< Jozue 2 >

1 Nunov sin Józue je iz Šitíma na skrivaj poslal ogledovat dva moža, rekoč: »Pojdita, poglejta deželo, celo Jeriho.« Odšla sta ter prišla v hišo pocestnice, po imenu Rahába in tam prenočila.
Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
2 Kralju Jerihe je bilo povedano, rekoč: »Glej, nocoj sta prišla sèm moža izmed Izraelovih otrok, da preiščeta deželo.«
A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
3 Kralj Jerihe je poslal k Rahábi, rekoč: »Privedi naprej moža, ki sta prišla k tebi, ki sta vstopila v tvojo hišo, kajti prišla sta, da bi preiskala vso deželo.«
Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
4 Ženska je vzela dva moža ter ju skrila in rekla tako: »K meni sta prišla moža, toda nisem vedela od kod sta bila.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
5 Pripetilo se je okoli časa zapiranja velikih vrat, ko je bilo temno, da sta moža odšla ven. Kam sta moža odšla, ne vem. Hitro ju zasledujte, kajti dohiteli ju boste.«
Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
6 Toda ona ju je privedla gor na streho hiše in ju skrila s stebli lana, ki jih je razvrstila po strehi.
(Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
7 Možje so ju zasledovali po poti k Jordanu, k prehodom in takoj, ko so tisti, ki so ju zasledovali, odšli ven, so zaprli velika vrata.
Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
8 Preden sta se ulegla, je prišla k njima na streho
Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
9 in možema rekla: »Vem, da vam je Gospod dal to deželo in da je vaša strahota padla na nas in da vsi prebivalci dežele zaradi vas slabijo.
Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
10 Kajti slišali smo, kako je Gospod za vas posušil vode Rdečega morja, ko ste prišli iz Egipta, in kaj ste storili dvema kraljema Amoréjcev, ki sta bila na drugi strani Jordana, Sihónu in Ogu, ki ste jih popolnoma uničili.
Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
11 Takoj, ko smo slišali te stvari, so se naša srca stopila niti tam zaradi vas ni ostalo nič več poguma v kateremkoli človeku, kajti Gospod, vaš Bog, on je Bog v nebesih zgoraj in na zemlji spodaj.
Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
12 Zdaj torej, prosim vaju, prisezita mi pri Gospodu, ker sem vama izkazala prijaznost, da bosta tudi vidva izkazala prijaznost hiši mojega očeta in mi dala zanesljivo znamenje.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
13 In da boste mojega očeta rešili živega in mojo mater, moje brate, moje sestre in vse, kar imajo in naša življenja osvobodili pred smrtjo.«
pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
14 Moža sta ji odgovorila: »Najina življenja za vaša, če ne izustiš te naše stvari. Zgodilo se bo, ko nam Gospod da deželo, da bomo s teboj postopali prijazno in zvesto.«
“Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
15 Potem ju je po vrvi spustila skozi okno, kajti njena hiša je bila na mestnem obzidju in prebivala je na obzidju.
Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
16 Rekla jima je: »Spravita se do gore, da vaju ne bi srečali zasledovalci in tam se skrivajta tri dni, dokler se zasledovalci ne vrnejo in potem lahko gresta svojo pot.«
Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
17 Moža sta ji rekla: »Midva bova brez krivde glede te tvoje prisege, s katero si naju prisegla.
Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
18 Glej, ko pridemo v deželo, boš to škrlatno vrv privezala na okno, skozi katero si naju spustila dol in domov k sebi boš privedla svojega očeta, svojo mater, svoje brate in vso družino svojega očeta.
Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
19 In zgodilo se bo, da kdorkoli bo šel ven skozi vrata tvoje hiše na ulico, bo njegova kri na njegovi glavi, midva pa bova brez krivde. In kdorkoli bo s teboj v hiši, njegova kri bo na najini glavi, če bo katerakoli roka nad njim.
Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
20 Če izustiš to našo stvar, potem bova prosta tvoje prisege, s katero si naju primorala priseči.«
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
21 Rekla je: »Glede na vajine besede, tako naj bo to.« Poslala ju je proč in sta odšla in na okno je privezala škrlatno vrv.
Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
22 Odšla sta in prišla h gori ter tam ostala tri dni, dokler se zasledovalci niso vrnili. Zasledovalci so ju iskali po vsej poti, toda niso ju našli.
Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
23 Tako sta se oba moža vrnila in spustila z gore, šla čez in prišla k Nunovemu sinu Józuetu in mu povedala vse stvari, ki so se jima pripetile.
Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
24 Józuetu sta rekla: »Resnično, Gospod je v naše roke izročil vso deželo, kajti celo vsi prebivalci dežele zaradi nas slabijo.«
Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”

< Jozue 2 >