< Jeremija 47 >
1 Beseda od Gospoda, ki je prišla preroku Jeremiju zoper Filistejce, preden je faraon udaril Gazo.
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tó tọ wòlíì Jeremiah wá nípa àwọn Filistini, kí ó tó di pé Farao dojúkọ Gasa.
2 »Tako govori Gospod: ›Glej, vode se dvigujejo iz severa in bodo preplavljajoča poplava in bodo poplavile deželo in vse, kar je v njej; mesto in tiste, ki prebivajo v njem. Potem bodo ljudje jokali in vsi prebivalci dežele bodo tulili
Báyìí ni Olúwa wí: “Wo bí omi ti ń ru sókè ní àríwá, wọn ó di odò tí ń bo bèbè mọ́lẹ̀. Wọn kò ní borí ilẹ̀ àti ohun gbogbo tó wà lórí rẹ̀, ìlú àti àwọn tó ń gbé nínú wọn. Àwọn ènìyàn yóò kígbe, gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà yóò hu
3 ob hrupu topotanja kopit njegovih močnih konj, ob drvenju njegovih bojnih voz in ob hrumenju njegovih koles. Očetje ne bodo gledali nazaj k svojim otrokom zaradi slabotnosti rok,
nígbà tí wọ́n bá gbọ́ ìró títẹ̀lé pátákò ẹsẹ̀ ẹṣin alágbára nígbà tí wọ́n bá gbọ́ ariwo kẹ̀kẹ́ ogun ọ̀tá ńlá àti iye kẹ̀kẹ́ wọn. Àwọn baba kò ní lè ran àwọn ọmọ lọ́wọ́; ọwọ́ wọn yóò kákò.
4 zaradi dneva, ki prihaja, da opleni vse Filistejce in da iztrebi iz Tira in Sidóna vsakega pomočnika, ki preostaja, kajti Gospod bo oplenil Filistejce, ostanek dežele Kaftor.
Nítorí tí ọjọ́ náà ti pé láti pa àwọn Filistini run, kí a sì mú àwọn tí ó là tí ó lè ran Tire àti Sidoni lọ́wọ́ kúrò. Olúwa ti ṣetán láti pa Filistini run, àwọn tí ó kù ní agbègbè Kafitori.
5 Plešavost je prišla nad Gazo; Aškelón je iztrebljen s preostankom njihove doline. Doklej boš zarezoval samega sebe?
Gasa yóò fá irun orí rẹ̀ nínú ọ̀fọ̀. A ó pa Aṣkeloni lẹ́nu mọ́; ìyókù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, ìwọ yóò ti sá ara rẹ lọ́gbẹ́ pẹ́ tó?
6 Oh ti, Gospodov meč, kako dolgo bo trajalo, preden boš tiho? Spravi se v svojo nožnico, počivaj in bodi miren.
“Ẹ̀yin kígbe, ‘Yé è, idà Olúwa, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò sinmi? Padà sínú àkọ̀ rẹ; sinmi kí o sì dákẹ́ jẹ́ẹ́.’
7 Kako je lahko tiho, glede na to, da mu je Gospod dal naročilo zoper Aškelón in zoper morsko obalo? Tam ga je on določil.‹«
Ṣùgbọ́n báwo ni yóò ṣe sinmi, nígbà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un, nígbà tí ó ti pa á láṣẹ láti dojúkọ Aṣkeloni àti agbègbè rẹ̀.”