< Apostolska dela 3 >
1 A Peter in Janez sta šla vkupej gor v tempelj ob uri molitve, ob devetih.
Ní ọjọ́ kan Peteru àti Johanu jùmọ̀ ń gòkè lọ sí tẹmpili ní wákàtí àdúrà; tí í ṣe wákàtí mẹ́ta ọ̀sán.
2 In nosili so nekega moža, kteri je hrom bil iz telesa matere svoje; in pokladali so ga vsak dan pred tempeljnova vrata, ktera se imenujejo Lepa, da je prosil miloščine od teh, kteri so hodili v tempelj.
Wọn sì gbé ọkùnrin kan ti ó yarọ láti inú ìyá rẹ̀ wá, tí wọ́n máa ń gbé kalẹ̀ lójoojúmọ́ ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili ti a ń pè ni Dáradára, láti máa ṣagbe lọ́wọ́ àwọn tí ń wọ inú tẹmpili lọ.
3 Ta, videvši Petra in Janeza, da hočeta iti v tempelj, prosil je, da bi prejel miloščine.
Nígbà tí ó rí Peteru àti Johanu bí wọn tí fẹ́ wọ inú tẹmpili, ó ṣagbe.
4 Peter pa, pogledavši na-nj z Janezom, reče: Poglej na naju!
Peteru sì tẹjúmọ́ ọn, pẹ̀lú Johanu, ó ní “Wò wá!”
5 In on je gledal na nju, misleč, da bo kaj prejel od nju.
Ó sì fiyèsí wọn, ó ń retí láti rí nǹkan láti gbà lọ́wọ́ wọn.
6 Peter pa reče: Srebra in zlata nimam; kar pa imam, to ti dam. V ime Jezusa Kristusa Nazarečana, vstani in hodi!
Peteru wí pé, “Wúrà àti fàdákà èmi kò ní, ṣùgbọ́n ohun tí mo ní èyí náà ni mo fi fún ọ. Ní orúkọ Jesu Kristi ti Nasareti, dìde kí o sì máa rìn.”
7 In prijemši ga za desno roko, vzdigne ga: in precej so se utrdila stopala njegova in gležnji.
Ó sì fà á lọ́wọ́ ọ̀tún, ó sì gbé dìde; lójúkan náà ẹsẹ̀ rẹ̀ àti egungun kókósẹ̀ rẹ̀ sì mókun.
8 In poskočivši, stal je in hodil, in vnide ž njima v tempelj, hodeč in poskakujoč in hvaleč Boga.
Ó sì ń fò sókè, ó dúró, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí rìn, ó sì bá wọn wọ inú tẹmpili lọ, ó ń rìn, ó sì ń fò, ó sì yín Ọlọ́run.
9 In videlo ga je vse ljudstvo da hodi in hvali Boga;
Gbogbo ènìyàn sì rí i, ó ń rìn, ó sì yin Ọlọ́run,
10 In poznali so ga, da je tisti, ki je za voljo miloščine sedel pri Lepih vratih tempeljnovih in napolnijo se strmenja in groze nad tem, kar mu se je prigodilo.
Wọn sì mọ̀ pé òun ni ó ti jókòó tí ń ṣagbe ní ẹnu-ọ̀nà Dáradára ti tẹmpili náà; hà, sì ṣe wọn, ẹnu sì yà wọn gidigidi sí ohun tí ó ṣe lára rẹ̀.
11 Ko se je pa hromi ta, ki je bil ozdravel, držal Petra in Janeza, priteče k njim vse ljudstvo v lopo, ki se imenuje Solomonova, in strmeli so.
Bí arọ ti a mú láradá sì ti di Peteru àti Johanu mú, gbogbo ènìyàn jùmọ̀ súre tọ̀ wọ́n lọ ni ìloro ti a ń pè ní ti Solomoni, pẹ̀lú ìyàlẹ́nu ńlá.
12 Videč pa to Peter, odgovorí ljudstvu: Možjé Izraelci! kaj se čudite temu, ali kaj naju gledate, kakor da bi bila s svojo močjó ali oblastjo storila, da ta hodi?
Nígbà tí Peteru sì rí i, ó dáhùn, ó wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, èéṣe tí háà fi ń ṣe yín sí èyí? Tàbí èéṣe ti ẹ̀yin fi tẹjúmọ́ wa, bí ẹni pé agbára tàbí ìwà mímọ́ wa ni àwa fi ṣe é ti ọkùnrin yìí fi ń rìn?
13 Bog Abrahamov, in Izakov, in Jakobov, Bog očetov naših oslavil je sina svojega Jezusa, kterega ste vi izdali, in zatajili ga pred obličjem Pilatovim, ko je on sodil, naj se izpustí.
Ọlọ́run Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, Ọlọ́run àwọn baba wa, òun ni ó ti yin Jesu ìránṣẹ́ rẹ̀ lógo; ẹni tí ẹ̀yin ti fi lé wọn lọ́wọ́, tí ẹ̀yin sì sẹ́ níwájú Pilatu, nígbà tí ó ti pinnu rẹ̀ láti dá a sílẹ̀.
14 A vi ste svetnika in pravičnega zatajili, in prosili ste, naj vam dá ubijalca.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ṣẹ́ Ẹni Mímọ́ àti Olóòótọ́ náà, ẹ̀yin sì béèrè kí a fi apànìyàn fún un yín.
15 A začetnika življenja ste umorili, kterega je Bog obudil iz mrtvih, čemur smo mi priče.
Ẹ̀yin sì pa ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìyè, ẹni tí Ọlọ́run sì ti jí dìde kúrò nínú òkú; ẹlẹ́rìí èyí ti àwa jẹ́.
16 In za voljo vere v ime njegovo je tega, ki ga vidite in poznate, utrdilo ime njegovo; in vera, ki je po njem, dala mu je popolno to zdravje vpričo vseh vas.
Nípa ìgbàgbọ́ nínú orúkọ Jesu, òun ni ó mú ọkùnrin yìí láradá, ẹni tí ẹ̀yin rí, tí ẹ sì mọ̀. Orúkọ Jesu àti ìgbàgbọ́ tí ó wá nípa rẹ̀ ni ó fún un ní ìlera pípé ṣáṣá yìí ni ojú gbogbo yín.
17 Ali sedaj, bratje, vém, da ste iz nevednosti storili, kakor tudi poglavarji vaši.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ará, mo mọ̀ pé nípa àìmọ̀ ni ẹ̀yin fi ṣe é, gẹ́gẹ́ bí àwọn olórí yín pẹ̀lú ti ṣe.
18 Bog pa, kar je bil naprej oznanil z ustmi vseh prerokov svojih, da bo Kristus trpel, dopolnil je tako.
Ṣùgbọ́n báyìí ni Ọlọ́run ti ṣe ìmúṣẹ àwọn ohun tí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu gbogbo àwọn wòlíì pé, Kristi rẹ̀ yóò jìyà.
19 Spokorite se torej in izpreobrnite, da se izbrišejo grehi vaši: da pridejo časi ohlajenja od obličja Gospodovega,
Nítorí náà ẹ ronúpìwàdà, kí ẹ sì yípadà sí Ọlọ́run, kí a lè pa ẹ̀ṣẹ̀ yín rẹ́, kí àkókò ìtura bá a lè ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá,
20 In pošlje oznanjenega vam Jezusa Kristusa,
àti kí ó ba à lè rán Kristi tí a ti yàn fún yín tẹlẹ̀: àní Jesu.
21 Kterega mora sicer nebo sprejeti do časov, ko se uravna vse, kar je Bog povedal z ustmi svetih prerokov svojih od nekedaj. (aiōn )
Ẹni tí ọ̀run kò lé ṣàìmá gbà títí di ìgbà ìmúpadà ohun gbogbo, tí Ọlọ́run ti sọ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tí wọn ti ń bẹ nígbà tí ayé ti ṣẹ̀. (aiōn )
22 Mojzes namreč je rekel očakom: "Preroka vam bo zbudil Gospod Bog vaš izmed bratov vaših, kakor mene; njega poslušajte v vsem, karkoli vam bo govoril.
Mose wí pé, ‘Olúwa Ọlọ́run yín yóò gbé wòlíì kan dìde fún yín nínú àwọn arákùnrin yín, bí èmi; òun ni ẹ̀yin yóò máa gbọ́ tirẹ̀ ní ohun gbogbo tí yóò máa sọ fún un yín.
23 Bo pa, da vsaka duša, ktera ne bo poslušala tega preroka, iztrebila se bo iz ljudstva."
Yóò sì ṣe, olúkúlùkù ọkàn ti kò bá gbọ́ ti wòlíì náà, òun ni a ó parun pátápátá kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.’
24 Pa tudi vsi preroki od Samuela in po tem, kolikorkoli jih je govorilo, oznanili so te dní.
“Àní, gbogbo àwọn wòlíì láti Samuẹli wá, àti àwọn tí ó tẹ̀lé e, iye àwọn tí ó ti sọ̀rọ̀, wọn sọ ti ọjọ́ wọ̀nyí pẹ̀lú.
25 Vi ste sinovi prerokov in zaveze, ktero je storil Bog z očaki našimi, govoreč Abrahamu: "In v semenu tvojem se bodo blagoslovili vsi narodi zemlje."
Ẹ̀yin ni ọmọ àwọn wòlíì, àti ti májẹ̀mú tí Ọlọ́run ti bá àwọn baba yín dá nígbà tí ó wí fún Abrahamu pé, ‘Láti ipasẹ̀ irú àwọn ọmọ rẹ̀ ni a ó ti bùkún fún gbogbo ìdílé ayé.’
26 Vam najprej je zbudil Bog sina svojega Jezusa, in poslal, da vas blagoslovi, da se vsak od vas obrne od hudobij svojih.
Nígbà ti Ọlọ́run jí Jesu Ọmọ rẹ̀ dìde, ó kọ́ rán an sí i yín láti bùkún fún un yín, nípa yíyí olúkúlùkù yín padà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀.”