< Jeremija 7 >
1 Beseda, ki je prišla Jeremiju od Gospoda, rekoč:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 »Stopi v velika vrata Gospodove hiše in razglasi to besedo in reci: ›Poslušajte Gospodovo besedo, vsi vi iz Juda, ki vstopate pri teh velikih vratih, da obožujete Gospoda.
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 Tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: ›Poboljšajte svoje poti in svoja dejanja in jaz vam bom povzročil, da prebivate na tem kraju.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Ne zaupajte v lažnive besede, rekoč: › Gospodov tempelj, ‹ › Gospodov tempelj, ‹ › Gospodov tempelj so ti.‹
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 Kajti če temeljito poboljšate svoje poti in svoja dejanja, če temeljito izvršite sodbo med človekom in njegovim sosedom,
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 če ne zatirate tujca, sirote, vdove, in na tem kraju ne prelivate nedolžne krvi niti v svojo škodo ne hodite za drugimi bogovi,
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 potem vam bom povzročil, da prebivate na tem kraju, v deželi, ki sem jo dal vašim očetom na veke vekov.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Glejte, zaupate v lažnive besede, ki ne morejo koristiti.
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 Ali boste kradli, morili, počeli zakonolomstvo, krivo prisegali, zažigali kadilo Báalu in hodili za drugimi bogovi, ki jih ne poznate
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 in prišli ter stali pred menoj v tej hiši, ki je imenovana z mojim imenom in rekli: »Rešeni smo, da bi počeli vse te ogabnosti?
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Ali je ta hiša, ki je imenovana z mojim imenom, v vaših očeh postala brlog roparjev? Glejte, celo jaz sem to videl, « govori Gospod.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 »Toda pojdite sedaj k mojemu kraju, ki je bil v Šilu, kjer sem najprej postavil svoje ime in poglejte, kaj sem mu storil zaradi zlobnosti svojega ljudstva Izraela.
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 In sedaj, ker ste storili vsa ta dejanja, « govori Gospod »in sem vam govoril, vas zgodaj vzdigoval in govoril, toda niste slišali; in vas klical, toda niste odgovorili;
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 zato bom tej hiši, ki je imenovana z mojim imenom, v katerega zaupate in kraju, ki sem ga dal vam in vašim očetom, storil kakor sem storil Šilu.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 Zavrgel vas bom iz svojega pogleda, kakor sem zavrgel vse vaše brate, celó celotno Efrájimovo seme.
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Zato ne moli za to ljudstvo, niti ne povzdiguj klica, niti molitve zanje, niti ne posreduj k meni, kajti jaz te ne bom poslušal.
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Mar ne vidiš, kaj počno v Judovih mestih in na ulicah [prestolnice] Jeruzalem?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 Otroci nabirajo les, očetje netijo ogenj in ženske gnetejo svoje testo, da naredijo kolače kraljici neba in da izlivajo pitne daritve k drugim bogovom, da bi me lahko dražili k jezi.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 Mar me dražijo do jeze?« govori Gospod: » Mar ne dražijo sami sebe, do zmešnjave njihovih lastnih obrazov?«
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 Zato tako govori Gospod Bog: »Glej, moja jeza in moja razjarjenost bo izlita na tem kraju, na človeka, na žival, na drevesa polja in na sad tal; ta bo gorela in ne bo pogašena.«
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 Tako govori Gospod nad bojevniki, Izraelov Bog: »Položite svoje žgalne daritve k svojim klavnim daritvam in jejte meso.
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 Kajti nisem govoril vašim očetom niti jim nisem zapovedal na dan, ko sem jih privedel iz egiptovske dežele, glede žgalnih daritev ali klavnih daritev,
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 toda ukazal sem jim to stvar, rekoč: ›Ubogajte moj glas in jaz bom vaš Bog in vi boste moje ljudstvo; hodite po vseh poteh, ki sem vam jih zapovedal, da vam bo lahko dobro.‹
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 Toda niso prisluhnili niti nagnili svojega ušesa, temveč so hodili po nasvetih in po zamislih svojega zlega srca in odšli nazaj in ne naprej.
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 Od dneva, ko so vaši očetje izšli iz egiptovske dežele, do tega dne, sem vam celo pošiljal vse svoje služabnike preroke, dnevno sem jih zgodaj vzdigoval in pošiljal.
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 Vendar mi niso prisluhnili niti nagnili svojega ušesa, temveč so otrdili svoj vrat. Ravnali so huje kakor njihovi očetje.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 Zato jim boš govoril vse te besede, toda ne bodo ti prisluhnili. Tudi klical boš k njim, toda ne bodo ti odgovorili.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 Toda rekel jim boš: ›To je narod, ki ne uboga glasu Gospoda, svojega Boga niti ne prejema grajanja. Resnica je izginila in je iztrebljena iz njihovih ust.‹«
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Ostriži svoje lase, oh [prestolnica] Jeruzalem in jih odvrzi proč in povzemi žalostinko na visokih krajih, kajti Gospod je zavrnil in zapustil rod svojega besa.
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 Kajti Judovi otroci so storili zlo v mojem pogledu, « govori Gospod. »Svoje ogabnosti so postavili v hiši, ki se imenuje z mojim imenom, da jo oskrunijo.
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 Zgradili so visoke kraje Tofeta, ki je v dolini sina Hinómovega, da svoje sinove in svoje hčere sežigajo v ognju, kar jim nisem zapovedal niti ni prišlo v moje srce.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 Zato, glej, prihajajo dnevi, « govori Gospod, »da ta ne bo več imenovan Tofet niti dolina sina Hinómovega, temveč dolina klanja, kajti v Tofetu bodo pokopavali, dokler tam ne bo več prostora.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 Trupla tega ljudstva bodo meso za perjad neba in zemeljske zveri in nihče jih ne bo podil proč.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 Potem bom povzročil, da od Judovih mest in od ulic [prestolnice] Jeruzalem preneha glas smeha, glas veselja, glas ženina in glas neveste, kajti dežela bo zapuščena.
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.