< Daniel 11 >

1 Tudi jaz sem v prvem letu Medijca Dareja, celó jaz, stal, da ga potrdim in okrepim.
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ará Media, mo dúró láti tì í lẹ́yìn àti láti dáàbò bò ó.)
2 Sedaj ti bom pokazal resnico: »Glej, v Perziji bodo vstali še trije kralji, četrti pa bo mnogo bogatejši kakor oni vsi. S svojo močjo bo po svojih bogastvih vse razvnel zoper področje Grčije.
“Ní ìsinsin yìí, mo sọ òtítọ́ fún ọ ọba mẹ́ta yóò dìde sí i ní Persia, àti ẹ̀kẹrin tí yóò jẹ́ ọlọ́rọ̀ ju gbogbo wọn lọ. Tí ó bá ti di alágbára nípa ọrọ̀ rẹ̀, yóò sì ru gbogbo wọn sókè lòdì sí ìjọba Giriki.
3 Vstal bo mogočen kralj, ki bo vladal z velikim gospostvom in počel glede na svojo voljo.
Nígbà náà ni ọba alágbára kan yóò fi ara hàn, yóò ṣe àkóso pẹ̀lú agbára ńlá, yóò sì ṣe bí ó ti wù ú.
4 Ko bo vstal, bo njegovo kraljestvo zlomljeno in razdeljeno bo proti štirim vetrovom neba, in ne k njegovemu potomstvu niti glede na njegovo gospostvo, ki mu je vladal, kajti njegovo kraljestvo bo izpuljeno, celo za druge poleg teh.
Lẹ́yìn ìgbà tí ó bá fi ara hàn tán, ìjọba rẹ̀ yóò fọ́, yóò sì pín sí mẹ́rin ní orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé, ìjọba náà kò sì ṣọ́wọ́ àwọn ìran rẹ̀ tàbí kí ó ní agbára tí ó ń lò tẹ́lẹ̀, nítorí, a ó fa ìjọba rẹ̀ tu a ó sì fi fún àwọn mìíràn.
5 Južni kralj bo močan in eden izmed njegovih princev in on bo močan nad njim in imel bo gospostvo; njegovo gospostvo bo veliko gospostvo.
“Ọba ìhà gúúsù yóò di alágbára ṣùgbọ́n ọ̀kan lára àwọn aláṣẹ rẹ̀ yóò di alágbára jù ú lọ, yóò sì ṣe àkóso ìjọba rẹ̀ pẹ̀lú agbára ńlá.
6 Ob koncu let se bosta združila skupaj, kajti kraljeva hči iz juga bo prišla k severnemu kralju, da sklene dogovor. Toda ona ne bo obdržala moči lakta niti on ne bo obstal niti njegov laket, temveč bo izdana in tisti, ki so jo privedli in tisti, ki jo je zaplodil in kdor jo je okrepil v teh časih.
Lẹ́yìn ọdún púpọ̀ wọn yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò lọ sí ọ̀dọ̀ ọba àríwá láti bá a dá májẹ̀mú àlàáfíà, ṣùgbọ́n òun kì yóò lè di agbára apá a rẹ̀ mú, bẹ́ẹ̀ ni òun kì yóò lè dádúró, ṣùgbọ́n a ó tẹrí i rẹ̀ ba àti àwọn tí ó mú un wá, àti ọmọ tí ó bí, àti ẹni tí ó ń mu lọ́kàn le ní gbogbo àkókò wọ̀nyí.
7 Toda iz mladike njenih korenin bo vstal nekdo v svoji lastnini, ki bo prišel z vojsko in vstopil v trdnjavo severnega kralja in se bo spoprijel zoper njih in bo prevladal.
“Ọ̀kan lára àwọn ìdílé e rẹ̀, ọmọbìnrin ọba gúúsù yóò dìde láti gba ipò o rẹ̀. Yóò sì kọlu ogun ọba àríwá, yóò sì wó odi alágbára; yóò bá wọn jà yóò sì borí.
8 Prav tako bo ujete odvedel v Egipt njihove bogove z njihovimi princi in z njihovimi dragocenimi posodami iz srebra in zlata, in nadaljeval bo več let kakor kralj iz severa.
Yóò gba òrìṣà wọn, ère dídá àti ohun èlò oníye lórí ti fàdákà àti ti wúrà, yóò sì kó wọn lọ sí Ejibiti. Fún ọdún díẹ̀ yóò fi ọba àríwá lọ́rùn sílẹ̀.
9 Tako bo južni kralj prišel v svoje kraljestvo in se bo vrnil v svojo lastno deželo.
Nígbà náà, ni ọba àríwá yóò gbógun ti ilẹ̀ ọba, gúúsù, ṣùgbọ́n yóò padà sí Orílẹ̀-èdè, òun fúnra rẹ̀.
10 Toda njegova sinova bosta razvneta in bosta zbrala množico velikih sil, in nekdo bo zagotovo prišel, preplavil in šel skozi. Potem se bo vrnil in bo razvnet, celó do svoje trdnjave.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò múra ogun wọn yóò kó ogun ńlá jọ, èyí tí a ó gbá lọ bí àgbàrá omi ńlá, yóò sì gbá a lọ títí dé ìlú olódi rẹ̀.
11 Južni kralj bo prevzet z gnevom in prišel bo in se boril z njim, celó s severnim kraljem, in postavil bo veliko množico, toda množica bo dana v njegovo roko.
“Nígbà náà ni ọba gúúsù yóò jáde pẹ̀lú ìbínú, yóò sì bá ọba àríwá jà, ẹni tí yóò kó ọmọ-ogun púpọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ọba gúúsù yóò borí i wọn.
12 In ko bo odvedel množico, bo njegovo srce povzdignjeno in podrl bo mnogo deset tisočev, toda s tem ne bo okrepljen.
Nígbà tí a bá kó ogun náà lọ, ọba gúúsù yóò kún fún agbára, yóò sì pa ẹgbẹẹgbẹ̀rún ní ìpakúpa síbẹ̀ kì yóò ṣẹ́gun.
13 Kajti severni kralj se bo vrnil in vzpostavil množico, večjo kakor prejšnja in zagotovo bo prišel čez določena leta z veliko vojsko in z mnogimi bogastvi.
Nítorí ọba àríwá yóò lọ kó ogun mìíràn jọ, tí ó pọ̀ ju ti àkọ́kọ́ lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún, yóò jáde pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ogun tí ó ti dira ogun fún dáradára.
14 V tistih časih bodo mnogi vstali zoper južnega kralja. Tudi roparji tvojega ljudstva se bodo povišali, da vzpostavijo videnje; vendar bodo padli.
“Ní àkókò ìgbà náà, ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò dìde sí ọba gúúsù. Àwọn ọlọ̀tẹ̀ nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ yóò ṣọ̀tẹ̀ ní ìmúṣẹ ìran náà, ṣùgbọ́n wọn kì yóò borí.
15 Tako bo prišel severni kralj in nasul nasip in zavzel najbolj utrjena mesta, in orožje iz juga se ne bo zoperstavilo niti njegovo izvoljeno ljudstvo niti ne bo nobene moči, da se zoperstavi.
Nígbà náà ni ọba àríwá yóò wá yóò sì gbé ogun tì í, yóò sì kó ìlú olódi. Ogun ọba gúúsù kò ní ní agbára láti kọjú ìjà sí i; bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọ̀wọ́ ogun tó dára jù kò ní ní agbára láti dúró.
16 Toda tisti, ki prihaja zoper njega, bo storil glede na svojo lastno voljo in nihče ne bo obstal pred njim. Ta pa bo stal v veličastni deželi, ki bo z njegovo roko použita.
Ẹni tí ó gbóguntì í yóò máa ṣe bí ó ti wù ú, kò sì ṣí ẹni tí yóò le è dojúkọ ọ́. Yóò sì fún ara rẹ̀ ní ibùjókòó ní ilẹ̀ tí ó dára, yóò sì ní agbára láti bà á jẹ́.
17 Svoj obraz bo tudi naravnal, da vstopi z močjo svojega celotnega kraljestva in pokončni z njim. Tako bo storil. Dal mu bo hčer izmed žensk, kvareč jo, toda ona ne bo obstala na njegovi strani niti ne bo zanj.
Yóò pinnu láti wá pẹ̀lú agbára ìjọba rẹ̀, yóò sì ní májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú ọba gúúsù yóò sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ fún un láti fẹ́ ẹ ní ìyàwó nítorí kí ó lè gba ìjọba, ṣùgbọ́n ète rẹ̀ yìí kì yóò dúró tàbí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún un.
18 Potem bo svoj obraz obrnil k otokom in bo mnoge zavzel, toda princ bo zaradi svoje koristi povzročil, da bo zasramovanje, ki ga je ta dajal, prenehalo. Brez njegovega lastnega zasramovanja mu bo povzročil, da se to obrne nadenj.
Nígbà náà ni yóò yí ara padà sí ilẹ̀ etí Òkun, yóò mú ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n aláṣẹ kan yóò mú òpin bá àfojúdi rẹ̀, yóò sì yí àfojúdi rẹ̀ padà sí orí rẹ̀.
19 Potem bo svoj obraz obrnil proti utrdbi svoje lastne dežele, toda spotaknil se bo, padel in ne bo najden.
Lẹ́yìn èyí, yóò sì yí padà sí ìlú olódi ti orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀, ṣùgbọ́n yóò kọsẹ̀ yóò sì ṣubú, a kì yóò sì rí i mọ́.
20 Potem bo v svoji lastnini vstal prenašalec davkov v slavi kraljestva, toda v nekaj dneh bo uničen, niti z jezo, niti v bitki.
“Arọ́pò rẹ̀ yóò rán agbowó orí kan jáde láti fi ìdí ipò ọlá ọba múlẹ̀ ṣùgbọ́n ní ìwọ̀n ọdún díẹ̀, a ó pa á run, kì yóò jẹ́ nípa ìbínú tàbí nínú ogun.
21 V njegovi lastnini bo vstala podla oseba, ki ji ne bodo dali časti kraljestva, toda vstopil bo miroljubno in kraljestvo dosegel z laskanji.
“Ẹni tí kò níláárí kan yóò rọ́pò rẹ̀, ẹni tí a kò tí ì fi ọlá ọba fún rí. Yóò sì gbógun sí ìjọba nígbà tí ọkàn àwọn ènìyàn balẹ̀ láìbẹ̀rù, yóò sì gbà á pẹ̀lú àrékérekè.
22 S silami poplave bodo odplavljeni izpred njega in bodo zlomljeni; da, tudi princ zaveze.
Nígbà náà, ni a ó gbà ogunlọ́gọ̀ ogun kúrò níwájú u rẹ̀, pẹ̀lú òun àti ọmọ-aládé ti májẹ̀mú náà ni a ó parun.
23 Potem ko z njim sklene sodelovanje, bo postopal varljivo, kajti prišel bo gor in postal močan z majhnim ljudstvom.
Lẹ́yìn tí ó wá ṣe ìpinnu pẹ̀lú u rẹ̀, yóò hùwà ẹ̀tàn, pẹ̀lú ìwọ̀nba ènìyàn kékeré ni yóò gba ìjọba.
24 Vstopil bo miroljubno, celo na najrodovitnejše kraje province. Počel bo to, kar njegovi očetje niso storili niti očetje njihovih očetov. Mednje bo razkropil plen, oplenjeno in bogastva. Da, napovedal bo svoje naklepe zoper oporišča, celo za nekaj časa.
Nígbà tí àwọn agbègbè tí ó lọ́rọ̀ gidigidi wà láìbẹ̀rù ni yóò gbóguntì wọ́n, yóò ṣe ohun tí baba rẹ̀ tàbí baba ńlá rẹ̀ kò ṣe rí, yóò pín ìkógun ẹrù àti ọrọ̀ fún àwọn ọmọ lẹ́yìn in rẹ̀. Yóò pète àti bi àwọn ìlú olódi ṣubú, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀ ni.
25 Z veliko vojsko bo razvnel svojo moč in svoj pogum zoper južnega kralja, in južni kralj bo razvnet v bitko z veliko in mogočno vojsko, toda ne bo obstal, kajti zoper njega bodo napovedali naklepe.
“Pẹ̀lú ogun púpọ̀, yóò sì ru agbára rẹ̀ àti ìgboyà rẹ̀ sókè sí ọba gúúsù. Ọba gúúsù yóò dìde ogun pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ-ogun tí ó lágbára gidigidi, ṣùgbọ́n kò ní le è dúró, nítorí ọ̀tẹ̀ tí ó gbèrò sí i.
26 Da, tisti, ki se hranijo od deleža njegove hrane, ga bodo uničili in njegova vojska se bo razkropila. Mnogi bodo popadali umorjeni.
Àwọn tí ó jẹ nínú oúnjẹ ọba yóò gbìyànjú láti parun, a ó gbá ogun rẹ̀ dànù, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni yóò ṣubú sí ogun.
27 Srci obeh teh kraljev bosta počeli vragolijo in pri eni mizi bosta govorila laži. Toda to ne bo uspelo, kajti vendar bo konec ob določenem času.
Àwọn ọba méjèèjì, ọkàn wọn tẹ̀ sí búburú, wọn yóò jókòó lórí tábìlì kan, wọn yóò máa parọ́ sí ara wọn, ṣùgbọ́n kò ní yọrí sí nǹkan kan nítorí òpin yóò wá ní àsìkò tí a yàn.
28 Potem se bo vrnil v svojo deželo z velikimi bogastvi, in njegovo srce bo zoper sveto zavezo. Počel bo junaška dejanja in se vrnil v svojo lastno deželo.
Ọba àríwá yóò padà sí ilẹ̀ rẹ̀ pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀, ṣùgbọ́n ọkàn rẹ̀ yóò lòdì sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì ṣiṣẹ́ lòdì sí i, yóò sì padà sí orílẹ̀-èdè òun fúnra rẹ̀.
29 Ob določenem času se bo vrnil in prišel proti jugu, toda ta ne bo kakor prejšnji ali kakor zadnji.
“Ní àsìkò tí a yàn, yóò gbógun sí gúúsù lẹ́ẹ̀kan sí i, ṣùgbọ́n ní ìgbà yí àyọríṣí yóò yàtọ̀ sí ti ìṣáájú.
30 Kajti ladje Kitéjcev bodo prišle zoper njega. Zato bo užaloščen, se vrnil in bo ogorčen zoper sveto zavezo. Tako bo storil; torej vrnil se bo in imel posvet s tistimi, ki so zapustili sveto zavezo.
Nítorí pé, ọkọ̀ ojú omi àwọn ilẹ̀ etídò ìwọ̀-oòrùn yóò takò ó, ọkàn rẹ̀ yóò sì pami. Nígbà náà, ni yóò padà, yóò sì bínú sí májẹ̀mú mímọ́, yóò sì padà, yóò sì fi ojúrere hàn sí àwọn tí ó kọ májẹ̀mú mímọ́ náà.
31 Sile bodo stopile na njegovo stran in oskrunili bodo svetišče moči in odpravili bodo dnevno daritev in postavili ogabnost, ki dela opustošenje.
“Agbára ọmọ-ogun rẹ̀ yóò dìde láti ba ohun mímọ́ ilé olódi tẹmpili jẹ́, yóò sì pa ẹbọ ojoojúmọ́ rẹ́. Nígbà náà ni wọn yóò gbé ìríra tí ó fa ìsọdahoro kalẹ̀.
32 Tiste, ki zlobno ravnajo zoper zavezo, bo pokvaril z laskanji, toda ljudstvo, ki pozna svojega Boga, bo močno in delalo bo junaška dela.
Pẹ̀lú irú àwọn tí ń ṣe búburú sí májẹ̀mú ní yóò fi ọ̀rọ̀ ìpọ́nni mú ṣọ̀tẹ̀, ṣùgbọ́n, àwọn tí ó mọ Ọlọ́run wọn yóò mú ọkàn le. Wọn yóò sì máa ṣe iṣẹ́ agbára.
33 Tisti med ljudstvom, ki razumejo, bodo poučevali mnoge, vendar bodo padali pod mečem in v plamenu, v ujetništvu in po plenjenju, mnogo dni.
“Àwọn tí ó mòye yóò máa kọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀, ṣùgbọ́n fún ìgbà díẹ̀, wọn yóò máa ṣubú nípa idà tàbí kí a jó wọn tàbí ìgbèkùn tàbí nípa ìkógun.
34 Torej ko bodo padali, jim bo pomagano z majhno pomočjo, toda mnogi se jih bodo oklenili z laskanji.
Nígbà tí wọ́n bá ṣubú, wọn yóò rí ìrànlọ́wọ́ díẹ̀, ọ̀pọ̀ àwọn tó ṣe aláìṣòótọ́ yóò sì darapọ̀ mọ́ wọn.
35 Nekateri izmed tistih z razumevanjem bodo padli, da se jih preizkusi in prečisti in se jih naredi bele, celó do časa konca, ker je to še za določeni čas.
Lára àwọn tí ó mòye yóò kọsẹ̀, nítorí kí a ba à tún wọn ṣe, wọ́n di mímọ́ àti aláìlábàwọ́n títí di ìgbà ìkẹyìn nítorí yóò sì wá ní àkókò tí a yàn.
36 Kralj pa bo počel glede na svojo voljo in poviševal se bo in se poveličeval nad vsakega boga in govoril bo osupljive stvari zoper Boga bogov in uspeval bo, dokler ne bo dovršeno ogorčenje, kajti to, kar je določeno, bo storjeno.
“Ọba yóò ṣe bí ó ti wù ú yóò sì gbé ara rẹ̀ ga, ju gbogbo òrìṣà lọ, yóò máa sọ àwọn ọ̀rọ̀ tí kò-ṣe-é-gbọ́-létí sí Ọlọ́run àwọn Ọlọ́run, yóò sì máa yege títí àkókò ìbínú yóò fi parí, nítorí ohun tí a ti pinnu yóò ṣẹlẹ̀.
37 Niti se ne bo oziral na Boga svojih očetov, niti na željo žensk, niti na kateregakoli boga, kajti poveličeval se bo nad vse.
Òun kò ní ka òrìṣà àwọn baba rẹ̀ sí tàbí èyí tí àwọn fẹ́, òun kò ní ka nǹkan kan sí, ṣùgbọ́n yóò gbé ara rẹ̀ ga ju gbogbo wọn lọ.
38 Toda v svoji lastnini bo spoštoval boga sil, in boga, ki ga njegovi očetje niso poznali, bo častil z zlatom, srebrom, dragocenimi kamni in prijetnimi stvarmi.
Ṣùgbọ́n dípò wọn, yóò bu ọlá fún òrìṣà àwọn ìlú olódi: òrìṣà tí àwọn baba rẹ̀ kò mọ̀ ni yóò bu ọlá fún pẹ̀lú wúrà àti fàdákà, pẹ̀lú òkúta iyebíye àti ẹ̀bùn tí ó lówó lórí.
39 Tako bo storil v najmočnejših oporiščih s tujim bogom, ki ga bo priznal in narastel s slavo. Povzročil jim bo, da vladajo nad mnogimi in deželo bo razdelil zaradi dobička.
Yóò kọlu àwọn ìlú olódi tí ó lágbára pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ òrìṣà àjèjì, yóò sì bu ọláńlá fún ẹni tí ó jẹ́wọ́ rẹ̀. Yóò mú wọn ṣe alákòóso lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, yóò sì pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí èrè.
40 Ob času konca bo južni kralj pritisnil nanj in severni kralj bo prišel proti njemu kot vrtinčast veter, z bojnimi vozovi in s konjeniki in z mnogimi ladjami in vstopil bo v dežele, jih preplavil in prešel.
“Ní ìgbà ìkẹyìn, ọba gúúsù yóò gbé ogun de sí i, ọba àríwá yóò sì jáde bí ìjì láti kọlù ú pẹ̀lú u kẹ̀kẹ́ ogun àti ẹlẹ́ṣin àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkọ̀ ojú omi. Yóò gbógun wọ orílẹ̀-èdè púpọ̀, yóò sì bo wọn mọ́lẹ̀ bí ìkún omi.
41 Vstopil bo tudi v veličastno deželo in mnoge dežele bodo premagane, toda te bodo pobegnile iz njegove roke, celó Edóm, Moáb in vodja Amónovih sinov.
Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì tún gbógun ti ilẹ̀ ológo náà pẹ̀lú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò ṣubú, ṣùgbọ́n Edomu, Moabu àti àwọn olórí Ammoni yóò bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.
42 Svojo roko bo iztegnil tudi nad dežele in egiptovska dežela ne bo ubežala.
Yóò lo agbára rẹ̀ lórí ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè; Ejibiti kì yóò là.
43 Toda imel bo oblast nad zakladi iz zlata, srebra in nad vsemi dragocenimi egiptovskimi stvarmi in Libijci in Etiopijci bodo pri njegovih korakih.
Yóò gba àkóso ìṣúra wúrà àti fàdákà àti gbogbo ọrọ̀ Ejibiti, pẹ̀lú ti Libia àti Kuṣi nígbà tí ó mú wọn tẹríba.
44 Toda novice iz vzhoda in iz severa ga bodo vznemirile, zato bo šel naprej z veliko razjarjenostjo, da uniči in popolnoma odpravi mnoge.
Ṣùgbọ́n ìròyìn láti ìlà-oòrùn àti láti ìwọ̀-oòrùn yóò mú ìdáríjì bá a, yóò sì fi ìbínú ńlá jáde lọ láti parun, àti láti pa ọ̀pọ̀lọpọ̀ run pátápátá.
45 Zasadil bo šotorska svetišča svoje palače med morjem in veličastno sveto goro, vendar bo prišel do svojega konca in nihče mu ne bo pomagal.
Yóò sì pàgọ́ ọ rẹ̀ láàrín Òkun kọjú sí àárín òkè mímọ́ ológo. Síbẹ̀ yóò wá sí òpin rẹ̀, ẹnìkan kò ní ràn án lọ́wọ́.

< Daniel 11 >