí ṣé mo ní láti kú?”
44 Saúl dijo: “Que Dios haga eso y más, porque seguramente morirás, Jonatán”.
Saulu sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, nítorí pé ìwọ Jonatani yóò sá à kú dandan.”
45 El pueblo dijo a Saúl: “¿Ha de morir Jonatán, que ha obrado esta gran salvación en Israel? ¡Lejos de eso! Vive Yahvé, que no se le caerá ni un pelo de la cabeza, ¡porque hoy ha trabajado con Dios!” Así que el pueblo rescató a Jonatán, para que no muriera.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Saulu pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jonatani kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Israẹli? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jonatani sílẹ̀, kò sì kú.
46 Entonces Saúl subió de seguir a los filisteos, y los filisteos se fueron a su lugar.
Nígbà náà ni Saulu sì dẹ́kun lílépa àwọn Filistini, àwọn Filistini sì padà sí ìlú wọn.
47 Cuando Saúl tomó el reino de Israel, luchó contra todos sus enemigos de todas partes: contra Moab, contra los hijos de Amón, contra Edom, contra los reyes de Soba y contra los filisteos. A dondequiera que se dirigía, los derrotaba.
Lẹ́yìn ìgbà tí Saulu ti jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni; Edomu, àti àwọn ọba Soba, àti àwọn Filistini. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.
48 Hizo valentía e hirió a los amalecitas, y libró a Israel de las manos de los que lo saqueaban.
Ó sì jà tagbára tagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Amaleki, ó sì ń gba Israẹli sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.
49 Los hijos de Saúl fueron Jonatán, Ishvi y Malquisúa, y los nombres de sus dos hijas fueron estos: el nombre de la primogénita, Merab, y el de la menor, Mical.
Àwọn ọmọ Saulu sì ni Jonatani, Iṣifi àti Malikiṣua. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Merabu àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Mikali.
50 El nombre de la esposa de Saúl era Ahinoam, hija de Ahimaas. El nombre del capitán de su ejército era Abner, hijo de Ner, tío de Saúl.
Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Ahinoamu ọmọbìnrin Ahimasi. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arákùnrin baba Saulu.
51 Cis era el padre de Saúl, y Ner el padre de Abner era hijo de Abiel.
Kiṣi baba Saulu àti Neri baba Abneri wọ́n sì jẹ́ ọmọ Abieli.
52 Hubo una severa guerra contra los filisteos durante todos los días de Saúl; y cuando éste veía a algún hombre poderoso o valiente, lo tomaba a su servicio.
Ní gbogbo ọjọ́ Saulu, ogun náà sì gbóná sí àwọn Filistini, níbikíbi tí Saulu bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.

< 1 Samuel 14 >