< 4 Mojzes 24 >

1 Ko je Bileám videl, da je to ugajalo Gospodu, da blagoslovi Izraela, ni odšel kakor ob drugih časih, da išče za izrekanji urokov, temveč je svoj obraz nameril proti divjini.
Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
2 Bileám je povzdignil svoje oči in videl Izraela prebivati v svojih šotorih glede na svoje rodove in duh od Boga je prišel nadenj.
Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
3 Vzel je njegovo prispodobo in rekel: »Bileám, Beórjev sin, je rekel in mož, katerega oči so odprte, je rekel.
ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
4 Rekel je tisti, ki je slišal besede od Boga, ki je videl vizijo Vsemogočnega pasti v videnje, toda svoje oči je imel odprte.
àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
5 Kako ljubki so tvoji šotori, oh Jakob in tvoja šotorska svetišča, oh Izrael!
“Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
6 Kakor se doline širijo naprej, kakor vrtovi pri rečnem bregu, kakor drevesa aloje, ki jih je Gospod zasadil, in kakor cedrova drevesa poleg vodá.
“Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
7 Vodo bo izlil iz svojih veder in njegovo seme bo na mnogih vodah in njegov kralj bo višji kakor Agág in njegovo kraljestvo bo povišano.
Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8 Bog ga je privedel iz Egipta; imel je, kakor bi bila moč samoroga. Pojedel bo narode svojih sovražnikov in njihove kosti bo zlomil in jih prebodel s svojimi puščicami.
“Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
9 Leži, ulegel se je kakor lev in kakor velik lev. Kdo ga bo razvnel? Blagoslovljen je, kdor te blagoslavlja in preklet je, kdor te preklinja.«
Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
10 Balákova jeza je bila vžgana zoper Bileáma in svoji roki je udaril skupaj in Balák je rekel Bileámu: »Poklical sem te, da prekolneš moje sovražnike in glej, ti si jih vse skupaj trikrat blagoslovil.
Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
11 Zato sedaj pobegni k svojemu kraju, Mislil sem te povišati k veliki časti; toda glej, Gospod te je zadržal pred častjo.«
Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
12 Bileám je rekel Baláku: »Mar nisem govoril tudi tvojim poslancem, ki si jih pošiljal k meni, rekoč:
Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
13 ›Če bi mi Balák dal svojo hišo, polno srebra in zlata, ne morem preko Gospodove zapovedi, da storim ali dobro ali slabo iz svojega lastnega mišljenja, temveč bom govoril to, kar govori Gospod?‹
‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
14 In sedaj glej, grem k svojemu ljudstvu. Pridi torej in oznanil ti bom, kaj bo to ljudstvo storilo tvojemu ljudstvu v zadnjih dneh.«
Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
15 Vzel je njegovo prispodobo in rekel: »Bileám, Beórjev sin, je rekel in mož, katerega oči so odprte, je rekel:
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
16 ›Rekel je ta, ki je slišal besede od Boga in poznal spoznanje Najvišjega, ki je videl videnje Vsemogočnega, padajoč v trans, toda z odprtimi očmi.
ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
17 Videl ga bom, toda ne sedaj. Gledal ga bom, toda ne [od] blizu. Prišla bo Zvezda iz Jakoba in Žezlo bo vstalo iz Izraela in udarilo bo Moábove vogale in uničilo vse Setove otroke.
“Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
18 Edóm bo posest, tudi Seír bo posest za svoje sovražnike, Izrael pa bo delal junaško.
Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
19 Iz Jakoba bo prišel tisti, ki bo imel gospostvo in uničil bo tistega, ki preostaja iz mesta.‹«
Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
20 Ko je pogledal na Amáleka, je vzel njegovo prispodobo ter rekel: »Amálek je bil prvi izmed narodov, toda njegov zadnji konec bo, da bo uničen na veke.«
Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
21 Pogledal je na Kenéjce in vzel njegovo prispodobo ter rekel: »Trdno je tvoje bivališče in svoje gnezdo postavljaš v skalo.
Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22 Vendar bo Kenéjec opustošen, dokler te Asúr ne bo odvedel ujetega.«
síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
23 Vzel je njegovo prispodobo in rekel: »Ojoj, kdo bo živel, ko Bog to dela!
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24 Ladje bodo prišle iz pokrajin Kitéjcev in prizadele Asúr in Eber in tudi on bo uničen na veke.«
Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
25 Bileám je vstal, odšel in se vrnil na svoj kraj in tudi Balák je odšel svojo pot.
Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.

< 4 Mojzes 24 >