< 1 Mojzes 44 >
1 Oskrbniku svoje hiše je zapovedal, rekoč: »Vreče mož napolni s hrano, kolikor lahko nesejo in denar vsakega človeka položi v ustje njegove vreče.
Nígbà náà ni Josẹfu pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Di oúnjẹ kún inú àpò àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n èyí tí wọ́n le rù, kí o sì mú owó olúkúlùkù àwọn ọkùnrin náà padà sí ẹnu àpò rẹ̀.
2 Mojo čašo pa, srebrno čašo, položi v ustje vreče najmlajšega in njegov žitni denar.« Ta je storil glede na besedo, ki jo je Jožef spregovoril.
Nígbà náà ni kí o mú kọ́ọ̀bù idẹ mi sí ẹnu àpò èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn nínú wọn pẹ̀lú owó tí ó fi ra ọkà,” ó sì ṣe bí Josẹfu ti sọ.
3 Takoj, ko je bila zjutraj svetloba, so bili možje odposlani, oni in njihovi osli.
Bí ilẹ̀ ti ń mọ́, wọ́n bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà lọ pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.
4 Ko so odšli ven iz mesta in še ne daleč proč, je Jožef rekel svojemu oskrbniku: »Vstani, sledi možem in ko jih boš dohitel, jim reci: ›Zakaj ste zlo nagradili za dobro?
Wọn kò tí ì rìn jìnnà sí ìlú náà tí Josẹfu fi wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Lépa àwọn ọkùnrin náà, nígbà tí o bá sì bá wọn, kí o wí pé, ‘Èéṣe ti ẹ fi búburú san rere?
5 Mar ni to tisto iz česar moj gospod pije in s čimer zares vedežuje? S takšnim dejanjem ste storili zlo.‹«
Èyí ha kọ́ ni kọ́ọ̀bù tí olúwa mi ń lò fún ohun mímu tí ó sì tún ń fi í ṣe àyẹ̀wò? Ohun tí ẹ ṣe yìí burú púpọ̀.’”
6 Ta jih je dohitel in jim spregovoril te iste besede.
Nígbà tí ó sì bá wọn, o sọ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún wọn.
7 Rekli so mu: »Zakaj moj gospod govori te besede? Bog ne daj, da bi tvoji služabniki storili glede na to stvar.
Ṣùgbọ́n wọ́n dá a lóhùn pé, “Kí ló dé tí olúwa mi sọ irú nǹkan wọ̀nyí? Ká má rí i! Àwọn ìránṣẹ́ rẹ kò le ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀!
8 Glej, denar, ki smo ga našli v ustjih svojih vreč, smo iz kánaanske dežele ponovno prinesli k tebi, kako bi potem ukradli srebro ali zlato iz hiše tvojega gospodarja?
A tilẹ̀ mú owó tí a rí lẹ́nu àpò wa padà tọ̀ ọ́ wá láti ilẹ̀ Kenaani. Nítorí náà èéṣe tí àwa yóò fi jí wúrà tàbí idẹ ní ilé olúwa à rẹ?
9 Pri komerkoli izmed tvojih služabnikov bi bilo to najdeno, naj umre, mi pa bomo tudi sužnji mojemu gospodu.«
Bí a bá rí i lọ́wọ́ èyíkéyìí nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ, kíkú ni yóò kú, àwọn tí ó kù yóò sì di ẹrú fún olúwa à rẹ.”
10 Rekel je: » Naj bo sedaj tudi to glede na vaše besede. Ta, pri komer bo to najdeno, bo moj služabnik, vi pa boste brez krivde.«
Ó wí pé, “Ó dára, kí ó rí bí ẹ ti ṣe sọ. Ẹnikẹ́ni tí mo bá rí i lọ́wọ́ rẹ̀ yóò di ẹrú mi. Ẹ̀yin tí ó kù yóò sì wà láìlẹ́bi.”
11 Potem so naglo sneli vsak mož svojo vrečo k tlom in vsak mož je svojo vrečo odprl.
Olúkúlùkù wọn yára sọ àpò rẹ̀ kalẹ̀, wọ́n sì tú u.
12 On pa je iskal in začel pri najstarejšem in nehal pri najmlajšem in čaša je bila najdena v Benjaminovi vreči.
Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí ní í wá a, bẹ̀rẹ̀ láti orí ẹ̀gbọ́n títí lọ sórí àbúrò pátápátá. Ó sì rí kọ́ọ̀bù náà nínú àpò ti Benjamini.
13 Potem so raztrgali svoja oblačila in vsak človek je otovoril svojega osla in vrnili so se v mesto.
Nígbà tí wọ́n rí èyí, wọ́n fa aṣọ wọn ya, wọ́n sì banújẹ́ gidigidi, wọn tún ẹrù wọn dì sórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọ́n sì padà sí inú ìlú.
14 Juda in njegovi bratje so prišli v Jožefovo hišo, kajti še je bil tam in padli so pred njim na tla.
Josẹfu sì wà nínú ilé nígbà tí Juda àti àwọn arákùnrin rẹ̀ wọlé wá. Gbogbo wọn sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
15 Jožef jim je rekel: »Kakšno dejanje je to, kar ste storili? Ali ne veste, da tak mož, kakor jaz, lahko zagotovo vedežuje?«
Josẹfu wí fún wọn pé, “Èwo ni èyí tí ẹ ṣe yìí? Ṣe ẹ kò mọ pé, ènìyàn bí èmi le è rí ìdí nǹkan nípa ṣíṣe àyẹ̀wò?”
16 Juda je rekel: »Kaj bomo rekli mojemu gospodu? Kaj naj govorimo? Ali kako se bomo očistili? Bog je odkril krivičnost svojih služabnikov. Glej, mi smo gospodovi služabniki, tako mi, kakor tudi ta, pri komer se je našla čaša.«
Juda dáhùn pé, “Kí ni à bá sọ fún olúwa mi? Báwo ni a ṣe lè wẹ ara wa mọ́? Ọlọ́run ti tú àṣírí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, a ti di ẹrú olúwa à mi báyìí àwa fúnra wa àti ẹni náà tí a rí kọ́ọ̀bù lọ́wọ́ rẹ̀.”
17 Rekel je: »Bog ne daj, da bi tako storil. Temveč človek, v čigar roki je najdena čaša, bo moj služabnik. Kar pa se tiče vas, se v miru dvignite k svojemu očetu.«
Ṣùgbọ́n Josẹfu dáhùn pé, “Ká má rí i pé mo ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀! Ẹni tí a bá kọ́ọ̀bù mi lọ́wọ́ rẹ̀ nìkan ni yóò di ẹrú mi, ẹ̀yin tí ó kù, ẹ máa lọ sọ́dọ̀ baba yín ní àlàáfíà.”
18 Potem se mu je približal Juda in rekel: »Oh, moj gospod, naj tvoj služabnik, prosim te, spregovori besedo v ušesa mojega gospoda in naj tvoja jeza ne gori zoper tvojega služabnika, kajti ti si celo kakor faraon.
Nígbà náà ni Juda súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó sọ ọ̀rọ̀ kan fún olúwa mi, má ṣe bínú sí ìránṣẹ́ rẹ bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ pẹ̀lú láṣẹ bí i ti Farao.
19 Moj gospod je svoje služabnike vprašal, rekoč: ›Imate očeta ali brata?‹
Olúwa mi béèrè lọ́wọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ǹjẹ́ ó ní baba tàbí arákùnrin?’
20 In mi smo mojemu gospodu rekli: ›Imamo očeta, starca in otroka njegove visoke starosti, malčka. Njegov brat je mrtev in on je sam ostal od svoje matere in njegov oče ga ljubi.‹
Àwa sì wí fún olúwa mi pé, ‘A ni baba tí ó ti darúgbó, ọmọkùnrin kan sì wà pẹ̀lú tí a bí fún un ní ọjọ́ ogbó rẹ̀. Ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀, baba rẹ̀ sì fẹ́ràn án rẹ̀.’
21 Ti pa si rekel svojim služabnikom: ›Privedite ga dol k meni, da lahko svoje oči usmerim nanj.‹
“Nígbà náà ni ó sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ mu un tọ̀ mí wá kí n le fojú ara mi rí i.’
22 Mi pa smo mojemu gospodu rekli: ›Deček ne more zapustiti svojega očeta, kajti če bi zapustil svojega očeta, bi njegov oče umrl.‹
A sì sọ fún olúwa à mi pé, ‘Ọmọkùnrin náà kò le è fi baba rẹ̀ sílẹ̀, bí ó bá dán an wò baba rẹ̀ yóò kú.’
23 Svojim služabnikom si rekel: ›Razen če pride dol z vami vaš najmlajši brat, ne boste več videli mojega obraza.‹
Ṣùgbọ́n ìwọ wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, ‘Ẹ má ṣe padà tọ̀ mí wá àyàfi bí àbíkẹ́yìn yín bá bá yín wá.’
24 Pripetilo se je, ko smo prišli gor k tvojemu služabniku, mojemu očetu, da smo mu povedali besede mojega gospoda.
Nígbà tí a padà lọ sọ́dọ̀ baba wa, tí í ṣe ìránṣẹ́ rẹ, a sọ ohun tí olúwa à mi wí fún un.
25 Naš oče je rekel: ›Pojdite ponovno in nam kupite malo hrane.‹
“Nígbà náà ni baba wa wí pé, ‘Ẹ padà lọ láti lọ ra oúnjẹ díẹ̀ wá.’
26 Mi pa smo rekli: ›Ne moremo iti dol. Če bo z nami naš najmlajši brat, potem bomo šli dol, kajti ne smemo videti moževega obraza, razen če bo z nami naš najmlajši brat.‹
Ṣùgbọ́n a wí pe, ‘Àwa kò le è padà lọ, àyàfi bí àbúrò wa pátápátá yóò bá bá wa lọ. A kò le è rí ojú ọkùnrin náà àyàfi tí àbúrò wa bá lọ pẹ̀lú wa.’
27 Tvoj služabnik, moj oče, nam je rekel: ›Vi veste, da mi je žena rodila dva sinova.
“Baba mi, ìránṣẹ́ rẹ wí fún wa pé, ‘Ẹ mọ̀ pé ìyàwó mi bí ọmọkùnrin méjì fún mi.
28 Eden je odšel od mene in rekel sem: ›Zagotovo je raztrgan na koščke‹ in od takrat ga nisem videl.
Ọ̀kan nínú wọn lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, mo sì wí pé, “Dájúdájú a ti fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.” N kò sì tí ì ri láti ọjọ́ náà.
29 Če tudi tega vzamete od mene in ga zadene nesreča, boste moje sive lase z bridkostjo privedli do groba.‹ (Sheol )
Tí ẹ bá tún mú èyí lọ, kúrò lọ́dọ̀ mi, tí ohunkóhun bá ṣe é, ìbànújẹ́ ni ẹ ó fi mú ewú orí mi lọ sí ipò òkú.’ (Sheol )
30 Zdaj torej, ko pridem k tvojemu služabniku, svojemu očetu in dečka ne bo z nami, glede na to, da je njegovo življenje vezano na življenje dečka,
“Nítorí náà, bí a bá padà tọ baba wa lọ láìsí ọmọ náà pẹ̀lú wa nígbà tí a mọ̀ pé, ọmọ náà ni ẹ̀mí baba wa.
31 se bo zgodilo, ko bo videl, da dečka ni z nami, da bo umrl. Tvoji služabniki bodo sive lase tvojega služabnika, našega očeta, z bridkostjo privedli do groba. (Sheol )
Tí ó bá ri pé ọmọkùnrin náà kò wá pẹ̀lú wa, yóò kùú. Àwọn ìránṣẹ́ rẹ yóò wá mú baba wa tòun ti ewú orí lọ sí ipò òkú ní ìbànújẹ́. (Sheol )
32 Kajti tvoj služabnik je postal pôrok za dečka mojemu očetu, rekoč: ›Če ga ne privedem k tebi, potem bom na veke prinašal krivdo svojemu očetu.‹
Ìránṣẹ́ rẹ ló ṣe onídùúró fún ààbò ọmọ náà lọ́dọ̀ baba mi. Mo wí pé, ‘Bí n kò bá mú un padà tọ̀ ọ́ wá, baba mi, èmi ó ru ẹ̀bi rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé mi!’
33 Zdaj torej, prosim te, naj tvoj služabnik ostane namesto dečka suženj mojemu gospodu, deček pa naj gre gor s svojimi brati.
“Nítorí náà, jẹ́ kí ìránṣẹ́ rẹ kí ó dúró ní ìhín lọ́dọ̀ olúwa à mi bí ẹrú dípò ọmọ náà. Kí ọmọ náà bá àwọn arákùnrin rẹ̀ padà.
34 Kajti kako bom šel k svojemu očetu, dečka pa ne bo z menoj? Da ne bi morda videl zla, ki bi prišlo na mojega očeta.«
Báwo ni mo ṣe lè padà tọ baba mi lọ láì bá ṣe pé ọmọ náà wà pẹ̀lú mi? Rárá, èmi kò fẹ́ kí n rí ìbànújẹ́ tí yóò dé bá baba mi.”