< 2 Mojzes 12 >
1 Gospod je spregovoril Mojzesu in Aronu v egiptovski deželi, rekoč:
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni ni ilẹ̀ Ejibiti pé,
2 »Ta mesec vam bo začetek mesecev. Ta vam bo prvi mesec v letu.
“Oṣù yìí ni yóò jẹ́ oṣù àkọ́kọ́ fún yín, oṣù àkọ́kọ́ nínú ọdún yín.
3 Govorita vsej Izraelovi skupnosti, rekoč: ›V desetem dnevu tega meseca si bo vsakdo vzel jagnje, glede na hišo svojih očetov, jagnje za hišo‹
Sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli pé ni ọjọ́ kẹwàá oṣù yìí, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan yóò mú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan fún ìdílé rẹ̀, ọ̀kan fún agbo ilé kọ̀ọ̀kan.
4 in če bo družina premajhna za jagnje, naj ga on in njegov sosed, poleg njegove hiše, vzameta glede na število duš. Vsak človek bo glede na svoje prehranjevanje preštet na jagnje.
Bí ìdílé kan bá kéré jù fún odidi ọ̀dọ́-àgùntàn kan, kí wọn kí ó ṣe àjọpín ọ̀kan pẹ̀lú aládùúgbò wọn ti ó sun mọ́ wọn kí wọ́n lo iye ènìyàn tiwọn jẹ láti ṣe òdínwọ̀n irú ọ̀dọ́-àgùntàn tiwọn yóò lò ní ìbámu pẹ̀lú ìwọ̀n ti ẹni kọ̀ọ̀kan lè jẹ.
5 Vaše jagnje bo brez pomanjkljivosti, samec prvega leta. Vzeli ga boste izmed ovc ali izmed koz.
Ọ̀dọ́-àgùntàn tí ìwọ yóò mú gbọdọ̀ jẹ́ akọ ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, ìwọ lè mú lára àgbò tàbí ewúrẹ́.
6 Varovali ga boste do štirinajstega dne istega meseca in celoten zbor Izraelove skupnosti ga bo zvečer zaklal.
Ṣe ìtọ́jú wọn títí di ọjọ́ kẹrìnlá oṣù yìí nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò pa ẹran náà ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
7 Vzeli bodo od krvi in le-to potegnili s črto na dva podboja in na naddurje hiš, v katerih ga bodo jedli.
Wọn yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ ẹran náà, wọn yóò fi kan ẹ̀gbẹ́ méjèèjì àti òkè ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé níbi tí wọ́n bá ti jẹ ẹran ọ̀dọ́-àgùntàn náà.
8 In v tej noči bodo jedli meso, pečeno na ognju in nekvašen kruh, in z grenkimi zelišči ga bodo jedli.
Ní òru ọjọ́ kan náà, wọn yóò jẹ ẹran tí a ti fi iná sun, pẹ̀lú ewé ewúro àti àkàrà aláìwú.
9 Ne jejte od njega surovega niti vsega skuhanega z vodo, temveč pečenega na ognju. Njegovo glavo z njegovimi nogami in z njegovo drobovino.
Ẹ má ṣe jẹ ẹran náà ni tútù tàbí ní bíbọ̀ nínú omi, ṣùgbọ́n kí ẹ fi iná sun orí, ẹsẹ̀ àti àwọn nǹkan inú ẹran náà.
10 In ničesar od njega ne boste pustili do jutra. To, kar od njega ostane do jutra, boste sežgali z ognjem.
Ẹ má ṣe fi èyíkéyìí sílẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, bí ó bá ṣẹ́kù di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, kí ẹ jó o níná.
11 Tako ga boste jedli: z vašimi ledji opasanimi, vašimi čevlji na vaših stopalih in vašo palico v vaši roki. Jedli ga boste v naglici. To je Gospodova pasha.
Báyìí ni ẹ̀yìn yóò ṣe jẹ́ tí ẹ̀yin ti àmùrè ní ẹ̀gbẹ́ yín, sáńdà yín ní ẹsẹ̀ yín àti ọ̀pá yín ni ọwọ́ yín. Ẹ yára jẹ ẹ́, oúnjẹ àjọ ìrékọjá Olúwa ni.
12 Kajti to noč pojdem skozi egiptovsko deželo in udaril bom vse prvorojeno v egiptovski deželi, tako človeka kakor žival in zoper vse egiptovske bogove bom izvršil sodbo. Jaz sem Gospod.
“Ní òru ọjọ́ yìí kan náà ni Èmi yóò la gbogbo ilẹ̀ Ejibiti kọjá, èmi yóò sì pa gbogbo àkọ́bí àti ènìyàn, àti ẹranko, èmi yóò mú ìdájọ́ wà sí orí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Ejibiti. Èmi ni Olúwa.”
13 Kri vam bo za simbol na hišah, kjer ste. Ko zagledam kri, bom šel mimo vas in nadloga ne bo na vas, da vas uniči, ko udarim egiptovsko deželo.
Ẹ̀jẹ̀ ni yóò jẹ́ àmì fún un yín ní àwọn ilé tí ẹ̀yin wà, nígbà tí èmi bá rí ẹ̀jẹ̀ náà, Èmi yóò ré e yín kọjá. Ààrùn kan kì yóò kàn yín nígbà tí èmi bá kọlu Ejibiti láti pa wọ́n run.
14 Ta dan vam bo v spomin, in vi ga boste ohranjali kot praznik Gospodu skozi svoje rodove. To praznovanje boste ohranjali kot odredbo na veke.
“Ọjọ́ òní ni yóò sì máa ṣe ọjọ́ ìrántí fún yín, ẹ́yin yóò sì máa láàrín àwọn ìran tí ó ń bọ̀ lẹ́yìn ni ẹ̀yin yóò ti máa ṣe ní àjọ fún Olúwa; ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
15 Sedem dni boste jedli nekvašeni kruh; celo prvi dan boste iz svojih hiš odstranili kvas, kajti kdorkoli jé kvašeni kruh od prvega dne do sedmega dne, bo ta duša iztrebljena iz Izraela.
Fún ọjọ́ méje ni ẹ̀yin yóò fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, ẹ ó gbé ìwúkàrà kúrò ni ilé yín, nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohunkóhun tí ó ni ìwúkàrà nínú láti ọjọ́ kìn-ín-ní di ọjọ́ keje ni kí a yọ kúrò ni Israẹli.
16 Na prvi dan bo sveti sklic in na sedmi dan vam bo sveti sklic. V teh ne bo opravljena nobena vrsta dela, razen tega, kar mora vsak človek jesti, samo to lahko delate.
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; àti ní ọjọ́ keje àpéjọ mímọ́ mìíràn yóò wà fún yín. Ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ kan ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, bí kò ṣe oúnjẹ tí olúkúlùkù yóò jẹ; kìkì èyí ni gbogbo ohun tí ẹ̀yin lè ṣe.
17 Obeležili boste praznik nekvašenega kruha, kajti na prav isti dan sem vaše vojske privedel iz egiptovske dežele. Zato boste ta dan v svojih rodovih obeleževali kot odredbo na veke.
“Ẹ ó sì kíyèsí àjọ àìwúkàrà, nítorí ní ọjọ́ náà gan an ni mo mú ogun yín jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti. Nítorí náà ni kí ẹ máa kíyèsi ọjọ́ náà ní ìran-ìran yín bí ìlànà tí yóò wà títí ayé.
18 V prvem mesecu, na štirinajsti dan meseca zvečer, boste jedli nekvašeni kruh do enaindvajsetega dne meseca zvečer.
Àkàrà ti kò ni ìwúkàrà ni ẹ̀yin yóò jẹ láti ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kẹrìnlá títí di ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kọ̀kànlélógún oṣù àkọ́kọ́.
19 Sedem dni naj v vaših hišah ne bo najti kvasa, kajti kdorkoli jé to, kar je kvašeno, celo ta duša bo iztrebljena iz Izraelove skupnosti, bodisi da je tujec ali rojen v deželi.
Fún ọjọ́ méje ni ẹ kò gbọdọ̀ ni ìwúkàrà nínú ilé yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ohun tí ó ni ìwúkàrà nínú ni a ó yọ kúrò ni àárín àwùjọ Israẹli, ìbá à ṣe àlejò tàbí ẹni tí a bí ní ilẹ̀ náà.
20 Ničesar kvašenega ne boste jedli. V vseh svojih prebivališčih boste jedli nekvašeni kruh.«
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi ìwúkàrà ṣe. Ní ibikíbi tí ẹ̀yin bá ń gbé, kí ẹ̀yin kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.”
21 Potem je Mojzes dal poklicati vse Izraelove starešine in jim rekel: »Izberite in vzemite si jagnje glede na svoje družine in zakoljite pashalno jagnje.
Ní ìgbà náà ni Mose pé gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ jáde lọ, kí ẹ sì yan ọ̀dọ́-àgùntàn fún àwọn ìdílé yín, kí ẹ sì pa ẹran àjọ ìrékọjá Olúwa.
22 Vzeli boste šop izopa in ga pomočili v kri, ki je v umivalniku in vratno preklado ter dva podboja premazali s krvjo, ki je v umivalniku; in nihče izmed vas do jutra ne bo šel ven pri vratih svoje hiše.
Ẹ̀yin yóò sì mú ìdí-ewé hísópù, ẹ tì í bọ inú ẹ̀jẹ̀ tí ó wà nínú ọpọ́n kí ẹ sì fi kun òkè à bá wọ ẹnu-ọ̀nà ilé yín àti ẹ̀gbẹ́ méjèèjì ìlẹ̀kùn yín. Ẹnikẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ jáde sí òde títí di òwúrọ̀.
23 Kajti Gospod bo šel skozi, da udari Egipčane in ko na vratni prekladi in dveh stranskih podbojih zagleda kri, bo Gospod šel mimo vrat in ne bo dopustil, da bi pokončevalec vstopil v vaše hiše, da vas udari.
Ní ìgbà tí Olúwa bá ń lọ káàkiri ní ilẹ̀ Ejibiti láti kọlù wọn, yóò rí ẹ̀jẹ̀ ni òkè ẹnu-ọ̀nà àti ni ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà ilé yín, yóò sì ré ẹnu-ọ̀nà ilé náà kọjá, kì yóò gba apanirun láààyè láti wọ inú ilé e yín láti kọlù yín.
24 Vi pa boste to stvar obeležili kot odredbo sebi in svojim sinovom na veke.
“Ẹ pa ìlànà yìí mọ́ gẹ́gẹ́ bí ohun tí ẹ ó máa ṣe títí ayérayé láàrín yín àti àwọn ìran yín.
25 In zgodilo se bo, ko boste prišli v deželo, ki vam jo bo dal Gospod, glede [na to], kar je obljubil, da boste ohranjali to službo.
Nígbà tí ẹ̀yin bá de ilẹ̀ tí Olúwa yóò fi fún un yín bí òun ti ṣe ìlérí, ẹ máa kíyèsi àjọ yìí.
26 Zgodilo se bo, ko vam bodo vaši otroci rekli: ›Kaj nameravate s tem služenjem?‹
Ní ìgbà tí àwọn ọmọ yín bá béèrè lọ́wọ́ yín, ‘Kí ni ohun tí àjọ yìí túmọ̀ sí fún un yín?’
27 da boste rekli: ›To je klavna daritev pashe Gospodu, ki je v Egiptu šel mimo hiš Izraelovih otrok, ko je udaril Egipčane in rešil naše hiše.‹« In ljudstvo je sklonilo glavo ter oboževalo.
Ẹ sọ fún wọn ni ìgbà náà, ‘Ẹbọ ìrékọjá sí Olúwa ni, ẹni tí ó rékọjá ilé àwọn ọmọ Israẹli ni ìgbà tí ó kọlu àwọn ara Ejibiti. Tí ó si da wa sí nígbà ti ó pa àwọn ara Ejibiti.’” Àwọn ènìyàn sì tẹríba láti sìn.
28 Izraelovi otroci so odšli in storili, kakor je Gospod zapovedal Mojzesu in Aronu, tako so storili.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
29 Pripetilo se je, da je ob polnoči Gospod udaril vse prvorojeno v egiptovski deželi, od faraonovega prvorojenca, ki je sedel na njegovem prestolu, do ujetnikovega prvorojenca, ki je bil v grajski ječi in vse prvorojeno od živine.
Ní ọ̀gànjọ́ òru Olúwa kọlu gbogbo àwọn àkọ́bí ilẹ̀ Ejibiti, láti orí àkọ́bí. Farao tí ó wà ní orí ìtẹ́ títí dé orí àkọ́bí ẹlẹ́wọ̀n tí ó wà nínú túbú àti àkọ́bí ẹran ọ̀sìn pẹ̀lú.
30 Faraon je ponoči vstal, on in vsi njegovi služabniki in vsi Egipčani in v Egiptu je bilo veliko vpitje, kajti ni bilo hiše, kjer ni bi bilo enega mrtvega.
Farao àti àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn ara Ejibiti dìde ní ọ̀gànjọ́ òru, igbe ẹkún ńlá sì gba gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, nítorí kò sí ilé kan tí ó yọ sílẹ̀ tí ènìyàn kan kò ti kú.
31 Ponoči je dal poklicati Mojzesa in Arona ter rekel: »Vstanite in odpravite se proč izmed mojega ljudstva, tako vidva kakor Izraelovi otroci in pojdite, služite Gospodu, kakor sta rekla.
Farao sì ránṣẹ́ pe Mose àti Aaroni ní òru, ó sì wí pé, “Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi ẹ̀yin àti àwọn ènìyàn Israẹli! Ẹ lọ láti sin Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹ ti béèrè.
32 Prav tako vzemite vaše trope in vaše črede, kakor sta rekla in izginite; in tudi mene blagoslovita.«
Ẹ kó agbo àgùntàn yín àti agbo màlúù yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti sọ, kí ẹ sì máa lọ, kí ẹ sì súre fún mi.”
33 Egipčani so pritiskali na ljudstvo, da bi jih lahko v naglici odposlali iz dežele, kajti rekli so: »Mi vsi bomo mrtvi ljudje.«
Àwọn ara Ejibiti ń rọ àwọn ènìyàn náà láti yára máa lọ kúrò ní ilẹ̀ wọn. Wọ́n wí pé, “Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ gbogbo wa ni yóò kú!”
34 Ljudstvo je vzelo svoje testo, preden je bilo to vzhajano in svoje nečke, ki so bile povezane v njihovih oblačilih, na svoje rame.
Àwọn ènìyàn náà sì mú ìyẹ̀fun púpọ̀ kí wọn tó fi ìwúkàrà sí i, wọ́n gbe le èjìká wọn nínú ọpọ́n tí wọ́n ti fi aṣọ dì.
35 Izraelovi otroci so storili glede na Mojzesovo besedo in od Egipčanov so si izposodili dragocenosti iz srebra in dragocenosti iz zlata in oblačil.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ti sọ fún wọn. Wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ ará Ejibiti fún ohun èlò fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ pẹ̀lú.
36 In Gospod je dal ljudstvu naklonjenost v očeh Egipčanov, tako da so jim posodili takšne stvari, kot so jih zahtevali. In oplenili so Egipčane.
Olúwa ti mú kí àwọn ènìyàn yìí rí ojúrere àwọn ará Ejibiti wọ́n sì fún wọn ní ohun tí wọ́n béèrè fún, wọ́n sì ko ẹrù àwọn ará Ejibiti.
37 Izraelovi otroci so potovali od Ramesésa do Sukóta, okoli šeststo tisoč pešcev, ki so bili možje, poleg otrok.
Àwọn ọmọ Israẹli sì rìn láti Ramesesi lọ sí Sukkoti. Àwọn ọkùnrin tó ń fi ẹsẹ̀ rìn tó ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ni iye láìka àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé.
38 Z njimi je odšla gor tudi mešana množica, tropi in črede, zelo veliko živine.
Ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn ni ó bá wọ́n lọ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹran ọ̀sìn, agbo àgùntàn àti agbo màlúù.
39 Iz testa, ki so ga prinesli iz Egipta, so spekli nekvašeni kruh, kajti ni bil še vzhajan, ker so bili sunjeni iz Egipta in niso mogli ostati niti si zase niso pripravili nobenega živeža.
Pẹ̀lú ìyẹ̀fun tí kò ní ìwúkàrà nínú tí wọ́n gbé jáde láti Ejibiti wá ni wọ́n fi ṣe àkàrà aláìwú. Ìyẹ̀fun náà kò ni ìwúkàrà nínú nítorí a lé wọn jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wọn kò si rí ààyè láti tọ́jú oúnjẹ fún ara wọn.
40 Torej začasno bivanje Izraelovih otrok, ki so prebivali v Egiptu, je bilo štiristo trideset let.
Iye ọdún ti àwọn ará Israẹli gbé ní ilẹ̀ Ejibiti jẹ́ irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n.
41 Ob koncu štiristo tridesetih let se je pripetilo, celo prav na isti dan se je pripetilo, da so vse Gospodove vojske odšle iz egiptovske dežele.
Ó sì ní òpin irinwó ọdún ó le ọgbọ̀n, ní ọjọ́ náà gan an, ni ó sì ṣe tí gbogbo ogun Olúwa jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
42 To je noč, ki bo zelo obeleževana Gospodu, ker jih je privedel iz egiptovske dežele. To je tista Gospodova noč, ki jo bodo obeleževali vsi Izraelovi otroci v svojih rodovih.
Nítorí pé, Olúwa ṣe àìsùn ni òru ọjọ́ náà láti mú wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní òru yìí ni gbogbo Israẹli ní láti máa ṣe àìsùn láti fi bu ọlá fún Olúwa títí di àwọn ìran tí ń bọ̀.
43 Gospod je rekel Mojzesu in Aronu: »To je odredba pashe: ›Naj noben tujec od tega ne jé,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé, “Ìwọ̀n yìí ni àwọn òfin fún àjọ ìrékọjá: “Àjèjì kò gbọdọ̀ jẹ nínú rẹ̀.
44 toda vsakogar služabnik, ki je kupljen za denar, ko si ga obrezal, potem bo jedel od tega.
Ẹrú tí ẹ̀yin bá rà lè jẹ́ nínú rẹ̀ lẹ́yìn tí ẹ̀yin bá ti kọ ọ́ ní ilà,
45 Tuj človek in najeti služabnik ne bosta jedla od tega.
ṣùgbọ́n àtìpó àti alágbàṣe kò ni jẹ nínú rẹ̀.
46 Jedlo se ga bo v eni hiši. Nič od mesa ne boš nosil ven iz hiše niti ne boste prelomili njegove kosti.
“Nínú ilé ni ẹ ti gbọdọ̀ jẹ ẹ́; ẹ kò gbọdọ̀ mú èyíkéyìí nínú ẹran náà jáde kúrò nínú ilé. Ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan nínú egungun rẹ̀.
47 Vsa Izraelova skupnost se bo tega držala.
Gbogbo àjọ Israẹli ni ó gbọdọ̀ ṣe àjọyọ̀ ọ rẹ̀.
48 Ko bo tujec začasno prebival s teboj in bo praznoval pasho Gospodu, naj bodo vsi njegovi moški obrezani in takrat pustite, da pride blizu in se tega drži, in on naj vam bo kakor nekdo, ki je rojen v deželi, kajti nobena neobrezana oseba ne bo jedla od tega.
“Àjèjì ti ó bá ń gbé ní àárín yín ti ó bá fẹ́ kópa nínú àjọ ìrékọjá Olúwa, ni o gbọdọ̀ kọ gbogbo àwọn ọmọkùnrin ilé rẹ̀ ní ilà; ní ìgbà náà ni ó lè kó ipa gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ tí a bí ní ilẹ̀ náà. Gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí a kò bá kọ ní ilà, wọ́n kò ni jẹ nínú rẹ̀.
49 Ena postava bo tistemu, ki je rojen doma in tujcu, ki začasno biva med vami.‹«
Òfin yìí kan náà ni ó mú àwọn ọmọ tí a bí ni ilẹ̀ náà àti àwọn àlejò tí ń gbé ní àárín yín.”
50 Tako so storili vsi Izraelovi otroci; kakor je Gospod zapovedal Mojzesu in Aronu, tako so storili.
Gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose àti Aaroni.
51 Na prav isti dan se je pripetilo, da je Gospod privedel Izraelove otroke po njihovih vojskah iz egiptovske dežele.
Àti pé ní ọjọ́ náà gan an ni Olúwa mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti gẹ́gẹ́ bí ìpín ìpín wọn.