< Nehemías 12 >
1 Esta es la lista de los sacerdotes y levitas que volvieron con Zorobabel, hijo de Sealtiel, y Jesúa, el sumo sacerdote: Seraías, Jeremías, Esdras,
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
Amariah, Malluki, Hattusi,
3 Secanías, Rehum, Meremot,
Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
5 Miamín, Maadías, Bilga,
Mijamini, Moadiah, Bilgah,
6 Semaías, Joiarib, Jedaías,
Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
7 Salú, Amoc, Hilcías y Jedaías. Estos eran los líderes de los sacerdotes y sus parientes en el tiempo de Jesúa.
Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
8 Los levitas eran Jesúa, Binúi, Cadmiel, Serebías, Judá y Matanías, quien con sus compañeros levitas estaba a cargo de los cantos de alabanza.
Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
9 Otros dos levitas, Bacbuquías y Uni, estaban frente a ellos en el servicio.
Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
10 El sumo sacerdote Jesúa era el padre de Joiacim, que era el padre de Eliasib, que era el padre de Joiada,
Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
11 que era el padre de Jonatán, que era el padre de Jadúa.
Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
12 En tiempos de Joiacim, estos eran los jefes de familia de los sacerdotes de la familia de Seraías, Meraías; de la de Jeremías, Ananías;
Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
13 de la de Esdras, Mesulam; de la de Amarías, Johanán;
ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
14 de la de Maluci, Jonatán; de la de Sebanías, José;
ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
15 de la de Harim, Adna; de la de Meraiot, Helcai;
ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
16 de la de Iddo, Zacarías; de la de Gineto, Mesulam
ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
17 de Abías, Zicri; de Miiamín y de Maadías, Piltai;
ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
18 de Bilga, Samúa; de Semaías, Jonatán;
ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
19 de Joiarib, Matenai; de Jedaías, Uzi;
ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
20 de Salai, Calai; de Amoc, Eber;
ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
21 de Hicíash, Hasabías; de Jedaías, Natanael.
ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
22 Los jefes de familia de los levitas en la época de Eliasib, Joiada, Johanán y Jaddua, además de los de los sacerdotes, fueron registrados durante el reinado de Darío el Persa.
Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
23 En cuanto a la genealogía de los hijos de Leví, los jefes de familia hasta la época de Johanán, hijo de Eliasib, fueron inscritos en el Libro de los Registros.
Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
24 Los jefes de los levitas eran Hasabías, Serebías y Jesúa, hijo de Cadmiel, junto con sus compañeros levitas, que estaban de pie frente a ellos, cada sección dando alabanzas y agradecimientos y respondiendo unos a otros, según lo dispuesto por David, el hombre de Dios.
Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
25 Se les unieron Matanías, Bacbucías y Abdías. Mesulam, Talmón y Acub eran guardianes de los almacenes de las puertas.
Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
26 Sirvieron en tiempos de Joiaquim, hijo de Jesúa, hijo de Josadac, y en tiempos del gobernador Nehemías y del sacerdote y escriba Esdras.
Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
27 Para dedicar el muro de Jerusalén, se llamó a los levitas de todos los lugares donde vivían para que vinieran a Jerusalén y celebraran con alegría la dedicación con cantos de alabanza y agradecimiento, acompañados de címbalos, arpas y liras.
Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
28 También trajeron a los cantores de los alrededores de Jerusalén y de las aldeas de los netofatitas,
A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
29 así como de Bet-gilgal y de la zona de Geba y Azmavet, pues los cantores se habían construido aldeas alrededor de Jerusalén.
láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
30 Una vez que los sacerdotes y los levitas se purificaron, purificaron el pueblo, las puertas y la muralla.
Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
31 Hice que los jefes de Judá subieran a la muralla y dispuse dos grandes coros para dar gracias. Un grupo se dirigió a la derecha de la muralla, hasta la Puerta del Desecho.
Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
32 Los siguieron Oseas y la mitad de los dirigentes de Judá,
Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
33 con Azarías, Esdras, Mesulam,
àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
34 Judá, Benjamín, Semaías y Jeremías,
Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
35 así como algunos de los sacerdotes con trompetas, y Zacarías, hijo de Jonatán, hijo de Semaías hijo de Matanías, hijo de Micaías, hijo de Zaccur, hijo de Asaf,
pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
36 y sus compañeros sacerdotes, Semaías, Azarel, Milalai, Gilalai, Maai, Netanel, Judá y Hanani, junto con los instrumentos musicales, tal como lo exigió David, el hombre de Dios. El escriba Esdras los dirigía.
àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
37 En la Puerta de la Fuente se dirigieron hacia arriba por la escalera de la ciudad de David, donde la muralla sube, por encima de la casa de David, y hacia la Puerta del Agua, al este.
Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
38 El otro grupo del coro fue en dirección contraria. Los seguí, junto con la mitad del pueblo, por la muralla, pasando por la Torre de los Hornos, hasta la Muralla Ancha,
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
39 por la Puerta de Efraín, la Puerta de Jesana, la Puerta del Pescado, la Torre de Hananel y la Torre de los Cien, hasta la Puerta de las Ovejas, deteniéndose en la Puerta de la Guardia.
kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
40 Los dos coros de acción de gracias ocuparon entonces su lugar en el Templo de Dios. Yo seguí con el grupo de líderes que me acompañaba,
Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
41 junto con los sacerdotes que tocaban sus trompetas: Eliaquim, Maasías, Miniamin, Micaías, Elioenai, Zacarías y Ananías.
àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
42 Luego vinieron los cantores Maasías, Semaías, Eleazar, Uzzi, Johanán, Malquías, Elam y Ezer, y los coros cantaron, dirigidos por Izrahías.
Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
43 Ese día se ofrecieron muchos sacrificios, celebrando que Dios les había traído tanta felicidad, una felicidad tremenda. Las mujeres y los niños también celebraron, y los sonidos de alegría en Jerusalén se podían escuchar a lo lejos.
Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
44 Ese mismo día se pusieron hombres a cargo de los almacenes que contenían las ofrendas, la primera parte de las cosechas y los diezmos. Lo que la Ley asignaba a los sacerdotes y a los levitas se llevaba a estos almacenes desde los campos de los alrededores de las ciudades, porque todo el pueblo de Judá se alegraba por el servicio de los sacerdotes y de los levitas.
Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
45 Ellos eran responsables del culto a su Dios y del servicio de purificación, junto con los cantores y los porteros, siguiendo las instrucciones de David y de su hijo Salomón.
Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
46 Porque hace mucho tiempo, en tiempos de David y de Asaf, se habían designado directores para los cantores y para los cantos de alabanza y de agradecimiento a Dios.
Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
47 Así que en el tiempo de Zorobabel y de Nehemías, todos en Israel proveían las dietas para los cantores y los porteros. También se aseguraban de proveer para los otros levitas, y los levitas daban una parte de esto a los descendientes de Aarón.
Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.