< Salmos 24 >
1 Un Salmo de David. La tierra es del Señor, y todo lo que está en ella le pertenece a Él. El mundo es suyo, y todos los que viven en él.
Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
2 Porque él es el único que colocó las bases de los mares, estableciéndolas sobre las aguas.
nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
3 ¿Quién puede ir al monte del Señor? ¿Quién tiene el permiso de posarse sobre su lugar santo?
Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
4 Aquellos que tengan manos limpias y corazones puros, que no adoran ídolos, y que no mienten bajo juramento.
Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
5 Tomarán consigo la bendición del Señor, reivindicada por el Dios que los salva.
Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
6 Estos son los que podrán ir al Señor y lo adorarán delante ti, Dios de Jacob. (Selah)
Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
7 ¡Ábranse puertas! ¡Levántense, puertas antiguas! ¡Dejen que el Rey de gloria entre!
Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
8 ¿Quién es este Rey de gloria? El Señor, fuerte y poderoso, valiente en la batalla.
Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
9 ¡Ábranse puertas! ¡Levántense, puertas antiguas! ¡Dejen que el Rey de gloria entre!
Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
10 ¿Quién es el Rey de gloria? El Señor todo poderoso, ¡Él es el Rey de gloria! (Selah)
Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)