< Estera 3 >

1 Po teh stvareh je Kralj Ahasvér povišal Hamána, Hamedátovega sina, Agágovca in ga napredoval in njegov sedež postavil nad vse prince, ki so bili z njim.
Lẹ́yìn àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ wọ̀nyí, ọba Ahaswerusi dá Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi lọ́lá, ọba gbé e ga, ó si fún un ní àga ọlá tí ó ju ti gbogbo àwọn ọlọ́lá tókù lọ.
2 Vsi kraljevi služabniki, ki so bili pri kraljevih velikih vratih, so se priklonili in častili Hamána, kajti kralj je glede njega tako zapovedal. Mordohaj pa se ni priklonil niti ga ni častil.
Gbogbo àwọn ìjòyè ọba tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ọba wọn kúnlẹ̀ wọ́n sì fi ọlá fun Hamani, nítorí ọba ti pàṣẹ èyí nípa tirẹ̀. Ṣùgbọ́n Mordekai kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún un.
3 Potem so kraljevi služabniki, ki so bili pri kraljevih velikih vratih, Mordohaju rekli: »Zakaj prestopaš kraljevo zapoved?«
Nígbà náà ni àwọn ìjòyè ọba tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà béèrè lọ́wọ́ Mordekai pé, “Èéṣe tí ìwọ kò ṣe pa àṣẹ ọba mọ́.”
4 Pripetilo se je torej, ko so mu dnevno govorili in jim ni prisluhnil, da so povedali Hamánu, da vidijo, ali bodo Mordohajeve zadeve obstale, kajti povedal jim je, da je bil Jud.
Ní ojoojúmọ́ ni wọ́n máa n sọ fún un ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti ṣe bẹ́ẹ̀. Nítorí náà, wọ́n sọ fún Hamani nípa rẹ̀ láti wò ó bóyá ó lè gba irú ìwà tí Mordekai ń hù yìí, nítorí tí ó ti sọ fún wọn pé Júù ni òun.
5 Ko je Hamán videl, da se Mordohaj ni priklonil niti ga ni častil, potem je bil Hamán poln besa.
Nígbà tí Hamani rí i pé Mordekai kò ní kúnlẹ̀ tàbí bu ọlá fún òun, ó bínú.
6 Zdelo se mu je v posmeh, da položi roke samo na Mordohaja, kajti pokazali so mu Mordohajevo ljudstvo. Zato je Hamán iskal, da uniči vse Jude, ki so bili po celotnem Ahasvérjevem kraljestvu, torej Mordohajevo ljudstvo.
Síbẹ̀ kò mọ irú ènìyàn tí Mordekai jẹ́, ó kẹ́gàn láti pa Mordekai nìkan. Dípò bẹ́ẹ̀ Hamani ń wá láti pa gbogbo ènìyàn Mordekai run, àwọn Júù jákèjádò gbogbo ìjọba Ahaswerusi.
7 V prvem mesecu, ki je mesec nisán, v dvanajstem letu kralja Ahasvérja, so metali pur, kar je žreb, pred Hamánom iz dneva v dan in iz meseca v mesec, do dvanajstega meseca, ki je mesec adár.
Ní ọdún kejìlá ọba Ahaswerusi, ní oṣù kìn-ín-ní, èyí ni oṣù Nisani, wọ́n da puri (èyí tí í ṣe, ìbò) ní iwájú Hamani láti yan ọjọ́ kan àti oṣù, ìbò náà sì wáyé ní oṣù kejìlá, oṣù Addari.
8 Hamán je rekel Kralju Ahasvérju: »Tam je neko ljudstvo, razkropljeno naokoli in razpršeno med ljudstvom po vseh provincah tvojega kraljestva. Njihove postave so različne od vsega ljudstva niti se ne držijo kraljevih postav. Zatorej to ni za kraljevo korist, da jih trpi.
Nígbà náà ni Hamani sọ fún ọba Ahaswerusi pé, “Àwọn ènìyàn kan wà tí wọ́n fọ́nká tí wọ́n sì túká ní ara àwọn ènìyàn ní gbogbo àgbáyé ìjọba rẹ̀ tí ìṣe wọn yàtọ̀ sí ti gbogbo àwọn tókù tí wọn kò sì pa òfin ọba mọ́; èyí kì í ṣe ìfẹ́ ọba láti gbà fún wọn bẹ́ẹ̀.
9 Če to ugaja kralju, naj bo to zapisano, da bodo lahko uničeni, jaz pa bom plačal deset tisoč talentov srebra rokam tistih, ki so zadolženi za to delo, da to prinesejo v kraljeve zakladnice.«
Tí ó bá tẹ́ ọba lọ́rùn, kí a gbé òfin kan jáde tí yóò pa wọ́n run, èmi yóò sì fi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá tálẹ́ǹtì fàdákà sínú ìṣúra ọba fún àwọn ọkùnrin tí wọn o ṣe iṣẹ́ náà.”
10 Kralj je iz svoje roke snel svoj prstan ter ga dal Hamedátovemu sinu Hamánu, Agágovcu, sovražniku Judov.
Nítorí náà, ọba sì bọ́ òrùka èdìdì tí ó wà ní ìka rẹ̀, ó sì fi fún Hamani ọmọ Hammedata, ará Agagi, ọ̀tá àwọn Júù.
11 Kralj je rekel Hamánu: »Srebro ti je dano, tudi ljudstvo, da storiš z njimi, kakor se ti zdi dobro.«
Ọba sọ fún Hamani pé, “Pa owó náà mọ́, kí o sì ṣe ohun tí ó wù ọ́ fún àwọn ènìyàn náà.”
12 Potem so bili na trinajsti dan prvega meseca poklicani kraljevi pisarji in bilo je napisano glede na vse, kar je Hamán ukazal kraljevim poročnikom in voditeljem, ki so bili nad vsako provinco in vladarjem vsakega ljudstva vsake province, glede na njihovo pisavo in vsakemu ljudstvu glede na njihov jezik. V imenu kralja Ahasvérja je bilo napisano in zapečateno s kraljevim prstanom.
Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹtàlá oṣù kìn-ín-ní àkọ́kọ́, wọ́n pe àwọn akọ̀wé ọba jọ. Wọ́n kọ ọ́ ní ìlànà bí ìgbèríko kọ̀ọ̀kan ṣe ń kọ̀wé, ó kọ̀wé sí àwọn ènìyàn kọ̀ọ̀kan ní èdè wọn gbogbo èyí tí Hamani ti pàṣẹ sí àwọn akọ̀wé ọba, sí baálẹ̀ ìgbèríko kọ̀ọ̀kan àti àwọn ọlọ́lá àwọn onírúurú ènìyàn. A kọ èyí ní orúkọ ọba Ahaswerusi fúnra rẹ̀ ó sì fi òrùka ọba ṣe èdìdì i rẹ̀.
13 Pisma so bila po slih poslana v vse kraljeve province, da uničijo, ubijejo in pogubijo vse Jude, tako mlade kakor stare, majhne otroke in ženske, na en dan, torej na trinajsti dan dvanajstega meseca, ki je mesec adár in da si njihov dobiček vzamejo za plen.
A sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìgbèríko ọba pẹ̀lú àṣẹ láti parun, láti pa gbogbo àwọn Júù èwe àti àgbà, obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́—ní ọjọ́ kan kí wọn sì parẹ́, ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kejìlá, oṣù Addari kí a sì kó àwọn ohun ìní wọn.
14 Prepis pisanja za zapoved, ki naj bo predana v vsako provinco, je bilo razglašeno vsem ljudstvom, da bodo pripravljeni za ta dan.
Kí ẹ mú àdàkọ ìwé náà kí a tẹ̀ ẹ́ jáde bí òfin ní gbogbo ìgbèríko kí ó sì di mí mọ̀ fún àwọn ènìyàn ìlú nítorí kí wọ́n le múra fún ọjọ́ náà.
15 Sli so odšli ven, podvizani s kraljevo zapovedjo in odlok je bil izdan v palači Suze. Kralj in Hamán pa sta se usedla, da pijeta, mesto Suze pa je bilo zbegano.
Àwọn ìránṣẹ́ náà sì jáde, wọ́n tẹ̀síwájú nípa àṣẹ ọba, ìkéde náà sì jáde ní ilé ìṣọ́ ti Susa. Ọba àti Hamani jókòó wọ́n ń mu, ṣùgbọ́n ìlú Susa wà nínú ìdààmú.

< Estera 3 >