< Salmos 82 >
1 Un salmo de Asaf. Dios permanece en medio de su gran asamblea para juzgar a los que juzgan.
Saamu ti Asafu. Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá, ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn “ọlọ́run òrìṣà”.
2 ¿Hasta cuándo juzgarán injustamente y mostrarán favoritismo hacia los malvados? (Selah)
“Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìṣòdodo kí ó sì ṣe ojú ìṣáájú sí àwọn ènìyàn búburú?
3 Defiendan a los pobres y a los huérfanos; apoyen los derechos de los que son oprimidos y están sufriendo.
Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba; ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.
4 Rescaten al pobre y a aquellos que no pueden ayudarse a sí mismos; sálvenlos de las garras de los malvados.
Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní; gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.
5 Estos jueces no tienen nada de sabiduría; viven en la oscuridad; los cimientos de la tierra son sacudidos.
“Wọn kò mọ̀ ohun kankan, wọn kò lóye ohun kankan. Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn; à si mí gbogbo ìpìlẹ̀ ayé.
6 Yo digo, “Ustedes son jueces; todos ustedes son hijos del Altísimo.
“Mo wí pé, ‘Ẹyin ní “Ọlọ́run òrìṣà”; ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ.’
7 Pero morirán como cualquier ser humano, caerán como cualquier otro líder”.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ó kú bí ènìyàn lásán; ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ-aládé.”
8 Levántate, Señor, y juzga la tierra, porque todas las naciones te pertenecen a ti.
Dìde, Ọlọ́run, ṣe ìdájọ́ ayé, nítorí gbogbo orílẹ̀-èdè ni ìní rẹ.