< Proverbios 15 >

1 Una respuesta amable evitará la ira, pero las palabras hirientes aumentarán el enojo.
Ìdáhùn pẹ̀lẹ́ yí ìbínú padà ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ líle máa ń ru ìbínú sókè.
2 Las palabras de los sabios despertarán interés por el conocimiento; pero los necios hablarán sin sentido.
Ahọ́n ọlọ́gbọ́n a máa gbé ìmọ̀ jáde ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń tú ọ̀rọ̀ ọ òmùgọ̀ jáde.
3 El Señor lo ve todo, y observa el bien y el mal.
Ojú Olúwa wà níbi gbogbo, Ó ń wo àwọn ẹni búburú àti àwọn ẹni rere.
4 Las palabras amables son Fuente de vida, pero el decir mentiras causa gran daño.
Ahọ́n tí ń mú ìtura wá jẹ́ igi ìyè ṣùgbọ́n ahọ́n ẹ̀tàn ń pa ẹ̀mí run.
5 Solo un necio aborrece la instrucción de su padre; pero el prudente acepta la corrección.
Aláìgbọ́n ọmọ kọ ìbáwí baba rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí jẹ́ ọlọ́gbọ́n.
6 Hay abundante tesoro donde en la vivienda de los justos; pero el salario de los malvados es causa de tribulación.
Ilé olódodo kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìṣúra, ṣùgbọ́n èrè àwọn ènìyàn búburú ń mú ìyọnu wá fún wọn.
7 Los sabios comparten su conocimiento, pero los necios no piensan de esta mima manera.
Ètè olódodo ń tan ìmọ̀ kalẹ̀; ṣùgbọ́n kò rí bẹ́ẹ̀ fún ọkàn aláìgbọ́n.
8 El Señor aborrece el sacrificio de los malvados, pero le complacen las oraciones de los justos.
Olúwa kórìíra ìrúbọ àwọn ènìyàn búburú ṣùgbọ́n àdúrà olódodo tẹ́ ẹ lọ́rùn.
9 El Señor odia el camino del malvado, pero ama a los que actúan con rectitud.
Olúwa kórìíra ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ó fẹ́ràn àwọn tí ń lépa òdodo.
10 Si abandonas el camino del bien, recibirás disciplina. Todo el que aborrece la corrección morirá.
Ẹni tí ó kúrò lójú ọ̀nà yóò rí ìbáwí gan an, ẹni tí ó kórìíra ìbáwí yóò kú.
11 Los muertos no tienen secretos que el Señor no sepa. ¡Cuanto más conoce nuestros pensamientos! (Sheol h7585)
Ikú àti ìparun ṣí sílẹ̀ níwájú Olúwa, mélòó mélòó ní nínú ọkàn àwọn ènìyàn. (Sheol h7585)
12 Los burladores no aprecian la corrección, por lo tanto no van donde los sabios para pedir consejo.
Ẹlẹ́gàn kò fẹ́ ẹni tí ń ba wí: kò ní gbàmọ̀ràn lọ́dọ̀ ọlọ́gbọ́n.
13 Si estas feliz por dentro, tu rostro lucirá alegre; pero si estas triste, lucirás derrotado.
Inú dídùn máa ń mú kí ojú túká ṣùgbọ́n ìbànújẹ́ ọkàn máa ń pa ẹ̀mí run.
14 Una mente inteligente busca el conocimiento; pero los necios se alimentan de estupidez.
Ọkàn olóye ń wá ìmọ̀ ṣùgbọ́n ẹnu aláìgbọ́n ń fẹ́ ìwà òmùgọ̀ bí ẹní jẹun.
15 La vida de los pobres es dura, pero si permaneces alegre, la vida es una fiesta sin final.
Gbogbo ọjọ́ àwọn olùpọ́njú jẹ́ ibi, ṣùgbọ́n onínúdídùn ń jẹ àlàáfíà ní ìgbà gbogbo.
16 Es mejor respetar al Señor y tener poco, que tener abundancia de dinero y además los problemas que le acompañan.
Ó sàn kí ó má pọ̀, kí ìbẹ̀rù Olúwa sì wà ju ọrọ̀ púpọ̀ pẹ̀lú ìyọnu.
17 Mejor una cena de vegetales donde hay amor, que comer carne con odio.
Oúnjẹ ewébẹ̀ níbi tí ìfẹ́ wà sàn ju àbọ́pa màlúù tòun ti ìríra.
18 Los irascibles provocan los problemas, pero los que tardan en enojarse ayudan a sosegar los conflictos.
Ènìyàn onínú ríru dá ìjà sílẹ̀ ṣùgbọ́n onísùúrù paná ìjà.
19 El camino de los perezosos está lleno de espinas, pero el camino de los justos es una autopista abierta.
Ọ̀nà ọ̀lẹ ni ẹ̀gún dí, ṣùgbọ́n ọ̀nà olódodo já geerege ni.
20 Un hijo sabio trae alegría a su padre; pero un hombre necio aborrece a su madre.
Ọlọ́gbọ́n ọmọ mú inú baba rẹ̀ dùn, ṣùgbọ́n aṣiwèrè ènìyàn kẹ́gàn ìyá rẹ̀.
21 La necedad alegra a los tontos, pero los prudentes hacen lo recto.
Inú ènìyàn aláìlóye a máa dùn sí ìwà òmùgọ̀; ṣùgbọ́n olóye ènìyàn a máa rin ọ̀nà tààrà.
22 Los planes se caen sin el buen consejo, pero hay éxito donde hay muchos consejeros.
Ìgbèrò a máa dasán níbi tí kò sí ìmọ̀ràn; ṣùgbọ́n a máa yege níbi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùbádámọ̀ràn wà.
23 Una buena respuesta trae alegría a sus oyentes. ¡Cuán bueno es oír la palabra acertada en el momento correcto!
Inú ènìyàn a máa dùn nígbà tí ó bá fèsì tó yẹ ọ̀rọ̀ tí ó bá sì wá lásìkò tó yẹ dára púpọ̀!
24 El camino de la vida para los justos va hacia arriba, para que pueden evitar caer en la tumba que esta debajo. (Sheol h7585)
Ọ̀nà ìyè ń lọ sókè fún ọlọ́gbọ́n láti sọ kí ó má bá à sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú. (Sheol h7585)
25 El Señor derriba la casa de los orgullosos, pero protege los límites de la casa de la viuda.
Olúwa fa ilé onígbèéraga ya lulẹ̀, ṣùgbọ́n ó pa ààlà opó onírẹ̀lẹ̀ mọ́ láìyẹ̀.
26 El Señor odia los pensamientos de los malvados, pero honra las palabras de los puros.
Olúwa kórìíra èrò ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n mímọ́ ni ọ̀rọ̀ ẹni pípé.
27 Los que codician las ganancias ilícitas acarrean problemas para sus familias. Pero los que aborrecen el soborno, vivirán.
Ọ̀kánjúwà ènìyàn mú ìyọnu bá ilé rẹ̀ ṣùgbọ́n ẹni tí ó kórìíra àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yóò yè.
28 Los justos piensan en la mejor forma de responder a una pregunta, pero los tontos hablan con maldad.
Ọkàn olódodo ń wọn ìdáhùn wò ṣùgbọ́n ẹnu ènìyàn búburú ń tú ibi jáde.
29 El Señor guarda distancia con los malvados, pero escucha las oraciones de los justos.
Olúwa jìnnà sí ènìyàn búburú ṣùgbọ́n ó ń gbọ́ àdúrà olódodo.
30 Los ojos brillantes producen alegría, y las buenas noticias mejoran el ánimo.
Ojú tó túká máa ń mú ayọ̀ wá fún ọkàn, ìròyìn ayọ̀ sì ń mú ìlera wá sínú egungun.
31 Si atiendes el buen consejo serás uno más entre los sabios.
Ẹni tí ó fetí sí ìbáwí tí ń fún ni ní ìyè, yóò wà ní àpéjọpọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n.
32 Si ignoras la instrucción, te aborreces a ti mismo; pero si escuchas la corrección, obtendrás entendimiento.
Ẹni tí ó kọ̀ ìbáwí kẹ́gàn ara rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí yóò ní ìmọ̀ sí i.
33 El respeto por el Señor enseña sabiduría; la humildad viene antes de la honra.
Ìbẹ̀rù Olúwa kọ́ ènìyàn ní ọgbọ́n, ìrẹ̀lẹ̀ sì ni ó máa ń ṣáájú ọlá.

< Proverbios 15 >