< Izaija 45 >
1 Tako govori Gospod svojemu maziljencu Kiru, čigar desnico sem prijel, da bi pred njim podjarmil narode in odpasal bom ledja kraljev, da pred njim odprem dvoje opuščenih velikih vrat in velika vrata ne bodo zaprta:
“Èyí ni ohun tí Olúwa sọ fún ẹni òróró rẹ̀, sí Kirusi, ọwọ́ ọ̀tún ẹni tí mo dì mú láti dojú àwọn orílẹ̀-èdè bolẹ̀ níwájú rẹ̀ àti láti gba ohun ìjà àwọn ọba lọ́wọ́ wọn, láti ṣí àwọn ìlẹ̀kùn níwájú rẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé a kì yóò ti àwọn ẹnu-ọ̀nà.
2 »Jaz bom šel pred teboj in naredil skrivljene kraje ravne, bronasta velika vrata bom razbil na koščke in železne zapahe presekal na dvoje.
Èmi yóò lọ síwájú rẹ, Èmi ó sì tẹ́ àwọn òkè ńlá pẹrẹsẹ Èmi yóò fọ gbogbo ẹnu-ọ̀nà idẹ èmi ó sì gé ọ̀pá irin.
3 Dal ti bom zaklade teme in skrita bogastva skrivnih krajev, da boš lahko vedel, da sem jaz, Gospod, ki te kličem s tvojim imenom, Izraelov Bog.
Èmi yóò sì fún ọ ní àwọn ọrọ̀ ibi òkùnkùn, ọrọ̀ tí a kó pamọ́ sí àwọn ibi tí ó fi ara sin, tó bẹ́ẹ̀ tí ìwọ yóò fi mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ó pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ.
4 Zaradi Jakoba, mojega služabnika in Izraela, mojega izvoljenega, sem te celó poklical po tvojem imenu. Imenoval sem te, čeprav me nisi poznal.
Nítorí Jakọbu ìránṣẹ́ mi àti Israẹli ẹni tí mo yàn, Mo pè ọ́ pẹ̀lú orúkọ rẹ, mo sì gbé oyè kan kà ọ́ lórí bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò gbà mí.
5 Jaz sem Gospod in nobenega drugega ni, ni Boga poleg mene. Opasal sem te, čeprav me nisi poznal,
Èmi ni Olúwa, àti pé kò sí ẹlòmíràn; yàtọ̀ sí èmi kò sí ọlọ́run kan, Èmi yóò fún ọ ní okun, bí o kò tilẹ̀ tí ì gbà mí,
6 da bi lahko vedeli od sončnega vzhoda in od zahoda, da ni nikogar poleg mene. Jaz sem Gospod in nobenega drugega ni.
tí o fi jẹ́ pé láti ìlà-oòrùn títí dé ibi ìwọ̀ rẹ̀ kí ènìyàn le mọ̀, kò sí ẹnìkan lẹ́yìn mi. Èmi ni Olúwa, lẹ́yìn mi kò sí ẹlòmíràn mọ́.
7 Jaz oblikujem svetlobo in ustvarjam temo, sklepam mir in ustvarjam zlo. Jaz, Gospod, delam vse te stvari.
Mo dá ìmọ́lẹ̀, mo sì dá òkùnkùn, Mo mú àlàáfíà wá, Mo sì dá àjálù; Èmi Olúwa ni ó ṣe nǹkan wọ̀nyí.
8 Kapljajte, ve nebesa od zgoraj in naj nebo izlije pravičnost. Naj se zemlja odpre in naj rodi rešitev duš in naj skupaj požene pravičnost; jaz, Gospod, sem to ustvaril.
“Ìwọ ọ̀run lókè rọ òjò òdodo sílẹ̀; jẹ́ kí àwọsánmọ̀ kí ó rọ̀ ọ́ sílẹ̀. Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó yanu gbagada, jẹ́ kí ìgbàlà kí ó dìde sókè, jẹ́ kí òdodo kí ó dàgbà pẹ̀lú rẹ̀; Èmi Olúwa ni ó ti dá a.
9 Gorje tistemu, ki se prepira s svojim Stvarnikom! Naj se črepinja prička s črepinjami zemlje. Mar bo ilo reklo tistemu, ki ga oblikuje: »Kaj delaš?« Ali tvoje delo: »On nima rok?«
“Ègbé ni fún ènìyàn tí ó ń bá Ẹlẹ́dàá rẹ̀ jà, ẹni tí òun jẹ́ àpáàdì kan láàrín àwọn àpáàdì tí ó wà lórí ilẹ̀. Ǹjẹ́ amọ̀ lè sọ fún amọ̀kòkò, pé: ‘Kí ni ohun tí ò ń ṣe?’ Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ lè sọ pé, ‘Òun kò ní ọwọ́?’ ()
10 Gorje tistemu, ki pravi svojemu očetu: »Čemu si zaplodil?« Ali ženski: »Kaj si rodila?«
Ègbé ni fún ẹni tí ó sọ fún baba rẹ̀ pé, ‘Kí ni o bí?’ tàbí sí ìyá rẹ̀, ‘Kí ni ìwọ ti bí?’
11 Tako govori Gospod, Sveti Izraelov in njegov Stvarnik: »Vprašajte me o stvareh, ki pridejo, glede mojih sinov in glede dela mojih rok mi zapovejte.
“Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ẹni Mímọ́ Israẹli, àti Ẹlẹ́dàá rẹ̀. Nípa ohun tí ó ń bọ̀, ǹjẹ́ o ń bi mí léèrè nípa àwọn ọmọ mi, tàbí kí o pàṣẹ fún mi nípa iṣẹ́ ọwọ́ mi bí?
12 Naredil sem zemljo in na njej ustvaril človeka. Jaz, celó moje roke so razprostrle nebo in zapovedal sem vsej njegovi vojski.
Èmi ni ẹni tí ó dá ilẹ̀ ayé tí ó sì da ọmọ ènìyàn sórí i rẹ̀. Ọwọ́ mi ni ó ti ta àwọn ọ̀run; mo sì kó àwọn àgbájọ ìràwọ̀ rẹ̀ síta.
13 Dvignil sem ga v pravičnosti in jaz bom usmerjal vse njegove poti. Zgradil bo moje mesto in izpustil bo moje ujetnike, ne za ceno niti [ne za] nagrado, « govori Gospod nad bojevniki.
Èmi yóò gbé Kirusi sókè nínú òdodo mi. Èmi yóò mú kí gbogbo ọ̀nà rẹ̀ kí ó tọ́. Òun yóò tún ìlú mi kọ́ yóò sì tú àwọn àtìpó mi sílẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún owó tàbí ẹ̀bùn kan, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.”
14 Tako govori Gospod: »Trud Egipta in trgovanje Etiopije in Sabejcev, postavnih mož, bo prišlo k tebi in oni bodo tvoji. Prišli bodo za teboj, v verigah bodo prišli in padli dol k tebi, ponižno te bodo prosili, rekoč: ›Zagotovo je Bog v tebi in tam ni nikogar drugega, tam ni Boga.‹
Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Àwọn èròjà ilẹ̀ Ejibiti àti àwọn ọjà ilẹ̀ Kuṣi, àti àwọn Sabeani— wọn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ wọn yóò sì jẹ́ tìrẹ; wọn yóò máa wọ́ tẹ̀lé ọ lẹ́yìn, wọn yóò máa wá lọ́wọ̀ọ̀wọ́. Wọn yóò máa foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀, wọn yóò sì máa bẹ̀bẹ̀ níwájú rẹ pé, ‘Nítòótọ́ Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ kò sì ṣí ẹlòmíràn; kò sí ọlọ́run mìíràn.’”
15 Resnično, ti si Bog, ki samega sebe skrivaš, oh Izraelov Bog, Odrešenik.
Nítòótọ́ ìwọ jẹ́ Ọlọ́run tí ó fi ara rẹ̀ pamọ́, Ìwọ Ọlọ́run àti Olùgbàlà Israẹli,
16 Osramočeni bodo in tudi zbegani, vsi izmed njih. Skupaj bodo šli v zmešnjavo, ki so izdelovalci malikov.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbẹ́ ère ni ojú yóò tì wọn yóò sì kan àbùkù; gbogbo wọn ni yóò bọ́ sínú àbùkù papọ̀.
17 Toda Izrael bo rešen v Gospodu z večno rešitvijo duš. Ne boste osramočeni niti zbegani, od veka do veka.
Ṣùgbọ́n Israẹli ni a ó gbàlà láti ọwọ́ Olúwa pẹ̀lú ìgbàlà ayérayé; a kì yóò kàn yín lábùkù tàbí kí a dójútì yín, títí ayé àìnípẹ̀kun.
18 Kajti tako govori Gospod, ki je ustvaril nebo; sam Bog, ki je oblikoval zemljo in jo naredil, osnoval jo je, ni je ustvaril zaman, oblikoval jo je, da bi bila naseljena. Jaz sem Gospod in nobenega drugega ni.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹni tí ó dá àwọn ọ̀run, Òun ni Ọlọ́run; ẹni tí ó mọ tí ó sì dá ayé, Òun ló ṣe é; Òun kò dá a láti wà lófo, ṣùgbọ́n ó ṣe é kí a lè máa gbé ibẹ̀, Òun wí pé: “Èmi ni Olúwa, kò sì ṣí ẹlòmíràn.
19 Nisem govoril na skrivnem, na temnem kraju zemlje. Jakobovemu semenu nisem rekel: ›Zaman me iščite.‹ Jaz, Gospod, govorim pravičnost, razglašam stvari, ki so pravilne.
Èmi kò sọ̀rọ̀ níbi tí ó fi ara sin, láti ibìkan ní ilẹ̀ òkùnkùn, Èmi kò tí ì sọ fún àwọn ìran Jakọbu pé, ‘Ẹ wá mi lórí asán.’ Èmi Olúwa sọ òtítọ́, Mo sì sọ èyí tí ó tọ̀nà.
20 Zberite se in pridite, približajte se skupaj, vi, ki ste pobegnili narodom. Nimajo spoznanja, ki postavljajo les svojih rezanih podob in molijo k bogu, ki ne more rešiti.
“Ẹ kó ara yín jọ kí ẹ sì wá; ẹ kórajọ, ẹ̀yin ìsáǹsá láti àwọn orílẹ̀-èdè wá. Aláìmọ̀kan ni àwọn tí ó ń ru ère igi káàkiri, tí wọ́n gbàdúrà sí àwọn òrìṣà tí kò le gba ni.
21 Povejte in privedite jih blizu; da, naj se skupaj posvetujejo. Kdo je to razglasil od starodavnega časa? Kdo je to povedal od tistega časa? Mar nisem jaz, Gospod? In nobenega drugega Boga ni poleg mene, pravičnega Boga in Odrešenika, nobenega ni poleg mene.
Jẹ́ kí a mọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀, fihàn wá, jẹ́ kí wọn jọ dámọ̀ràn papọ̀. Ta ló ti sọ èyí lọ́jọ́ tí o ti pẹ́, ta ló ti wí èyí láti àtètèkọ́ṣe? Kì í ha á ṣe Èmi, Olúwa? Àti pé kò sí Ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn mi, Ọlọ́run olódodo àti olùgbàlà; kò sí ẹlòmíràn àfi èmi.
22 Poglejte k meni in bodite rešeni, vsi konci zemlje, kajti jaz sem Bog in nobenega drugega ni.
“Yípadà sí mi kí a sì gbà ọ́ là, ẹ̀yin ìpẹ̀kun ilẹ̀ ayé; nítorí Èmi ni Ọlọ́run kò sì ṣí ẹlòmíràn.
23 Prisegel sem sam pri sebi, beseda je izšla iz mojih ust v pravičnosti in se ne bo vrnila: ›Da se bo k meni priklonilo vsako koleno, vsak jezik bo prisegel.‹
Nípa èmi tìkára mi ni mo ti búra, ẹnu mi ni ó ti sọ ọ́ pẹ̀lú gbogbo ipá mi, ọ̀rọ̀ náà tí a kì yóò lè parẹ́. Níwájú mi ni gbogbo orúnkún yóò wólẹ̀; nípa mi ni gbogbo ahọ́n yóò búra.
24 Zagotovo bo nekdo rekel: ›V Gospodu imam pravičnost in moč.‹ Celó k njemu bodo prišli ljudje in vsi tisti, ki so ogorčeni zoper njega, bodo osramočeni.
Wọn yóò sọ ní ti èmi, ‘Nínú Olúwa nìkan ni òdodo àti agbára wà.’” Gbogbo àwọn tí ó ti bínú sí; yóò wá sọ́dọ̀ rẹ̀ a ó sì dójútì wọn.
25 V Gospodu bo vse seme Izraela opravičeno in bo slavilo.
Ṣùgbọ́n nínú Olúwa gbogbo àwọn ìran Israẹli ni a ó rí ní òdodo, a o sì gbé wọn ga.