< 1 Mojzes 11 >

1 Celotna zemlja pa je bila enojezična in enega govora.
Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
2 Pripetilo se je, ko so potovali od vzhoda, da so našli ravnino v šinárski deželi in tam so prebivali.
Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
3 Rekli so drug drugemu: »Pojdimo, delajmo opeko in jih temeljito žgimo.« In opeko so imeli za kamen, blato pa so imeli za malto.
Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
4 Rekli so: »Pojdimo, zgradimo si mesto in stolp, čigar vrh bo lahko segal do neba in naredimo si ime, da ne bomo razkropljeni po obličju celotne zemlje.«
Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
5 Gospod pa je prišel dol, da vidi mesto in stolp, ki so ga gradili človeški otroci.
Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
6 Gospod je rekel: »Glej, ljudstvo je eno in vsi imajo en jezik in to so začeli delati in zdaj ne bo nič zadržano pred njimi, kar so si domislili storiti.
Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
7 Pojdimo, gremo dol in jim tam zmešajmo njihov jezik, da ne bodo mogli razumeti govora drug drugega.«
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
8 Tako jih je Gospod od tam razkropil naokoli po obličju celotne zemlje in prenehali so graditi mesto.
Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
9 Zato je ime tega mesta imenovano Babel, ker je tam Gospod zmešal jezik vse zemlje, in od tam jih je Gospod razkropil naokoli po obličju vse zemlje.
Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
10 To so Semovi rodovi. Sem je bil star sto let in dve leti po poplavi je zaplodil Arpahšáda.
Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
11 Potem ko je Sem zaplodil Arpahšáda, je živel petsto let ter zaplodil sinove in hčere.
Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
12 Arpahšád je živel petintrideset let ter zaplodil Šelaha.
Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
13 Arpahšád je, potem ko je zaplodil Šelaha, živel štiristo tri leta ter zaplodil sinove in hčere.
Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
14 Šelah je živel trideset let ter zaplodil Eberja.
Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
15 Šelah je, potem ko je zaplodil Eberja, živel štiristo tri leta ter zaplodil sinove in hčere.
Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
16 Eber je živel štiriintrideset let ter zaplodil Pelega.
Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
17 Eber je, potem ko je zaplodil Pelega, živel štiristo trideset let ter zaplodil sinove in hčere.
Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
18 Peleg je živel trideset let ter zaplodil Reguja.
Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
19 Peleg je, potem ko je zaplodil Reguja, živel dvesto devet let ter zaplodil sinove in hčere.
Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
20 Regu je živel dvaintrideset let ter zaplodil Serúga.
Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
21 Regu je, potem ko je zaplodil Serúga, živel dvesto sedem let ter zaplodil sinove in hčere.
Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
22 Serúg je živel trideset let ter zaplodil Nahórja.
Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
23 Serúg je, potem ko je zaplodil Nahórja, živel dvesto let ter zaplodil sinove in hčere.
Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
24 Nahór je živel devetindvajset let ter zaplodil Teraha.
Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
25 Nahór je, potem ko je zaplodil Teraha, živel sto devetnajst let ter zaplodil sinove in hčere.
Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
26 Terah je živel sedemdeset let ter zaplodil Abrama, Nahórja in Harána.
Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
27 Torej to so Terahovi rodovi. Terah je zaplodil Abrama, Nahórja in Harána; Harán pa je zaplodil Lota.
Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
28 Harán je umrl pred svojim očetom Terahom v deželi svojega rojstva, v Uru Kaldejcev.
Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
29 Abram in Nahór sta si vzela ženi. Ime Abramove žene je bilo Sarája; in ime Nahórjeve žene Milka, hči Harána, Milkinega očeta in Jiskinega očeta.
Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
30 Toda Sarája je bila jalova; ni imela nobenega otroka.
Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
31 Terah je vzel Abrama, svojega sina in vnuka Lota, Haránovega sina in svojo snaho Sarájo, ženo svojega sina Abrama in odšli so iz Ura Kaldejcev, da gredo v kánaansko deželo in prišli so v Harán ter tam prebivali.
Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
32 Terahovih dni je bilo dvesto pet let, in Terah je umrl v Haránu.
Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.

< 1 Mojzes 11 >