< Amos 3 >

1 Poslušajte to besedo, ki jo je Gospod govoril zoper vas, oh Izraelovi otroci, zoper celotno družino, ki sem jo privedel iz egiptovske dežele, rekoč:
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
2 »Samo vas sem poznal izmed vseh zemeljskih družin, zato vas bom kaznoval zaradi vseh vaših krivičnosti.
“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
3 Mar lahko dva hodita skupaj, razen če se strinjata?
Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
4 Ali bo lev rjovel v gozdu, kadar nima plena? Ali bo mlad lev vpil iz svojega brloga, če ni ničesar dobil?
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
5 Ali lahko ptica pade v zanko na tla, kjer zanjo ni nobene pasti? Mar nekdo pobere zanko s tal in ni sploh ničesar ujel?
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
6 Mar bo šofar zatrobil v mestu in ljudstvo ne bo prestrašeno? Mar bo zlo v mestu in Gospod tega ni storil?
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
7 Zagotovo Gospod Bog ne bo storil ničesar, da ne bi svojo skrivnost razodeval svojim služabnikom prerokom.
Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8 Lev je zarjovel, kdo se ne bo bal? Gospod Bog je spregovoril, kdo ne bi prerokoval?
Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
9 Razglasi v palačah pri Ašdódu in v palačah egiptovske dežele in reci: ›Zberite se na gorah Samarije in glejte velike nemire v njeni sredi in zatirane v njeni sredi.‹
Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
10 Kajti ne znajo delati pravilno, « govori Gospod, »tisti, ki kopičijo nasilje in rop v svojih palačah.«
“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11 Zato tako govori Gospod Bog: »Nasprotnik bo celo naokoli dežele in tvojo moč bo privedel dol od tebe in tvoje palače bodo oplenjene.«
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
12 Tako govori Gospod: »Kakor pastir iz levjih ust izvleče dve nogi ali košček ušesa, tako bodo izvlečeni Izraelovi otroci, ki prebivajo v Samariji, v kotu postelje in na ležišču v Damasku.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
13 Prisluhnite in pričujte v Jakobovi hiši, « govori Gospod Bog, Bog nad bojevniki,
“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
14 »da na dan, ko bom na njem obiskal Izraelove prestopke, bom obiskal tudi oltarje Betela in oltarni rogovi bodo odsekani in padli na tla.
“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
15 Zimsko hišo bom udaril s poletno hišo [vred] in slonokoščene hiše bodo izginile in velike hiše bodo uničene, « govori Gospod.
Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.

< Amos 3 >