< Ezekiel 25 >
1 Beseda Gospodova je ponovno prišla k meni, rekoč:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 »Človeški sin, naravnaj svoj obraz proti Amóncem in prerokuj zoper njih;
“Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
3 in reci Amóncem: ›Poslušajte besedo Gospoda Boga. Tako govori Gospod Bog, ker praviš: ›Aha, zoper moje svetišče, ko je bilo oskrunjeno; in zoper Izraelovo deželo, ko je bila zapuščena; in zoper Judovo hišo, ko so odšli v ujetništvo; ‹
Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
4 glej, zatorej te bom izročil možem vzhoda za posest in v tebi si bodo postavili svoje palače in svoja prebivališča bodo naredili v tebi. Jedli bodo tvoj sad in pili bodo tvoje mleko.
kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
5 In jaz bom Rabo naredil hlev za kamele in Amónce kraj ležišča za trope, in spoznali boste, da jaz sem Gospod.‹
Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
6 Kajti tako govori Gospod Bog: ›Ker si ploskal s svojima rokama in topotal s stopali in se razveseljeval v srcu z vsem svojim prezirom zoper Izraelovo deželo;
Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
7 glej, zato bom nadte iztegnil svojo roko in te izročil v plen poganom; in jaz te bom odrezal izmed ljudstev in ti povzročil, da izgineš iz dežel. Uničil te bom, in vedel boš, da jaz sem Gospod.‹
nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
8 Tako govori Gospod Bog: ›Zato ker Moáb in Seír govorita: ›Glej, Judova hiša je podobna vsem poganom; ‹
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
9 zatorej, glej, odprl bom Moábov bok od mest, od njegovih mest, ki so na njegovih mejah, slavo dežele: Bet Ješimót, Báal Meón in Kirjatájim,
nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
10 do mož vzhoda z Amónci [vred] in jih dal v posest, da se Amóncev ne bo spominjalo med narodi.
Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
11 In izvršil bom sodbe nad Moábom; in spoznali bodo, da jaz sem Gospod.‹
Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
12 Tako govori Gospod Bog: ›Zato ker je Edóm zoper Judovo hišo ravnal z maščevanjem in [jih] silno užalil in se maščeval nad njimi; ‹
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
13 zato tako govori Gospod Bog: ›Tudi jaz bom svojo roko iztegnil nad Edóm in iz njega bom iztrebil moža in žival; in opustošil ga bom od Temána; in tisti iz Dedána bodo padli pod mečem.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
14 In svoje maščevanje bom položil nad Edóm po roki svojega ljudstva Izraela, in v Edómu bodo storili glede na mojo jezo in glede na mojo razjarjenost; in spoznali bodo moje maščevanje, ‹ govori Gospod Bog.
Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
15 Tako govori Gospod Bog: ›Ker so Filistejci postopali z maščevanjem in so se maščevali s krutim srcem, da ga uničijo zaradi starega sovraštva; ‹
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
16 zato tako govori Gospod Bog: ›Glej, svojo roko bom iztegnil nad Filistejce in iztrebil bom Keretéjce in uničil bom preostanek morske obale.
nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
17 In nad njimi bom izvršil veliko maščevanje z besnimi grajami; in spoznali bodo, da jaz sem Gospod, ko bom nanje položil svoje maščevanje.‹«
Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”