< Job 8 >
1 Potem je odgovoril Bildád Suhéjec in rekel:
Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
2 »Doklej boš govoril te stvari? In kako dolgo bodo besede iz tvojih ust podobne močnemu vetru?
“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
3 Mar Bog izkrivlja sodbo? Mar Vsemogočni izkrivlja pravico?
Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
4 Če so tvoji otroci grešili zoper njega in jih je zavrgel zaradi njihovega prestopka,
Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
5 če hočeš zgodaj iskati Boga in narediti ponižno prošnjo Vsemogočnemu,
Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
6 če bi bil ti čist in pravičen, bi se on sedaj zaradi tebe zagotovo prebudil in prebivališče tvoje pravičnosti naredil uspešno.
Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
7 Čeprav je bil tvoj začetek majhen, bi vendar tvoj zadnji konec silno narasel.
Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
8 Kajti poizvedi, prosim te, o prejšnjem času in se pripravi, da preiskuješ o njihovih očetih
“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
9 (kajti mi smo samo od včeraj in ne vemo nič, ker so naši dnevi na zemlji senca).
Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
10 Mar te ne bodo poučili in ti povedali in izustili besed iz svojega srca?
Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
11 Mar lahko loček zraste brez blata? Mar lahko perunika raste brez vode?
Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
12 Medtem ko je še v svojem zelenju in ni odtrgana, ovene pred katerimkoli drugim zeliščem.
Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
13 Takšne so steze vseh, ki pozabljajo Boga in upanje hinavca bo propadlo,
Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
14 katerega upanje bo odrezano, katerega trdno upanje bo pajkova mreža.
Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
15 Naslonil se bo na svojo hišo, toda ta ne bo obstala; trdno jo bo držal, toda ta ne bo zdržala.
Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
16 Zelen je pred soncem in njegova veja poganja v njegovem vrtu.
Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
17 Njegove korenine so ovite okoli kupa in strmi na kraj kamnov.
Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
18 Če ga uniči iz svojega kraja, potem ga bo ta zatajil, rekoč: ›Nisem te videl.‹
Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
19 Glej, to je radost njegove poti in iz zemlje bodo pognali drugi.
Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
20 Glej, Bog ne bo zavrnil popolnega moža niti ne bo pomagal hudodelcem,
“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
21 dokler tvojih ust ne napolni s smehom in tvojih ustnic z radostjo.
títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
22 Tisti, ki te sovražijo, bodo oblečeni s sramoto in bivališče zlobnega bo prišlo v nič.«
ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”