< 5 Mojzes 9 >

1 Poslušaj, oh Izrael: ›Danes prečkaš Jordan, da vstopiš in vzameš v last narode, večje in močnejše kakor ti, velika mesta in ograjena do neba,
Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
2 veliko in visoko ljudstvo, otroke Anákovcev, ki jih poznaš in o katerih si slišal reči: ›Kdo lahko stoji pred Anákovimi otroki!‹
Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
3 Razumi torej ta dan, da je Gospod, tvoj Bog, tisti, ki gre preko pred teboj. Kakor požirajoč ogenj jih bo uničil in on jih bo privedel dol, pred tvoj obraz. Tako jih boš pognal ven in jih hitro uničil, kakor ti je rekel Gospod.
Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
4 Ne govori v svojem srcu, potem ko jih je Gospod, tvoj Bog, spodil izpred tebe, rekoč: ›Zaradi moje pravičnosti me je Gospod privedel, da vzamem v last to deželo, ‹ temveč jih je zaradi zlobnosti teh narodov Gospod pognal izpred tebe.
Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
5 Ne greš, da zaradi svoje pravičnosti ali zaradi poštenosti svojega srca vzameš v last njihovo deželo, temveč zaradi zlobnosti teh narodov jih je Gospod, tvoj Bog, pognal izpred tebe in da lahko izpolni besedo, ki jo je Gospod prisegel tvojim očetom, Abrahamu, Izaku in Jakobu.
Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
6 Razumi torej, da ti Gospod, tvoj Bog, te dobre zemlje ne daje v posest zaradi tvoje pravičnosti, kajti ti si trdovratno ljudstvo.
Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
7 Zapomni si in ne pozabi, kako si v divjini do besa dražil Gospoda, svojega Boga. Od dneva, ko si odšel iz egiptovske dežele, dokler niste prišli na ta kraj, ste bili uporni zoper Gospoda.
Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
8 Tudi na Horebu ste do besa izzivali Gospoda, tako da je bil Gospod nad vami jezen, da vas uniči.
Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
9 Ko sem odšel gor na goro, da prejmem kamniti plošči, torej plošči zaveze, ki jo je Gospod sklenil z vami, potem sem na gori ostal štirideset dni in štirideset noči niti nisem jedel kruha niti pil vode.
Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
10 In Gospod mi je izročil dve kamniti plošči, popisani z Božjim prstom. Na njima je bilo napisano glede na vse besede, ki jih je Gospod z vami govoril na gori, iz srede ognja, na dan zbora.
Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
11 Ob koncu štiridesetih dni in štiridesetih noči se je pripetilo, da mi je Gospod dal dve kamniti plošči, torej plošči zaveze.
Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
12 Gospod mi je rekel: ›Vstani, hitro se spusti od tod, kajti tvoje ljudstvo, ki si jih privedel iz Egipta, se je izpridilo. Hitro so se obrnili proč iz poti, ki sem jim jo zapovedal. Naredili so si ulito podobo.‹
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
13 Nadalje mi je Gospod spregovoril, rekoč: ›Videl sem to ljudstvo in glej, to je trdovratno ljudstvo.
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
14 Pusti me pri miru, da jih lahko uničim in njihovo ime izbrišem izpod neba. Iz tebe pa bom naredil narod, mogočnejši in večji kakor oni.‹
Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
15 Tako sem se obrnil in prišel dol z gore in gora je gorela z ognjem in dve tabli zaveze sta bili v mojih dveh rokah.
Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
16 Pogledal sem in glej, grešili ste zoper Gospoda, svojega Boga in si naredili ulito tele. Hitro ste se obrnili proč iz poti, ki vam jo je zapovedal Gospod.
Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
17 Vzel sem dve plošči in ju vrgel iz svojih dveh rok ter ju razbil pred vašimi očmi.
Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
18 In padel sem dol pred Gospodom, kakor prvič, štirideset dni in štirideset noči. Niti nisem jedel kruha niti nisem pil vode zaradi vseh vaših grehov, ki ste jih z zlobnim početjem zagrešili v Gospodovih očeh, da ga izzivate k jezi.
Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
19 Kajti bal sem se jeze in silnega nezadovoljstva, s katerim je bil Gospod ogorčen zoper vas, da vas uniči. Toda Gospod mi je tudi ob tistem času prisluhnil.
Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Gospod je bil zelo jezen nad Aronom, da bi ga uničil, jaz pa sem isti čas molil za Arona.
Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
21 Vzel sem vaš greh, tele, ki ste ga naredili in ga sežgal z ognjem in ga poteptal in ga zelo drobno zmlel, dokler ni bil ta majhen kakor prah, in njegov prah sem vrgel v potok, ki se spušča z gore.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
22 In pri Tabêri, pri Masi in pri Kibrot-Hattaavi ste do besa izzivali Gospoda.
Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
23 Podobno, ko vas je Gospod poslal iz Kadeš Barnée, rekoč: ›Pojdite gor in vzemite v last deželo, ki sem vam jo dal.‹ Potem ste se uprli zoper zapoved Gospoda, svojega Boga in mu niste verjeli niti niste prisluhnili njegovemu glasu.
Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
24 Od dneva, ko sem vas spoznal, ste bili uporni zoper Gospoda.
Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
25 Tako sem padel dol pred Gospodom, štirideset dni in štirideset noči, kakor sem prvič padel dol, ker je Gospod rekel, da vas bo uničil.
Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
26 Molil sem torej h Gospodu in rekel: ›Oh Gospod Bog, ne uniči svojega ljudstva in svoje dediščine, ki si jo odkupil preko svoje veličine, ki si jo s svojo mogočno roko privedel iz Egipta.
Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
27 Spomni se svojih služabnikov: Abrahama, Izaka in Jakoba. Ne glej na trmoglavost teh ljudi niti k njihovi zlobnosti niti k njihovemu grehu,
Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
28 da ne bi dežela, od koder si nas privedel, rekla: ›Ker jih Gospod ni bil zmožen privesti v deželo, ki jim jo je obljubil in ker jih je sovražil, jih je privedel ven, da jih pobije v divjini.‹
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
29 Vendar so tvoje ljudstvo in tvoja dediščina, ki si jih izpeljal s svojo mogočno močjo in s svojim iztegnjenim laktom.‹
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”

< 5 Mojzes 9 >