< 5 Mojzes 12 >

1 To so zakoni in sodbe, ki jih boste obeležili, da jih počnete v deželi, ki ti jo daje Gospod, Bog vaših očetov, da jo vzamete v last, vse dni, ko živite na zemlji.
Wọ̀nyí ni àwọn ìlànà àti òfin tí ẹ gbọdọ̀ ṣọ́ra láti máa tẹ̀lé, ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, fi fún un yín láti gbà: ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá fi wà lórí ilẹ̀ náà.
2 Vse kraje, na katerih so narodi, ki jih boste vzeli v last, služili svojim bogovom na visokih gorah, na hribih in pod vsakim zelenim drevesom, boste popolnoma uničili.
Gbogbo ibi gíga àwọn òkè ńlá, àti òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀ níbi tí àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ ó lé jáde, tí ń sin òrìṣà wọn ní kí ẹ mú kúrò pátápátá.
3 Porušili boste njihove oltarje, zlomili njihove stebre, njihove ašere sežgali z ognjem, posekali boste rezane podobe njihovih bogov in njihova imena uničili iz tega kraja.
Ẹ wó àwọn pẹpẹ wọn, ẹ bi òpó ìsìn wọn ṣubú, kí ẹ sì sun òpó Aṣerah wọn ní iná. Ẹ gé gbogbo ère òrìṣà wọn lulẹ̀, kí ẹ sì pa orúkọ wọn rẹ́ ní gbogbo ààyè wọn.
4 Tako ne boste storili Gospodu, svojemu Bogu.
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí i tiwọn.
5 Toda na kraj, ki ga bo Gospod, vaš Bog, izbral izmed vseh vaših rodov, da tam položi svoje ime, celó k njegovemu prebivališču boste sledili in tja boš prišel
Ṣùgbọ́n ẹ wá ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà yín, láti fi orúkọ rẹ̀ síbẹ̀ bí i ibùgbé rẹ̀. Ibẹ̀ ni kí ẹ lọ.
6 in tja boste prinašali svoje žgalne daritve, svoje klavne daritve, svoje desetine, vzdigovalne daritve svoje roke, svoje zaobljube, svoje prostovoljne daritve in prvence od svojih čred in od svojih tropov.
Níbẹ̀ ni kí ẹ mú ẹbọ sísun àti ẹbọ yín wá, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àwọn ẹ̀jẹ́ yín, ọrẹ àtinúwá yín, àti àwọn àkọ́bí gbogbo màlúù yín àti ewúrẹ́ ẹ yín.
7 Tam boste jedli pred Gospodom, svojim Bogom in veselili se boste v vsem, k čemur položite svojo roko, vi in vaše družine, v čemer te je Gospod, tvoj Bog, blagoslovil.
Níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, kí ẹ̀yin àti ìdílé yín jẹun kí ẹ sì yó, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín, torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín.
8 Ne boste počeli po vseh stvareh, ki jih mi ta dan delamo tukaj, vsak mož karkoli je pravilno v njegovih lastnih očeh.
Kí ẹ̀yin kí ó má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí a tí ṣe níhìn-ín lónìí yìí, tí olúkúlùkù ń ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
9 Kajti doslej niste prišli k počitku in k dediščini, ki vam jo daje Gospod, vaš Bog.
Níwọ́n ìgbà tí ẹ ti dé ibi ìsinmi, àti ibi ogún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
10 Toda ko greste čez Jordan in prebivate v deželi, ki vam jo daje Gospod, vaš Bog, da jo podedujete in ko vam daje počitek pred vsemi vašimi sovražniki naokoli, tako da varno prebivate,
Ṣùgbọ́n ẹ ó la Jordani kọjá, ẹ ó sì máa gbé ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín bí ìní, yóò sì fún un yín ní ìsinmi, kúrò láàrín àwọn ọ̀tá a yín, tí ó yí i yín ká, kí ẹ ba à lè máa gbé láìléwu.
11 potem bo tam kraj, ki ga bo Gospod, vaš Bog, izbral, da svojemu imenu povzroči, da prebiva tam. Tja boste prinesli vse, kar sem vam zapovedal: vaše žgalne daritve, vaše klavne daritve, vaše desetine, vzdigovalno daritev vaše roke in vso vašo izbiro zaobljub, ki ste jih zaobljubili Gospodu,
Níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀. Níbẹ̀ ni kí ẹ mú gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún un yín wá: àwọn ọrẹ ẹ yín àti àwọn ẹbọ sísun, ìdámẹ́wàá yín àti ọrẹ àkànṣe, àti gbogbo ohun ìní yín tí ẹ ti yàn, èyí tí ẹ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa.
12 in veselili se boste pred Gospodom, vašim Bogom, vi in vaši sinovi, vaše hčere, služabniki, vaše dekle in Lévijevec, ki je znotraj tvojih velikih vrat, ker nima ne deleža, ne dediščine z vami.
Kí ẹ máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbẹ̀, ẹ̀yin, àwọn ọmọkùnrin yín, àwọn ọmọbìnrin yín, ìránṣẹ́bìnrin àti ìránṣẹ́kùnrin yín, àti àwọn Lefi láti ìlú u yín, tí wọn kò ní ìpín tàbí ogún tiwọn.
13 Pazi nase, da ne daruješ svojih žgalnih daritev na vsakem kraju, ki ga vidiš,
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe rú ẹbọ sísun yín ní ibikíbi tí ẹ̀yin fẹ́.
14 temveč na kraju, ki ga bo Gospod izbral v enem izmed tvojih rodov, tam boš daroval svoje žgalne daritve in tam boš počel vse, kar ti zapovem.
Ibi tí Olúwa yóò yàn láàrín àwọn ẹ̀yà a yín nìkan ni kí ẹ ti máa rú ẹbọ sísun yín, kí ẹ sì máa kíyèsi ohun gbogbo tí mo pàṣẹ fún un yín níbẹ̀.
15 Vendar v vseh svojih velikih vratih lahko zakolješ in ješ meso, karkoli tvoja duša poželi, glede na blagoslov Gospoda, tvojega Boga, ki ti ga je dal. Nečisti in čisti lahko jé od tega, kakor od srnjaka in kakor od jelena.
Síbẹ̀síbẹ̀, ẹ lọ pa àwọn ẹran yín ní èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín, kí ẹ sì jẹ ẹran náà tó bí ẹ ti fẹ́, bí ẹ ti ń ṣe sí àgbọ̀nrín àti èsúró, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run yín tí ó fi fún un yín, àti ẹni mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ nínú àwọn ẹran náà.
16 Samo krvi ne boste jedli; kakor vodo jo boste izlili na zemljo.
Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
17 Znotraj svojih velikih vrat ne smeš jesti desetine svojega žita ali svojega vina ali svojega olja ali prvencev svojih čred ali svojega tropa, niti česarkoli od svojih zaobljub, ki si jih zaobljubil, niti svojih prostovoljnih daritev ali vzdigovalne daritve svoje roke,
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ìdámẹ́wàá oúnjẹ yín, wáìnì tuntun, òróró, àkọ́bí àwọn màlúù yín, tàbí ti ewúrẹ́ ẹ yín, ohunkóhun tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ àtinúwá, tàbí ẹ̀bùn pàtàkì ní ìlú ẹ̀yin tìkára yín.
18 temveč jih moraš jesti pred Gospodom, svojim Bogom, na kraju, ki ga bo Gospod, tvoj Bog, izbral, ti in tvoj sin, tvoja hči, tvoj sluga, tvoja dekla in Lévijevec, ki je znotraj tvojih velikih vrat, in veselil se boš pred Gospodom, svojim Bogom, v vsem, k čemur priložiš svoji roki.
Bí kò ṣe kí ẹ jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, níbi tí Olúwa Ọlọ́run yín, yóò yàn: ìwọ, àwọn ọmọkùnrin rẹ, àwọn ọmọbìnrin rẹ, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin rẹ àti àwọn ọmọ Lefi láti ìlú u yín, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ìdáwọ́lé e yín.
19 Pazi nase, da ne zapustiš Lévijevca tako dolgo, kot živiš na zemlji.
Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe gbàgbé àwọn Lefi, ní gbogbo ìgbà tí ẹ bá ń gbé ní ilẹ̀ ẹ yín.
20 Ko bo Gospod, tvoj Bog, povečal tvojo mejo, kakor ti je obljubil in boš rekel: ›Jedel bom meso, ‹ ker tvoja duša hrepeni, da bi jedla meso; lahko ješ meso, karkoli tvoja duša poželi.
Bí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti fẹ́ agbègbè e yín bí ó ti ṣe ìlérí, fún un yín, tí ẹ sì wí pé, àwa yóò jẹ ẹran, nítorí tí ọkàn wa fẹ́ jẹran. Ẹ jẹ ẹran náà bí ẹ tí fẹ́.
21 Če je kraj, ki ga je izbral Gospod, tvoj Bog, da tam položi svoje ime, predaleč od tebe, potem boš zaklal od svoje črede in od svojega tropa, ki ti ga je dal Gospod, kakor sem ti zapovedal in v svojih velikih vratih boš jedel karkoli tvoja duša poželi.
Bí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín bá yàn fún orúkọ rẹ̀ bá jìnnà sí i yín, kí ẹ pa màlúù tàbí ewúrẹ́ tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fún un yín, bí mo ti pàṣẹ fún un yín ní ìlú u yín, ẹ lè jẹ ẹ́ bí ẹ ti fẹ́.
22 Celo kakor se pojesta srnjak in jelen, tako jih boš ti pojedel. Nečisti in čisti bosta enako jedla od njih.
Ẹ jẹ wọ́n bí ẹ ó ti jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín, ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́.
23 Samo bodi odločen, da ne ješ krvi, kajti kri je življenje in življenja ne smeš jesti z mesom.
Ṣùgbọ́n ẹ rí i dájú pé ẹ kò jẹ ẹ̀jẹ̀ wọn, nítorí pé ẹ̀jẹ̀ ni ẹ̀mí, ẹ kò sì gbọdọ̀ jẹ ẹ̀mí pọ̀ mọ́ ẹran.
24 Ne boš je jedel. Kakor vodo jo boš izlil na zemljo.
Ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á sílẹ̀ bí omi.
25 Ne boš je jedel, da bo lahko dobro s teboj in s tvojimi otroki za teboj, ko boš delal to, kar je pravilno v Gospodovih očeh.
Ẹ má ṣe jẹ ẹ́, kí ó bá à lè dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín, tí ń bọ̀ lẹ́yìn in yín. Nígbà yí ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó tọ̀nà lójú Olúwa.
26 Samo svoje svete stvari, ki jih imaš in svoje zaobljube boš vzel in šel na kraj, ki ga bo Gospod izbral
Ẹ mú àwọn ohun tí ẹ yà sọ́tọ̀ àti àwọn ẹ̀jẹ́ yín, kí ẹ sì lọ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
27 in daroval boš svoje žgalne daritve, meso in kri, na oltarju Gospoda, svojega Boga. In kri tvojih klavnih daritev bo izlita na oltar Gospoda, tvojega Boga in jedel boš meso.
Ẹ fi ẹbọ sísun yín kalẹ̀ lórí i pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, àti ẹran àti ẹ̀jẹ̀ rẹ̀. Ẹ̀jẹ̀ ọrẹ yín ni ki ẹ dà sí pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run yín, ṣùgbọ́n ẹ lè jẹ ẹran.
28 Obeležuj in poslušaj vse te besede, ki sem ti jih zapovedal, da bo lahko dobro s teboj in s tvojimi otroki za teboj na veke, ko delaš to, kar je dobro in pravilno v očeh Gospoda, tvojega Boga.
Ẹ kíyèsára láti máa gbọ́rọ̀ sí gbogbo ìlànà tí mò ń fún un yín, kí o bá à dára fún ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín nígbà gbogbo, nítorí pé nígbà náà ní ẹ tó ń ṣe ohun tí ó dára tí ó sì tọ̀nà níwájú Olúwa Ọlọ́run yín.
29 Ko bo Gospod, tvoj Bog, izpred tebe uničil narode, kamor greš, da jih vzameš v last in jih zasedeš in prebivaš v njihovi deželi,
Olúwa Ọlọ́run yín yóò gé àwọn orílẹ̀-èdè tí ẹ fẹ́ lé kúrò tí ẹ sì fẹ́ gba ilẹ̀ wọn kúrò níwájú u yín. Ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ bá ti lé wọn jáde tí ẹ sì ń gbé ilẹ̀ wọn.
30 pazi nase, da ne boš ujet s tem, da jim slediš, potem ko so bili uničeni izpred tebe, in da ne povprašuješ po njihovih bogovih, rekoč: ›Kako so ti narodi služili svojim bogovom? Celo jaz bom počel podobno.‹
Lẹ́yìn ìgbà tí a bá ti pa wọ́n run níwájú u yín, ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ba à bọ́ sínú àdánwò nípa bíbéèrè nípa àwọn òrìṣà wọn wí pé, “Báwo ni àwọn orílẹ̀-èdè yìí ṣe ń sin àwọn òrìṣà wọn? Àwa náà yóò ṣe bẹ́ẹ̀”.
31 Ne boš tako počel Gospodu, svojemu Bogu, kajti vsako ogabnost Gospodu, ki jo on sovraži, so počeli svojim bogovom, kajti celo svoje sinove in svoje hčere so v ognju sežigali svojim bogovom.
Ẹ kò gbọdọ̀ sin Olúwa Ọlọ́run yín bí àwọn, torí pé, nípa sínsin ọlọ́run wọn, wọ́n ń ṣe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ìríra tí Ọlọ́run kórìíra. Wọ́n ń dáná sun àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn láti fi rú ẹbọ sí ère òrìṣà wọn.
32 Katerokoli stvar ti zapovem, obeležuj, da jo storiš. K temu ne boš dodal niti od tega ne boš jemal.
Ẹ rí i pé ẹ̀ ń ṣe gbogbo ohun tí mo ti pàṣẹ fún un yín. Ẹ má ṣe fi kún un, ẹ má sì ṣe yọ kúrò níbẹ̀.

< 5 Mojzes 12 >