< Nehemías 7 >

1 Una vez reconstruida la muralla y levantadas las puertas, nombré a los porteros, a los cantores y a los levitas.
Lẹ́yìn ìgbà tí a tún odi mọ tán tí mo sì ri àwọn ìlẹ̀kùn sí ààyè wọn, a sì yan àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin àti àwọn Lefi.
2 Puse a mi hermano Hanani a cargo de Jerusalén, junto con Hananías, el comandante de la fortaleza, porque era un hombre honesto que respetaba a Dios más que muchos otros.
Mo fún Hanani arákùnrin mi pẹ̀lú Hananiah olórí ilé ìṣọ́ ní àṣẹ lórí Jerusalẹmu, nítorí tí ó jẹ́ ènìyàn olóòtítọ́, ó sì bẹ̀rù Ọlọ́run jù bí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ti ṣe lọ.
3 Les dije: “No permitan que se abran las puertas de Jerusalén hasta que el sol esté caliente, y asegúrate de que los guardias cierren y echen el cerrojo a las puertas mientras estén de servicio. Nombra a algunos de los habitantes de Jerusalén como guardias, para que estén en sus puestos, frente a sus propias casas”.
Mo sọ fún wọn pé, “A kò gbọdọ̀ ṣí ìlẹ̀kùn Jerusalẹmu títí oòrùn yóò fi mú. Nígbà tí àwọn aṣọ́bodè bá sì wà lẹ́nu iṣẹ́, jẹ́ kí wọn ti ìlẹ̀kùn kí wọn sì há wọn. Bákan náà, yàn nínú àwọn tí ń gbé Jerusalẹmu gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́. Àwọn mìíràn níbi tí a pín wọn sí àti àwọn mìíràn ní tòsí ilé e wọn.”
4 En aquellos tiempos la ciudad era grande y con mucho espacio, pero no había mucha gente en ella, y las casas no habían sido reconstruidas.
Ìlú náà tóbi ó sì ní ààyè, ṣùgbọ́n ènìyàn inú rẹ̀ kéré, a kò sì tí ì tún àwọn ilé inú rẹ̀ kọ́.
5 Mi Dios me animó a que todos -los nobles, los funcionarios y el pueblo- vinieran a registrarse según su genealogía familiar. Encontré el registro genealógico de los que habían regresado primero. Esto es lo que descubrí escrito allí.
Nígbà náà ni Ọlọ́run mi fi sí mi ní ọkàn láti kó àwọn ọlọ́lá, àwọn ìjòyè, àti àwọn ènìyàn jọ fún ìforúkọsílẹ̀ ní ìdílé ìdílé. Mo rí ìwé àkọsílẹ̀ ìtàn ìran àwọn tí ó kọ́ gòkè padà wá láti ìgbèkùn. Èyí ni ohun tí mo rí tí a kọ sínú ìwé náà.
6 Esta es una lista de la gente de la provincia que regresó del cautiverio. Estos eran los exiliados que habían sido llevados a Babilonia por el rey Nabucodonosor. Regresaron a Jerusalén y a Judá, a sus ciudades de origen.
Èyí ni àwọn ènìyàn agbègbè náà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti ìgbèkùn, àwọn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó ní ìgbèkùn (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú u rẹ̀.
7 Estaban dirigidos por Zorobabel, Jesúa, Nehemías, Azarías, Raamías, Nahamani, Mardoqueo, Bilsán, Misperet, Bigvai, Nehum y Baana. Este es el número de hombres del pueblo de Israel:
Wọ́n jọ rìn wá pẹ̀lú u Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Asariah, Raamiah, Nahamani, Mordekai, Bilṣani, Misperi, Bigfai, Nehumu, àti Baanah). Àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọkùnrin Israẹli,
8 Los hijos de Paros, 2.172;
àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
9 los hijos de Sefatías, 372;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
10 los hijos de Ara, 652;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀tàléláàádọ́ta ó lé méjì
11 los hijos de Pahat-moab, (los hijos de Jesúa y Joab), 2.818;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnlá ó lé méjìdínlógún
12 los hijos de Elam, 1.254;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
13 los hijos de Zatu, 845;
Sattu jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
14 los hijos de Zacai, 760;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
15 los hijos de Binui, 648;
Binnui jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́jọ
16 los hijos de Bebai, 628;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé méjìdínlọ́gbọ̀n
17 los hijos de Azgad, 2.322;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó dín méjìdínlọ́gọ́rin
18 los hijos de Adonicam, 667;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méje
19 los hijos de Bigvai, 2.067.
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́tàdínláàádọ́rin
20 Los hijos de Adin, 655.
Adini jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé márùn-ún
21 Los hijos de Ater, (hijos de Ezequías), 98;
Ateri (láti ipasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́rùn-ún
22 los hijos de Hasum, 328;
Haṣumu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́jọ
23 los hijos de Bezai, 324;
Besai jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó ó lé mẹ́rin
24 los hijos de Harif, 112;
Harifu jẹ́ méjìléláàádọ́fà
25 los hijos de Gabaón, 95;
Gibeoni jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
26 el pueblo de Belén y Netofa, 188;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu àti Netofa jẹ́ igba ó dín méjìlélógún
27 el pueblo de Anatot, 128;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
28 el pueblo de Bet-azmavet 42;
Beti-Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
29 el pueblo de Quiriat-jearim, Cafira y Beerot, 743;
Kiriati-Jearimu, Kefira, àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
30 el pueblo de Ramá y Geba, 621;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
31 el pueblo de Micmas, 122;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
32 el pueblo de Bet-el y Ai, 123;
Beteli àti Ai jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
33 el pueblo del otro Nebo, 52;
Nebo mìíràn jẹ́ méjìléláàádọ́ta
34 los hijos del otro Elam, 1.254;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
35 los hijos de Harim, 320;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó
36 los hijos de Jericó, 345;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún.
37 los hijos de Lod, Hadid y Ono, 721;
Lodi, Hadidi, àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé ọ̀kan
38 los hijos de Senaa, 3.930.
Senaa jẹ́ ẹgbàajì ó dín àádọ́rin.
39 Este es el número de los sacerdotes: los hijos de Jedaías (por la familia de Jesúa), 973;
Àwọn àlùfáà: àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
40 los hijos de Imer, 1.052;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
41 los hijos de Pasur, 1.247;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
42 los hijos de Harim, 1.017.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
43 Este es el número de los levitas: los hijos de Jesúa por Cadmiel (hijos de Hodavías), 74;
Àwọn ọmọ Lefi: àwọn ọmọ Jeṣua (láti ipasẹ̀ Kadmieli, láti ipasẹ̀ Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
44 los cantores de los hijos de Asaf, 148;
Àwọn akọrin: àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádọ́jọ.
45 los porteros de las familias de Salum, Ater, Talmón, Acub, Hatita y Sobai, 138.
Àwọn aṣọ́nà: àwọn ọmọ Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita, àti Ṣobai jẹ́ méjìdínlógóje.
46 Los descendientes de estos servidores del Templo: Ziha, Hasufa, Tabaot,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ Siha, Hasufa, Tabboati,
47 Queros, Sia, Padón,
Kerosi, Sia, Padoni,
48 Lebana, Hagaba, Salmai,
Lebana, Hagaba, Ṣalmai,
49 Hanán, Gidel, Gahar,
Hanani, Giddeli, Gahari,
50 Reaía, Rezín, Necoda,
Reaiah, Resini, Nekoda,
51 Gazam, Uza, Paseah,
Gassamu, Ussa, Pasea,
52 Besai, Mehunim, Nefusim,
Besai, Mehuni, Nefisimu,
53 Bacbuc, Hacufa, Harhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri,
54 Bazlut, Mehída, Harsa,
Basluti, Mehida, Harṣa,
55 Barcos, Sísara, Tema,
Barkosi, Sisera, Tema,
56 Nezía, y Hatifa.
Nesia, àti Hatifa.
57 Los descendientes de los siervos del rey Salomón: Sotai, Soferet, Perida,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni: àwọn ọmọ Sotai, Sofereti; Perida,
58 Jaala, Darcón, Gidel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
59 Sefatías, Hatil, Poqueret-hazebaim y Amón.
Ṣefatia, Hattili, Pokereti-Haṣṣebaimu, àti Amoni.
60 El total de los siervos del Templo y de los descendientes de los siervos de Salomón era de 392.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
61 Los que procedían de las ciudades de Tel-mela, Tel-Harsa, Querub, Addán e Imer no podían demostrar su genealogía familiar, ni siquiera que eran descendientes de Israel.
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
62 Entre ellos estaban las familias de Delaía, Tobías y Necoda, 642 en total.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
63 Además había tres familias sacerdotales, hijos de Habaía, Cos y Barzilai. (Barzilai se había casado con una mujer descendiente de Barzilai de Galaad, y se llamaba por ese nombre).
Lára àwọn àlùfáà ni: àwọn ọmọ Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi, ẹni tí a ń fi orúkọ yìí pè).
64 Se buscó un registro de ellos en las genealogías, pero no se encontraron sus nombres, por lo que se les prohibió servir como sacerdotes.
Àwọn wọ̀nyí wá àkọsílẹ̀ orúkọ ìran wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí í níbẹ̀, fún ìdí èyí, a yọ wọ́n kúrò nínú àwọn tí ń ṣiṣẹ́ àlùfáà gẹ́gẹ́ bí aláìmọ́.
65 El gobernador les ordenó que no comieran nada de los sacrificios del santuario hasta que un sacerdote pudiera preguntar al Señor sobre el asunto utilizando el Urim y el Tumim.
Baálẹ̀ sọ fún wọn nítorí náà pé wọn kò gbọdọ̀ kópa nínú jíjẹ oúnjẹ mímọ́ títí tí àlùfáà tí yóò wá tí ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu yóò fi dé.
66 El total de personas que regresaron fue de 42.360.
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó,
67 Además había 7.337 sirvientes y 245 cantores y cantoras.
yàtọ̀ sí àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin tí wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀ta dín lẹ́gbàárin ó dín ẹ̀tàlélọ́gọ́ta; wọ́n sì tún ní àwọn akọrin ọkùnrin àti obìnrin tí wọ́n jẹ́ òjìlúgba ó lé márùn-ún.
68 Tenían 736 caballos, 245 mulas,
Ẹṣin wọn jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin, ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlúgba ó dín márùn-ún;
69 435 camellos y 6.720 burros.
ìbákasẹ wọn jẹ́ òjìlénírinwó ó dín márùn-ún; kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọ́n jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
70 Algunos de los jefes de familia hicieron contribuciones voluntarias para el trabajo. El gobernador entregó a la tesorería 1.000 dáricos de oro, 50 cuencos y 530 conjuntos de ropa para los sacerdotes.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé náà kópa nínú ṣíṣe iṣẹ́ náà. Baálẹ̀ fún ilé ìṣúra ní ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, àádọ́ta àwo koto àti ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀ta lé mẹ́wàá ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
71 Algunos de los jefes de familia donaron al tesoro para la obra 20.000 dáricos de oro y 2.200 minas de plata.
Díẹ̀ lára àwọn olórí ìdílé fún ilé ìṣúra ní ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà àti ẹgbọ̀kànlá mina fàdákà.
72 El resto del pueblo donó 20.000 dáricos de oro, 2.000 minas de plata y 67 conjuntos de ropa para los sacerdotes.
Àròpọ̀ gbogbo ohun tí àwọn ènìyàn tókù fi sílẹ̀ jẹ́ ogún ẹgbẹ̀rún dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún méjì mina fàdákà àti ẹẹ́tàdínláàdọ́rin ẹ̀wù fún àwọn àlùfáà.
73 Los sacerdotes, los levitas, los porteros, los cantores y los servidores del Templo, así como parte del pueblo y el resto de los israelitas, volvieron a vivir en sus pueblos específicos. En el séptimo mes los israelitas vivían en sus pueblos,
Àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn aṣọ́bodè, àwọn akọrin, àwọn ènìyàn díẹ̀, àwọn ìránṣẹ́ ilé Ọlọ́run, àti gbogbo ènìyàn Israẹli wà ní ìlú wọn. Nígbà tí ó di oṣù keje, tí àwọn ọmọ Israẹli sì ti wà nínú ìlú u wọn,

< Nehemías 7 >