< 5 Mojzes 33 >

1 To je blagoslov, s katerim je Mojzes, Božji mož, pred svojo smrtjo blagoslovil Izraelove otroke.
Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
2 Rekel je: » Gospod je prišel s Sinaja in se iz Seírja dvignil k njim. On sije z gore Parán in prišel je z deset tisoči svetih. Iz njegove desnice je šla zanje ognjena postava.
Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
3 Da, ljubil je ljudstvo. Vsi njegovi sveti so v tvoji roki in usedli so se pri tvojih stopalih; vsak bo prejel od tvojih besed.
Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
4 Mojzes nam je zapovedal postavo, torej dediščino Jakobove skupnosti.
òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
5 In on je bil kralj v Ješurúnu, ko so se zbrali skupaj poglavarji ljudstva in so bili Izraelovi rodovi zbrani skupaj.
Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
6 Naj Ruben živi in ne umre in naj njegovih mož ne bo malo.«
“Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
7 To je blagoslov za Juda. Rekel je: »Prisluhni, Gospod, Judovemu glasu in privedi ga k svojemu ljudstvu. Naj mu njegove roke zadoščajo in ti mu bodi pomoč pred njegovimi sovražniki.«
Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
8 O Léviju je rekel: » Naj bosta tvoj Tumím in tvoj Urím s tvojim svetim, ki si ga preizkusil pri Masi in s katerim si se prepiral pri vodah Meríbe,
Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
9 ki je svojemu očetu in svoji materi rekel: ›Nisem ga videl.‹ Niti ni priznal svojih bratov niti spoznal svojih lastnih otrok, kajti obeležili so tvojo besedo in se držali tvoje zaveze.
Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
10 Jakoba bodo učili tvojih sodb in Izraela tvoje postave. Pred teboj bodo postavili kadilo in celotno žgalno daritev na tvoj oltar.
Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
11 Blagoslovi Gospod njegovo imetje in sprejmi delo njegovih rok. Skozi ledja udari tiste, ki vstajajo zoper njega in izmed tistih, ki ga sovražijo, da ne vstanejo ponovno.«
Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
12 In o Benjaminu je rekel: »Ljubljen od Gospoda bo varno prebival pri njem in Gospod ga bo ves dan pokrival in prebival bo med njegovimi rameni.«
Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
13 O Jožefu je rekel: »Njegova dežela naj bo blagoslovljena od Gospoda, za dragocene stvari z neba in za roso in za globino, ki leži spodaj
Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
14 in za dragoceno sadje, porojeno s soncem in za dragocene stvari, navržene z luno
àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
15 in za vodilne stvari starodavnih gora in za dragocene stvari trajnih hribov
pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
16 in za dragocene stvari zemlje in njene polnosti in za dobro voljo tistega, ki je prebival v grmu. Naj nad Jožefovo glavo pride blagoslov in na vrh glave tistega, ki je bil ločen od svojih bratov.
Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
17 Njegova slava je podobna prvencu njegovega bikca in njegovi rogovi so podobni rogovom samorogov. Z njimi bo suval ljudstvo skupaj h koncem zemlje, in oni so Efrájimovi deset tisoči in oni so Manásejevi deset tisoči.«
Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
18 O Zábulonu je rekel: »Veseli se Zábulon v svojem odhajanju in Isahár v svojih šotorih.
Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
19 Ljudstvo bosta klicala h gori. Tam bodo darovali klavne daritve pravičnosti, kajti sesali bodo od obilja morij in od zakladov, skritih v pesku.«
Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
20 O Gadu je rekel: »Blagoslovljen bodi, kdor povečuje Gad. Ta prebiva kakor lev in trga laket s têmenom.
Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
21 Prvi del si je priskrbel zase, ker je bil tam, v deležu postavodajalca, dokončan; in prišel je s poglavarji ljudstva, izvršil je Gospodovo pravičnost in njegove sodbe z Izraelom.«
Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
22 O Danu je rekel: »Dan je levji mladič. Poskakoval bo iz Bašána.«
Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
23 O Neftáliju je rekel: »Oh Neftáli, nasičen z naklonjenostjo in poln Gospodovega blagoslova. Ti poseduj zahod in jug.«
Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
24 O Aserju je rekel: »Aser naj bo blagoslovljen z otroki. Sprejemljiv naj bo svojim bratom in naj svoje stopalo omoči v olju.
Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
25 Tvoji čevlji bodo železo in bron in kakor tvoji dnevi, takšna bo tvoja moč.
Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
26 Nobenega ni podobnega Ješurúnovemu Bogu, ki jaha na nebesih v tvojo pomoč in v svoji odličnosti na nebu.
“Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
27 Večen Bog je tvoje zatočišče in spodaj so večne roke in on bo izpred tebe sunil sovražnika in rekel bo: ›Uniči jih.‹
Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
28 Potem bo Izrael sam prebival na varnem. Jakobov studenec bo na deželi žita in vina; tudi njegovo nebo bo kapljalo roso.
Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
29 Srečen si ti, oh Izrael. Kdo je tebi podoben, oh ljudstvo, rešeno po Gospodu, ščitu tvoje pomoči in kdo je meč tvoje odličnosti! In tvoji sovražniki ti bodo najdeni kot lažnivci, in teptal jih boš na njihovih visokih krajih.«
Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”

< 5 Mojzes 33 >