< Génesis 10 >

1 Estos son los descendientes de los hijos de Noé: Sem, Cam y Jafet, a quienes después del diluvio nacieron estos hijos:
Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
2 Hijos de Jafet: Gómer, Magog, Madai, Javán, Tubal, Mósoc y Tirás.
Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
3 Hijos de Gómer: Asquenaz, Rifat, Togormá.
Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
4 Hijos de Javán: Elisá, Tarsis, Kitim y Dodanim.
Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
5 Estos se propagaron sobre las islas de las gentes y en sus tierras, según sus lenguas y sus tribus y sus naciones.
(Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
6 Hijos de Cam: Cus, Misraim, Put y Canán.
Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
7 Hijos de Cus: Sabá, Havilá, Sabtá, Ragmá y Sabtecá. Hijos de Ragmá: Sabá y Dedán.
Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
8 Cus engendró Nimrod, el cual fue el primero que se hizo poderoso en la tierra.
Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
9 Fue él un gran cazador delante de Yahvé; por lo cual suele decir: “Gran cazador delante de Yahvé, como Nimrod”.
Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
10 Reinó primero en Babel, Erec, Acad y Calné, en la tierra de Sinear.
Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
11 De aquella tierra salió para Asur y edificó Nínive, Rehobot-Ir, Calah,
Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
12 y Resen, entre Nínive y Calah; aquella es la gran ciudad.
àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
13 Misraim engendró a los de Ludim, los Anamim, los Lahabim, los Naftuhim,
Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
14 los Patrusim, los Casluhim, de donde salieron los Filisteos y los Caftoreos.
Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
15 Canaán engendró a Sidón, su primogénito, y a Het,
Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
16 y también al Jebuseo, al Amorreo, al Gergeseo,
Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
17 al Heveo, al Araceo, al Sineo,
àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
18 al Arvadeo, al Samareo y al Hamateo. Después se dispersaron las tribus de los cananeos.
àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
19 El territorio de los cananeos se extendió desde Sidón, en dirección a Gerar, hasta Gaza; y en dirección a Sodoma, Gomorra, Adamá y Seboím, hasta Lesa.
Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
20 Estos son los hijos de Cam, según sus familias y según sus lenguas, en sus territorios y según sus naciones.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
21 Nacieron hijos también a Sem, padre de todos los hijos de Éber y hermano mayor de Jafet.
A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
22 Hijos de Sem: Elam, Asur, Arfaxad, Lud y Aram.
Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
23 Hijos de Aram: Us, Hul, Géter y Mas.
Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
24 Arfaxad engendró a Sálah, y Sálah engendró a Éber.
Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
25 A Éber le nacieron dos hijos: el nombre de uno fue Fáleg, porque en sus días fue dividida la tierra. Su hermano se llamaba Joctán.
Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
26 Joctán engendró a Almodad, a Sálef, a Hazarmávet, a Járah,
Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
27 a Hadoram, a Uzal, a Diklá,
Hadoramu, Usali, Dikla,
28 a Obal, a Abomael, a Sabá,
Obali, Abimaeli, Ṣeba.
29 a Ofir, a Havilá y a Jobab. Todos estos fueron hijos de Joctán.
Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
30 Su territorio se extendió desde Mesá, en dirección a Sefar, al monte del Oriente.
Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
31 Estos son los hijos de Sem, según sus tribus y lenguas, en sus territorios y según sus naciones.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
32 Estas son las tribus de los hijos de Noé, según su origen y sus naciones; y de ellas se propagaron los pueblos en la tierra después del diluvio.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.

< Génesis 10 >