< Job 21 >
1 Toda Job je odgovoril in rekel:
Jobu wá dáhùn, ó sì wí pé,
2 »Marljivo prisluhnite mojemu govoru in to naj bodo vaše tolažbe.
“Ẹ tẹ́tí sílẹ̀ dáradára sì àwọn ọ̀rọ̀ mi, kí èyí kí ó jásí ìtùnú fún mi.
3 Pustite mi, da lahko govorim in potem, ko bom govoril, zasmehujte.
Ẹ jọ̀wọ́ mi ki èmi sọ̀rọ̀; lẹ́yìn ìgbà ìwọ le máa fi mi ṣẹ̀sín ń ṣo.
4 Kar se mene tiče ali je moja pritožba proti človeku? In če bi bilo tako, zakaj naj potem moj duh ne bi bil nemiren?
“Àròyé mi ha ṣe sí ènìyàn bí? Èétise tí ọkàn mi kì yóò fi ṣe àìbalẹ̀?
5 Poglejte me in bodite osupli in svojo roko položite na svoja usta.
Ẹ wò mí fín, kí ẹnu kí ó sì yà yín, kí ẹ sì fi ọwọ́ lé ẹnu yín.
6 Celo kadar se spomnim, sem prestrašen in trepetanje se oprijemlje mojega mesa.
Àní nígbà tí mo rántí, ẹ̀rù bà mí, ìwárìrì sì mú mi lára.
7 Zakaj zlobni živijo, postanejo stari in so mogočni v moči?
Nítorí kí ní ènìyàn búburú fi wà ní ayé, tí wọ́n gbó, àní tí wọ́n di alágbára ní ipa?
8 Njihovo seme je z njimi utrjeno v njihovem pogledu in njihovo potomstvo pred njihovimi očmi.
Irú-ọmọ wọn fi ìdí kalẹ̀ ní ojú wọn pẹ̀lú wọn, àti ọmọ ọmọ wọn ní ojú wọn.
9 Njihove hiše so varne pred strahom niti nad njimi ni Božje palice.
Ilé wọn wà láìní ewu àti ẹ̀rù, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run kò sí lára wọn.
10 Njihov bik plodi in ne odpove; njihova krava povrže in ne zavrže svojega teleta.
Akọ màlúù wọn a máa gùn, kì í sì tàsé; abo màlúù wọn a máa bí, kì í sì í ṣẹ́yun.
11 Svoje malčke pošiljajo kakor trop in njihovi otroci plešejo.
Wọn a máa rán àwọn ọmọ wọn wẹ́wẹ́ jáde bí agbo ẹran, àwọn ọmọ wọn a sì máa jo kiri.
12 Vzamejo tamburin in harfo in se veselijo ob zvoku piščali.
Wọ́n mú ohun ọ̀nà orin, ìlù àti haapu; wọ́n sì ń yọ̀ sí ohùn fèrè.
13 Svoje dni preživijo v obilju in v trenutku gredo dol v grob. (Sheol )
Wọ́n n lo ọjọ́ wọn nínú ọrọ̀; wọn sì lọ sí ipò òkú ní àlàáfíà. (Sheol )
14 Zato Bogu rečejo: ›Odidi od nas, kajti mi ne želimo spoznanja tvojih poti.
Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí fún Ọlọ́run pé, ‘Lọ kúrò lọ́dọ̀ wa!’ Nítorí pé wọn kò fẹ́ ìmọ̀ ipa ọ̀nà rẹ.
15 Kaj je Vsemogočni, da bi mu služili? In kakšno korist bi imeli, če molimo k njemu?‹
Kí ni Olódùmarè tí àwa ó fi máa sìn in? Èrè kí ni a ó sì jẹ bí àwa ba gbàdúrà sí i?
16 Glej, njihovo dobro ni v njihovi roki; nasvet zlobnega je daleč od mene.
Kíyèsi i, àlàáfíà wọn kò sí nípa ọwọ́ wọn; ìmọ̀ ènìyàn búburú jìnnà sí mi réré.
17 Kako pogosto je sveča zlobnih ugasnjena! In kako pogosto nanje prihaja njihovo uničenje! Bog v svoji jezi deli bridkosti.
“Ìgbà mélòó mélòó ní a ń pa fìtílà ènìyàn búburú kú? Ìgbà mélòó mélòó ní ìparun wọn dé bá wọn, tí Ọlọ́run sì í máa pín ìbìnújẹ́ nínú ìbínú rẹ̀?
18 So kakor strnišče pred vetrom in kakor pleve, ki jih vihar odnaša proč.
Wọ́n dàbí àgékù koríko níwájú afẹ́fẹ́, àti bí ìyàngbò, tí ẹ̀fúùfù ńlá fẹ́ lọ.
19 Bog kopiči njegovo krivičnost za njegove otroke. Nagrajuje ga in on bo to vedel.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Ọlọ́run to ìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jọ fún àwọn ọmọ rẹ̀.’ Jẹ́ kí ó san án fún un, yóò sì mọ̀ ọ́n.
20 Njegove oči bodo videle njegovo uničenje in pil bo od besa Vsemogočnega.
Ojú rẹ̀ yóò rí ìparun ara rẹ̀, yóò sì máa mu nínú ríru ìbínú Olódùmarè.
21 Kajti kakšen užitek ima on v njegovi hiši za njim, ko je število njegovih mesecev na sredi prekinjeno?
Nítorí pé àlàáfíà kí ni ó ní nínú ilé rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀, nígbà tí a bá ké iye oṣù rẹ̀ kúrò ní agbede-méjì?
22 Mar bo kdorkoli Boga učil spoznanja? Ker on sodi tiste, ki so visoko.
“Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni le kọ Ọlọ́run ní ìmọ̀? Òun ní í sá à ń ṣe ìdájọ́ ẹni ibi gíga.
23 Nekdo umre v svoji polni moči, v celoti spokojen in tiho.
Ẹnìkan a kú nínú pípé agbára rẹ̀, ó wà nínú ìrora àti ìdákẹ́ pátápátá.
24 Njegove prsi so polne mleka in njegove kosti so navlažene z mozgom.
Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú, egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
25 Drugi pa umira v grenkobi svoje duše in nikoli ne jé z užitkom.
Ẹlòmíràn a sì kú nínú kíkorò ọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
26 Podobno se bodo ulegli v prah in ličinke jih bodo pokrile.
Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínú erùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
27 Glej, poznam vaše misli in naklepe, ki ste jih krivično domišljali zoper mene.
“Kíyèsi i, èmi mọ̀ èrò inú yín àti àrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
28 Kajti pravite: »Kje je prinčeva hiša? Kje so bivališča zlobnih?
Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní ilé ọmọ-aládé, àti níbo ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
29 Mar jih niste prosili, da gredo po poti? Ali poznate njihove simbole,
Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjá lọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn,
30 da je zlobni prihranjen za dan uničenja? Privedeni bodo k dnevu besa.
pé ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fún ọjọ́ ìparun. A ó sì mú wọn jáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
31 Kdo bo njegovo pot oznanil njegovemu obrazu? Kdo mu bo poplačal, kar je storil?
Ta ni yóò tako ipa ọ̀nà rẹ̀ lójúkojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
32 Vendar bo priveden h grobu in ostal bo v gomili.
Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ó sì máa ṣọ́ ibojì òkú.
33 Grude iz doline mu bodo sladke in vsak človek bo priveden za njim, kakor so tam brezštevilni pred njim.
Ògúlùtu àfonífojì yóò dùn mọ́ ọn. Gbogbo ènìyàn yóò sì máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn, bí ènìyàn àìníye ti lọ síwájú rẹ̀.
34 Kako me potem zaman tolažite, glede na to, da v vaših odgovorih ostaja neresnica?«
“Èéha ti ṣe tí ẹ̀yin fi ń tù mí nínú lásán, bí ò ṣe pé ní ìdáhùn yín, àrékérekè wa níbẹ̀!”